< Job 9 >

1 Jobu sì dáhùn ó sì wí pé,
Atunci Iov a răspuns și a zis:
2 “Èmi mọ̀ pe bẹ́ẹ̀ ni ní òtítọ́. Báwo ní ènìyàn yóò ha ti ṣe jẹ́ aláre níwájú Ọlọ́run?
Cu adevărat știu că așa este, dar cum ar fi un om drept cu Dumnezeu?
3 Bí ó bá ṣe pé yóò bá a jà, òun kì yóò lè dalóhùn kan nínú ẹgbẹ̀rún ọ̀rọ̀.
Dacă se va certa cu el, nu îi poate răspunde una dintr-o mie.
4 Ọlọ́gbọ́n nínú àwọn alágbára ní ipa ní Òun. Ta ni ó ṣe agídí sí i tí ó sì gbé fún rí?
El este înțelept în inimă și puternic în tărie; cine a prosperat împietrindu-se împotriva lui?
5 Ẹni tí ó sí òkè nídìí tí wọn kò sì mọ́: tí ó taari wọn ṣubú ní ìbínú rẹ̀.
Care mută munții și ei nu știu, care îi răstoarnă în mânia sa.
6 Tí ó mi ilẹ̀ ayé tìtì kúrò ní ipò rẹ̀, ọwọ̀n rẹ̀ sì mì tìtì.
Care clatină pământul din locul lui și stâlpii săi se cutremură.
7 Ó pàṣẹ fún oòrùn kò sì le è ràn, kí ó sì dí ìmọ́lẹ̀ ìràwọ̀ mọ́.
Care poruncește soarelui iar el nu răsare; și sigilează stelele.
8 Òun nìkan ṣoṣo ni ó ta ojú ọ̀run, ti ó sì ń rìn lórí ìgbì Òkun.
Care singur întinde cerurile și calcă pe valurile mării.
9 Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Beari àti Orioni, Pleiadesi àti ìràwọ̀ púpọ̀ ti gúúsù.
Care face Ursa, Orionul și Pleiadele și încăperile sudului.
10 Ẹni tí ń ṣe ohun tí ó tóbi jù àwárí lọ, àní ohun ìyanu láìní iye.
Care face lucruri mari, peste putință a fi socotite, da, și minuni fără număr.
11 Kíyèsi i, ó ń kọjá lọ ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ mi, èmi kò sì rí i, ó sì kọjá síwájú, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò rí ojú rẹ̀.
Iată, el merge pe lângă mine și eu nu îl văd; trece de asemenea pe lângă mine, dar nu îl percep.
12 Kíyèsi i, ó já a gbà lọ, ta ni ó lè fà á padà? Ta ni yóò bi í pé kí ni ìwọ ń ṣe nì?
Iată, el ia, cine îl poate împiedica? Cine îi va spune: Ce faci?
13 Ọlọ́run kò ní fa ìbínú rẹ̀ sẹ́yìn, àwọn onírànlọ́wọ́ ti Rahabu a sì tẹríba lábẹ́ rẹ̀.
Dacă Dumnezeu nu își va retrage mânia, ajutoarele mândre se încovoaie sub el.
14 “Kí ní ṣe tí èmi ti n o fi ba ṣàròyé? Tí èmi yóò fi ma ṣe àwáwí?
Cu cât mai puțin să îi răspund și să îmi aleg cuvintele [să mă judec] cu el?
15 Bí ó tilẹ̀ ṣe pé mo ṣe aláìlẹ́bi, èmi kò gbọdọ̀ dá a lóhùn; ṣùgbọ́n èmi ó gbàdúrà fún àánú.
Căruia, deși am fost drept, totuși nu i-aș răspunde, ci aș face cerere către judecătorul meu.
16 Bí èmi bá sì ké pè é, tí Òun sì dá mi lóhùn, èmi kì yóò sì gbàgbọ́ pé, Òun ti fetí sí ohùn mi.
Dacă l-aș fi chemat, iar el mi-ar fi răspuns, totuși nu aș crede că a dat ascultare vocii mele.
17 Nítorí pé òun yóò lọ̀ mí lúúlúú pẹ̀lú ìjì ńlá, ó sọ ọgbẹ́ mi di púpọ̀ láìnídìí.
Căci mă frânge cu o furtună și îmi înmulțește rănile fără motiv.
18 Òun kì yóò jẹ́ kí èmi kí ó rí ẹ̀mí mi, ṣùgbọ́n ó mú ohun kíkorò kún un fún mi.
Nu îmi va permite să îmi trag suflarea, ci mă umple cu amărăciune.
19 Bí mo bá sọ ti agbára, wò ó! Alágbára ni, tàbí ní ti ìdájọ́, ta ni yóò dá àkókò fún mi láti rò?
Dacă vorbesc despre putere, iată, el este puternic; și despre judecată, cine îmi va rândui un timp să pledez?
20 Bí mo tilẹ̀ dá ara mi láre, ẹnu ara mi yóò dá mi lẹ́bi; bí mo wí pé olódodo ni èmi yóò sì fi mí hàn ní ẹni ẹ̀bi.
Dacă mă declar drept, propria mea gură mă va condamna; dacă spun: Sunt desăvârșit, aceasta mă va dovedi de asemenea pervers.
21 “Olóòótọ́ ni mo ṣe, síbẹ̀ èmi kò kíyèsi ara mi, ayé mi ní èmi ìbá máa gàn.
Chiar dacă eu aș fi desăvârșit, totuși nu mi-aș cunoaște sufletul, mi-aș disprețui viața.
22 Ohùn kan náà ni, nítorí náà ni èmi ṣe sọ: ‘Òun a pa ẹni òtítọ́ àti ènìyàn búburú pẹ̀lú.’
Acesta este un lucru, de aceea l-am spus: El nimicește pe cel desăvârșit și pe cel stricat.
23 Bí ìjàǹbá bá pa ni lójijì, yóò rẹ́rìn-ín nínú ìdààmú aláìṣẹ̀.
Dacă biciul ucide dintr-odată, el va râde la încercarea celui nevinovat.
24 Nígbà tí a bá fi ayé lé ọwọ́ ènìyàn búburú; ó sì bo àwọn onídàájọ́ rẹ̀ lójú; bí kò bá rí bẹ́ẹ̀ ǹjẹ́ ta ni?
Pământul este dat în mâna celor stricați; el acoperă fețele judecătorilor acestuia; dacă nu, unde și cine este el?
25 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí ọjọ́ mi yára ju oníṣẹ́ lọ, wọ́n fò lọ, wọn kò rí ayọ̀.
Acum zilele mele sunt mai iuți decât un alergător; ele zboară și nu văd nimic bun.
26 Wọ́n kọjá lọ bí ọkọ̀ eèsún papirusi tí ń sáré lọ; bí idì tí ń yára si ohùn ọdẹ.
Au trecut precum corăbiile iuți, precum acvila care se grăbește la pradă.
27 Bí èmi bá wí pé, ‘Èmi ó gbàgbé arò ìbìnújẹ́ mi, èmi ó fi ọkàn lélẹ̀, èmi ó sì rẹ ara mi lẹ́kún.’
Dacă spun: Voi uita plângerea mea, îmi voi părăsi întristarea și mă voi mângâia;
28 Ẹ̀rù ìbànújẹ́ mi gbogbo bà mí, èmi mọ̀ pé ìwọ kì yóò mú mi bí aláìṣẹ̀.
Mi-e teamă de toate întristările mele, știu că nu mă vei considera nevinovat.
29 Bí ó bá ṣe pé ènìyàn búburú ni èmi, ǹjẹ́ kí ni èmi ń ṣe làálàá lásán sí?
Dacă sunt stricat, de ce muncesc în zadar?
30 Bí mo tilẹ̀ fi ọṣẹ dídì wẹ ara mi, tí mo fi omi aró wẹ ọwọ́ mi mọ́,
Dacă mă spăl cu apă din zăpadă și îmi curăț mâinile ca niciodată,
31 síbẹ̀ ìwọ ó gbé mi wọ inú ihò ọ̀gọ̀dọ̀ aṣọ ara mi yóò sọ mi di ìríra.
Totuși mă vei scufunda în șanț și propriile mele haine mă vor detesta.
32 “Nítorí Òun kì í ṣe ènìyàn bí èmi, tí èmi ó fi dá a lóhùn tí àwa o fi pàdé ní ìdájọ́.
Pentru că nu este om cum sunt eu, ca să îi răspund și să venim împreună la judecată.
33 Bẹ́ẹ̀ ni kò sí alátúnṣe kan ní agbede-méjì wa tí ìbá fi ọwọ́ rẹ̀ lé àwa méjèèjì lára.
Între noi nu este arbitru, să își pună mâna peste amândoi.
34 Kí ẹnìkan sá à mú ọ̀pá Ọlọ́run kúrò lára mi, kí ìbẹ̀rù rẹ̀ kí ó má sì ṣe dáyà fò mí.
Să își ia toiagul de la mine și să nu mă îngrozească spaima lui;
35 Nígbà náà ni èmi ìbá sọ̀rọ̀, èmi kì bá sì bẹ̀rù rẹ̀; ṣùgbọ́n bí ó tí dúró tì mí, kò ri bẹ́ẹ̀ fún mi.
Atunci aș vorbi și nu m-aș teme de el; dar nu este așa cu mine.

< Job 9 >