< Job 9 >

1 Jobu sì dáhùn ó sì wí pé,
A LAILA olelo mai la o Ioba, i mai la,
2 “Èmi mọ̀ pe bẹ́ẹ̀ ni ní òtítọ́. Báwo ní ènìyàn yóò ha ti ṣe jẹ́ aláre níwájú Ọlọ́run?
Ua ike no au, he oiaio no: A, pehea la e hoaponoia'i ke kanaka imua o ke Akua?
3 Bí ó bá ṣe pé yóò bá a jà, òun kì yóò lè dalóhùn kan nínú ẹgbẹ̀rún ọ̀rọ̀.
Ina makemake oia e hoopaapaa me ia, Aole e hiki ke hoapono imua ona i kekahi hapa tausani.
4 Ọlọ́gbọ́n nínú àwọn alágbára ní ipa ní Òun. Ta ni ó ṣe agídí sí i tí ó sì gbé fún rí?
He akamai ia ma ka naau, a ua nui ka ikaika: Owai la ka mea hoopaakiki ku e ia ia, a ua pomaikai?
5 Ẹni tí ó sí òkè nídìí tí wọn kò sì mọ́: tí ó taari wọn ṣubú ní ìbínú rẹ̀.
Oia ka mea hoonee aku i na mauna, aole lakou i ike; Ka mea hoohiolo ia lakou ma kona inaina;
6 Tí ó mi ilẹ̀ ayé tìtì kúrò ní ipò rẹ̀, ọwọ̀n rẹ̀ sì mì tìtì.
Ka mea hoonaue i ka honua mai kona wahi aku, A haalulu kona mau kukulu;
7 Ó pàṣẹ fún oòrùn kò sì le è ràn, kí ó sì dí ìmọ́lẹ̀ ìràwọ̀ mọ́.
Ka mea olelo aku i ka la, aole ia i puka mai, A hoopaa aku hoi ia i na hoku;
8 Òun nìkan ṣoṣo ni ó ta ojú ọ̀run, ti ó sì ń rìn lórí ìgbì Òkun.
O ka mea wale no nana i hohola na lani, A hele hoi maluna o na ale kiekie o ke kai;
9 Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Beari àti Orioni, Pleiadesi àti ìràwọ̀ púpọ̀ ti gúúsù.
O ka mea nana i hana o Uresa nui, me Oriona, A me Peleiade, a me ke kukuluhema loa aku;
10 Ẹni tí ń ṣe ohun tí ó tóbi jù àwárí lọ, àní ohun ìyanu láìní iye.
O ka mea i hana i na mea nui hiki ole ke huliia; A me na mea kupanaha hiki ole ke heluia.
11 Kíyèsi i, ó ń kọjá lọ ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ mi, èmi kò sì rí i, ó sì kọjá síwájú, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò rí ojú rẹ̀.
Aia hoi, maalo ae ia ma o'u nei, aole au i ike: Hele mai hoi oia, aka, aole au i hoomaopopo ia ia.
12 Kíyèsi i, ó já a gbà lọ, ta ni ó lè fà á padà? Ta ni yóò bi í pé kí ni ìwọ ń ṣe nì?
Aia hoi, lawe wale aku no ia, owai la ke pale aku ia ia? Owai la ka mea e olelo aku ia ia, Heaha kau e hana nei?
13 Ọlọ́run kò ní fa ìbínú rẹ̀ sẹ́yìn, àwọn onírànlọ́wọ́ ti Rahabu a sì tẹríba lábẹ́ rẹ̀.
I hoopau ole ae ke Akua i kona inaina, Kulou iho na kokua haaheo malalo ona.
14 “Kí ní ṣe tí èmi ti n o fi ba ṣàròyé? Tí èmi yóò fi ma ṣe àwáwí?
Pehea la hoi wau e olelo aku ai ia ia, A e wae ae i na huaolelo imua ona?
15 Bí ó tilẹ̀ ṣe pé mo ṣe aláìlẹ́bi, èmi kò gbọdọ̀ dá a lóhùn; ṣùgbọ́n èmi ó gbàdúrà fún àánú.
Ina he pono ko'u, aole au e olelo aku ia ia, E nonoi aku no wau i kuu lunakanawai.
16 Bí èmi bá sì ké pè é, tí Òun sì dá mi lóhùn, èmi kì yóò sì gbàgbọ́ pé, Òun ti fetí sí ohùn mi.
Ina ua kahea aku au, a ua lohe mai kela; Aole au e hooiaio, na hoolohe mai ia i ko'u leo.
17 Nítorí pé òun yóò lọ̀ mí lúúlúú pẹ̀lú ìjì ńlá, ó sọ ọgbẹ́ mi di púpọ̀ láìnídìí.
O ka mea e ulupa mai ia'u me ka ino, A hoonui wale mai ia i ko'u mau palapu.
18 Òun kì yóò jẹ́ kí èmi kí ó rí ẹ̀mí mi, ṣùgbọ́n ó mú ohun kíkorò kún un fún mi.
Aole ia e ae mai ia'u e hanu i kuu hanu, Aka, hoopiha mai no ia ia'u i na mea awaawa.
19 Bí mo bá sọ ti agbára, wò ó! Alágbára ni, tàbí ní ti ìdájọ́, ta ni yóò dá àkókò fún mi láti rò?
Ina [e olelo iho au] no ka ikaika, aia hoi, oia ka ikaika: A ina no ka hooponopono ana, Owai la ke hai mai i ka manawa?
20 Bí mo tilẹ̀ dá ara mi láre, ẹnu ara mi yóò dá mi lẹ́bi; bí mo wí pé olódodo ni èmi yóò sì fi mí hàn ní ẹni ẹ̀bi.
Ina owau e hoapono ia'u iho, hoohewa mai kuu waha ia'u; Ina [olelo iho au, ] Ua hala ole, ina ua hookahuli mai ia ia'u.
21 “Olóòótọ́ ni mo ṣe, síbẹ̀ èmi kò kíyèsi ara mi, ayé mi ní èmi ìbá máa gàn.
Ina ua hala ole au, aole hoi au e ike i kuu uhane: E hoowahawaha no au i kuu ola.
22 Ohùn kan náà ni, nítorí náà ni èmi ṣe sọ: ‘Òun a pa ẹni òtítọ́ àti ènìyàn búburú pẹ̀lú.’
Ua hookahi no ia, nolaila e olelo aku au, Ke luku nei no ia i ka mea hala ole a me ka mea hewa.
23 Bí ìjàǹbá bá pa ni lójijì, yóò rẹ́rìn-ín nínú ìdààmú aláìṣẹ̀.
Ina e pepehi koke mai ka mea uhau, E akaaka mai no ia i ka eha ana o ka poe hala ole.
24 Nígbà tí a bá fi ayé lé ọwọ́ ènìyàn búburú; ó sì bo àwọn onídàájọ́ rẹ̀ lójú; bí kò bá rí bẹ́ẹ̀ ǹjẹ́ ta ni?
Ua haawiia'ku ka honua iloko o ka lima o ka poe hewa: Ua uhi mai ia i na maka o kona mau lunakanawai; A i ole ia, auhea la, owai la hoi oia?
25 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí ọjọ́ mi yára ju oníṣẹ́ lọ, wọ́n fò lọ, wọn kò rí ayọ̀.
Ua oi ka mama o kuu mau la mamua o ka mea holo: Ke holo ae nei lakou, Ke ike ole nei lakou i ka maikai.
26 Wọ́n kọjá lọ bí ọkọ̀ eèsún papirusi tí ń sáré lọ; bí idì tí ń yára si ohùn ọdẹ.
Ua hala aku la lakou e like me na moku holo: E like me ka aeto e lele ana i ka mea ai.
27 Bí èmi bá wí pé, ‘Èmi ó gbàgbé arò ìbìnújẹ́ mi, èmi ó fi ọkàn lélẹ̀, èmi ó sì rẹ ara mi lẹ́kún.’
Ina olelo iho au, e hoopoina no wau i kuu kanikau ana, E waiho aku au i kuu maka kaumaha, a e hooluolu ia'u iho;
28 Ẹ̀rù ìbànújẹ́ mi gbogbo bà mí, èmi mọ̀ pé ìwọ kì yóò mú mi bí aláìṣẹ̀.
Makau iho la au i kuu mea ehaeha a pau, Ua ike au, aole oe e hoapono mai ia'u, he hala ole.
29 Bí ó bá ṣe pé ènìyàn búburú ni èmi, ǹjẹ́ kí ni èmi ń ṣe làálàá lásán sí?
Ina ua hewa au, No ke aha la hoi wau e luhi make hewa nei?
30 Bí mo tilẹ̀ fi ọṣẹ dídì wẹ ara mi, tí mo fi omi aró wẹ ọwọ́ mi mọ́,
Ina e holoi au ia'u iho i ka wai hau, A e hoomaemae au i kuu mau lima i ka sopa;
31 síbẹ̀ ìwọ ó gbé mi wọ inú ihò ọ̀gọ̀dọ̀ aṣọ ara mi yóò sọ mi di ìríra.
Alaila, e kiola iho oe ia'u iloko o ka lua lepo, A e hoopailua ko'u mau kapa ia'u.
32 “Nítorí Òun kì í ṣe ènìyàn bí èmi, tí èmi ó fi dá a lóhùn tí àwa o fi pàdé ní ìdájọ́.
No ka mea, aole ia he kanaka e like me au, e paio aku ai au ia ia, A halawai maua i ka hookolokolo ana.
33 Bẹ́ẹ̀ ni kò sí alátúnṣe kan ní agbede-méjì wa tí ìbá fi ọwọ́ rẹ̀ lé àwa méjèèjì lára.
Aole hoi he mea nana e uwao iwaena o maua, I kau mai ai ia i kona lima maluna o maua elua.
34 Kí ẹnìkan sá à mú ọ̀pá Ọlọ́run kúrò lára mi, kí ìbẹ̀rù rẹ̀ kí ó má sì ṣe dáyà fò mí.
E lawe aku ia i kona kookoo mai o'u aku nei, A mai hooweliweli mai kona makau ia'u.
35 Nígbà náà ni èmi ìbá sọ̀rọ̀, èmi kì bá sì bẹ̀rù rẹ̀; ṣùgbọ́n bí ó tí dúró tì mí, kò ri bẹ́ẹ̀ fún mi.
Alaila e olelo aku au, aole hoi wau e makau ia ia, Aka, aole pela wau ia'u iho.

< Job 9 >