< Job 1 >

1 Ọkùnrin kan wà ní ilẹ̀ Usi, orúkọ ẹni tí í jẹ́ Jobu; ọkùnrin náà sì ṣe olóòtítọ́, ó dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó kórìíra ìwà búburú.
Był w ziemi Uz człowiek imieniem Hiob; ten człowiek był doskonały i prawy, i bojący się Boga, a stroniący od zła.
2 A sì bi ọmọkùnrin méje àti ọmọbìnrin mẹ́ta fún un.
I urodziło mu się siedmiu synów i trzy córki.
3 Ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn, àti ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ìbákasẹ, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta àjàgà ọ̀dá màlúù, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì pọ̀; bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin yìí sì pọ̀jù gbogbo àwọn ará ìlà-oòrùn lọ.
A jego dobytek stanowiło siedem tysięcy owiec, trzy tysiące wielbłądów, pięćset jarzm wołów i pięćset oślic; [miał też] bardzo liczną służbę. Był on człowiekiem najmożniejszym wśród wszystkich ludzi Wschodu.
4 Àwọn ọmọ rẹ̀ a sì máa lọ í jẹun àsè nínú ilé ara wọn, olúkúlùkù ní ọjọ́ rẹ̀; wọn a sì máa ránṣẹ́ pé arábìnrin wọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta láti jẹun àti láti pẹ̀lú wọn.
Jego synowie schodzili się i urządzali ucztę, każdy w [swoim] domu w ustalonym dniu. Posyłali po swoje trzy siostry i zapraszali je, aby jadły i piły wraz z nimi.
5 Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ àsè wọn pé yíká, ni Jobu ránṣẹ́ lọ í yà wọ́n sí mímọ́, ó sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì rú ẹbọ sísun níwọ̀n iye gbogbo wọn; nítorí tí Jobu wí pé: bóyá àwọn ọmọ mi ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣọpẹ́ fún Ọlọ́run lọ́kàn wọn. Bẹ́ẹ̀ ní Jobu máa ń ṣe nígbà gbogbo.
A gdy minęły dni uczty, Hiob posyłał i poświęcał ich. Potem wstawał wczesnym rankiem i składał całopalenia [stosownie do] ich liczby. Mówił bowiem Hiob: Może moi synowie zgrzeszyli i złorzeczyli Bogu w swoich sercach. Tak Hiob czynił zawsze.
6 Ǹjẹ́ ó di ọjọ́ kan, nígbà tí àwọn ọmọ Ọlọ́run wá í pé níwájú Olúwa, Satani sì wá pẹ̀lú wọn.
Zdarzyło się [pewnego] dnia, gdy synowie Boży przybyli, aby stanąć przed PANEM, że też szatan pojawił się wśród nich.
7 Olúwa sì bi Satani wí pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?” Nígbà náà ní Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Ní ìlọsíwá-sẹ́yìn lórí ilẹ̀ ayé, àti ní ìrìnkèrindò nínú rẹ̀.”
Wtedy PAN zapytał szatana: Skąd przychodzisz? Szatan odpowiedział PANU: Krążyłem po ziemi i przechadzałem się po niej.
8 Olúwa sì sọ fún Satani pé, “Ìwọ ha kíyèsi Jobu ìránṣẹ́ mi, pé kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀ ní ayé, ọkùnrin tí í ṣe olóòtítọ́, tí ó sì dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, ti ó sì kórìíra ìwà búburú.”
PAN powiedział do szatana: Czy zwróciłeś uwagę na mojego sługę Hioba – że nie ma nikogo mu równego na ziemi? [To] człowiek doskonały i prawy, bojący się Boga i stroniący od zła.
9 Nígbà náà ni Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Jobu ha bẹ̀rù Ọlọ́run ní asán bí?”
A szatan odpowiedział PANU: Czy Hiob za darmo boi się Boga?
10 “Ìwọ kò ha ti ṣọgbà yìí ká, àti yí ilé rẹ̀ àti yí ohun tí ó ní ká, ní ìhà gbogbo? Ìwọ bùsi iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀, ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì ń pọ̀ si ní ilẹ̀.
Czy nie ogrodziłeś zewsząd jego samego, jego domu i wszystkiego, co ma? Błogosławiłeś dziełom jego rąk, a jego dobytek rozmnożył się na ziemi.
11 Ǹjẹ́, nawọ́ rẹ nísinsin yìí, kí ó sì fi tọ́ ohun gbogbo tí ó ni; bí kì yóò sì bọ́hùn ni ojú rẹ.”
Ale wyciągnij tylko swoją rękę i dotknij wszystkiego, co ma, a [na pewno] będzie ci w twarz złorzeczył.
12 Olúwa sì dá Satani lóhùn wí pé, “Kíyèsi i, ohun gbogbo tí ó ní ń bẹ ní ìkáwọ́ rẹ, kìkì òun tìkára rẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ fi ọwọ́ rẹ kàn.” Bẹ́ẹ̀ ni Satani jáde lọ kúrò níwájú Olúwa.
Wtedy PAN powiedział do szatana: Oto wszystko, co ma, [jest] w twojej mocy, tylko na niego nie wyciągaj ręki. I szatan odszedł sprzed oblicza PANA.
13 Ó sì di ọjọ́ kan nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, tí wọ́n mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n wọn ọkùnrin,
Zdarzyło się [któregoś] dnia, gdy jego synowie i córki jedli i pili wino w domu najstarszego brata;
14 oníṣẹ́ kan sì tọ Jobu wá wí pé, “Àwọn ọ̀dá màlúù ń tulẹ̀, àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì ń jẹ ní ẹ̀gbẹ́ wọn,
Że do Hioba przybył posłaniec i powiedział: Woły orały, a oślice pasły się obok nich;
15 àwọn ará Sabeani sì kọlù wọ́n, wọ́n sì ń kó wọn lọ pẹ̀lú, wọ́n ti fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa, èmi nìkan ṣoṣo ní ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ.”
I napadli Sabejczycy, i zabrali je, a sługi pozabijali ostrzem miecza. Uszedłem tylko ja sam, aby cię [o tym] powiadomić.
16 Bí ó ti ń sọ ní ẹnu; ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé, “Iná ńlá Ọlọ́run ti ọ̀run bọ́ sí ilẹ̀, ó sì jó àwọn àgùntàn àti àwọn ìránṣẹ́; èmi nìkan ṣoṣo ní ó sálà láti ròyìn fún ọ.”
A gdy ten jeszcze mówił, przyszedł inny i powiedział: Ogień Boży spadł z nieba, spalił owce i sługi i pochłonął ich. Uszedłem tylko ja sam, aby cię [o tym] powiadomić.
17 Bí ó sì ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan sì dé pẹ̀lú tí ó wí pé, “Àwọn ará Kaldea píngun sí ọ̀nà mẹ́ta, wọ́n sì kọlù àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì kó wọn lọ, pẹ̀lúpẹ̀lú wọ́n sì fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa; èmi nìkan ṣoṣo ni ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ!”
A gdy ten jeszcze mówił, przyszedł inny i powiedział: Chaldejczycy podzieleni na trzy oddziały napadli na wielbłądy, zabrali je, a sługi pozabijali ostrzem miecza. Uszedłem tylko ja sam, aby cię [o tym] powiadomić.
18 Bí ó ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin ń jẹ, wọ́n ń mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n.
A gdy ten jeszcze mówił, przyszedł inny i powiedział: Twoi synowie i córki jedli i pili wino w domu najstarszego brata;
19 Sì kíyèsi i, ẹ̀fúùfù ńlá ńlá ti ìhà ijù fẹ́ wá kọlu igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilé, ó sì wó lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wọ́n sì kú, èmi nìkan ṣoṣo ni ó yọ láti ròyìn fún ọ.
A oto gwałtowny wiatr powiał od pustyni i uderzył w cztery węgły domu, tak że zawalił się na dzieci i pomarły. Uszedłem tylko ja sam, aby cię [o tym] powiadomić.
20 Nígbà náà ni Jobu dìde, ó sì fa aṣọ ìgúnwà rẹ̀ ya, ó sì fá orí rẹ̀ ó wólẹ̀ ó sì gbàdúrà
Wtedy Hiob wstał, rozdarł swój płaszcz, ogolił swoją głowę, potem upadł na ziemię i oddał pokłon;
21 wí pé, “Ní ìhòhò ní mo ti inú ìyá mi jáde wá, ni ìhòhò ní èmi yóò sì tún padà lọ. Olúwa fi fún ni, Olúwa sì gbà á lọ, ìbùkún ni fún orúkọ Olúwa.”
I powiedział: Nagi wyszedłem z łona swojej matki i nagi tam powrócę. PAN dał, PAN też wziął, niech imię PANA będzie błogosławione.
22 Nínú gbogbo èyí Jobu kò ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi òmùgọ̀ pe Ọlọ́run lẹ́jọ́.
W tym wszystkim Hiob nie zgrzeszył ani nie oskarżał Boga o nic niewłaściwego.

< Job 1 >