< Job 9 >

1 Jobu sì dáhùn ó sì wí pé,
Ningĩ Ayubu agĩcookia, akiuga atĩrĩ:
2 “Èmi mọ̀ pe bẹ́ẹ̀ ni ní òtítọ́. Báwo ní ènìyàn yóò ha ti ṣe jẹ́ aláre níwájú Ọlọ́run?
“Ti-itherũ nĩnjũũĩ ũhoro ũcio nĩ wa ma. No rĩrĩ, mũndũ angĩhota atĩa gũkorwo arĩ mũthingu mbere ya Mũrungu?
3 Bí ó bá ṣe pé yóò bá a jà, òun kì yóò lè dalóhùn kan nínú ẹgbẹ̀rún ọ̀rọ̀.
O na korwo mũndũ enda gũkararania na Ngai-rĩ, ndangĩhota kũmũcookeria kĩũria o na kĩmwe harĩ ciũria ngiri.
4 Ọlọ́gbọ́n nínú àwọn alágbára ní ipa ní Òun. Ta ni ó ṣe agídí sí i tí ó sì gbé fún rí?
Ũũgĩ wake nĩ mũingĩ mũno, na ũhoti wake nĩ mũnene. Nũũ wanaregana nake akĩgaacĩra?
5 Ẹni tí ó sí òkè nídìí tí wọn kò sì mọ́: tí ó taari wọn ṣubú ní ìbínú rẹ̀.
Eeheragia irĩma itekũmenya, na agacingʼaũrania nĩ kũrakara.
6 Tí ó mi ilẹ̀ ayé tìtì kúrò ní ipò rẹ̀, ọwọ̀n rẹ̀ sì mì tìtì.
Athingithagia thĩ ĩkoima handũ hayo, na akainainia itugĩ ciayo.
7 Ó pàṣẹ fún oòrùn kò sì le è ràn, kí ó sì dí ìmọ́lẹ̀ ìràwọ̀ mọ́.
Aathaga riũa rĩkaaga kũratha; nake agiragĩrĩria ũtheri wa njata.
8 Òun nìkan ṣoṣo ni ó ta ojú ọ̀run, ti ó sì ń rìn lórí ìgbì Òkun.
Nĩwe watambũrũkirie igũrũ arĩ o wiki, na athiiaga agĩkinyangaga makũmbĩ ma iria.
9 Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Beari àti Orioni, Pleiadesi àti ìràwọ̀ púpọ̀ ti gúúsù.
Nĩwe Mũũmbi wa njata iria ciĩtagwo Nduba, na Karaũ, na Kĩrĩmĩra, o na ikundi cia njata cia mwena wa gũthini.
10 Ẹni tí ń ṣe ohun tí ó tóbi jù àwárí lọ, àní ohun ìyanu láìní iye.
Nĩekaga magegania matangĩmenyeka, na akaringa ciama itangĩtarĩka.
11 Kíyèsi i, ó ń kọjá lọ ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ mi, èmi kò sì rí i, ó sì kọjá síwájú, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò rí ojú rẹ̀.
Rĩrĩa aahĩtũkĩra harĩa ndĩ, ndingĩmuona; o na rĩrĩa aathiĩra harĩa ndĩ ndimenyaga.
12 Kíyèsi i, ó já a gbà lọ, ta ni ó lè fà á padà? Ta ni yóò bi í pé kí ni ìwọ ń ṣe nì?
Angĩgutha kĩndũ-rĩ, nũũ ũngĩhota kũmũgiria? Nũũ ũngĩmũũria atĩrĩ, ‘Nĩ atĩa ũreka?’
13 Ọlọ́run kò ní fa ìbínú rẹ̀ sẹ́yìn, àwọn onírànlọ́wọ́ ti Rahabu a sì tẹríba lábẹ́ rẹ̀.
Ngai ndahingagĩrĩria marakara make; o na arĩa maateithagĩrĩria Rahabu nĩmamũinamagĩrĩra.
14 “Kí ní ṣe tí èmi ti n o fi ba ṣàròyé? Tí èmi yóò fi ma ṣe àwáwí?
“Niĩ-rĩ, ndaakĩhota atĩa kũmũkararia? Ingĩruta kũ ciugo cia kũmũcookeria?
15 Bí ó tilẹ̀ ṣe pé mo ṣe aláìlẹ́bi, èmi kò gbọdọ̀ dá a lóhùn; ṣùgbọ́n èmi ó gbàdúrà fún àánú.
O na korwo ndihĩtĩtie-rĩ, ndingĩhota kũmũcookeria ũndũ; ũrĩa ingĩĩka no gũthaitha ingĩthaitha Mũnjiirithia anjiguĩre tha.
16 Bí èmi bá sì ké pè é, tí Òun sì dá mi lóhùn, èmi kì yóò sì gbàgbọ́ pé, Òun ti fetí sí ohùn mi.
O na ingĩamwĩtire nake anjĩtĩke-rĩ, ndingĩĩtĩkia nĩangĩathikĩrĩirie.
17 Nítorí pé òun yóò lọ̀ mí lúúlúú pẹ̀lú ìjì ńlá, ó sọ ọgbẹ́ mi di púpọ̀ láìnídìí.
We angĩamemendire na kĩhuhũkanio, na aingĩhie ironda ciakwa hatarĩ gĩtũmi.
18 Òun kì yóò jẹ́ kí èmi kí ó rí ẹ̀mí mi, ṣùgbọ́n ó mú ohun kíkorò kún un fún mi.
Ndarekaga njookererwo nĩ mĩhũmũ, no nĩahatagĩrĩria na mathĩĩna.
19 Bí mo bá sọ ti agbára, wò ó! Alágbára ni, tàbí ní ti ìdájọ́, ta ni yóò dá àkókò fún mi láti rò?
Korwo no ũhoro wa hinya-rĩ, we arĩ hinya mũno! Na korwo no ũhoro wa ciira wa kĩhooto-rĩ, nũũ ũngĩmwĩta?
20 Bí mo tilẹ̀ dá ara mi láre, ẹnu ara mi yóò dá mi lẹ́bi; bí mo wí pé olódodo ni èmi yóò sì fi mí hàn ní ẹni ẹ̀bi.
O na korwo ndiahĩtĩtie-rĩ, kanua gakwa no kandue mũhĩtia; korwo ndiarĩ na ũcuuke-rĩ, nĩkangĩanduire mũhĩtia.
21 “Olóòótọ́ ni mo ṣe, síbẹ̀ èmi kò kíyèsi ara mi, ayé mi ní èmi ìbá máa gàn.
“O na gũtuĩka ndirĩ na ũcuuke-rĩ, ndikwĩrĩrĩra; muoyo wakwa nĩndĩwagĩire kĩene.
22 Ohùn kan náà ni, nítorí náà ni èmi ṣe sọ: ‘Òun a pa ẹni òtítọ́ àti ènìyàn búburú pẹ̀lú.’
Ũhoro no ũrĩa ũmwe; nĩkĩo ndĩroiga atĩrĩ, ‘Aniinaga arĩa matarĩ ũcuuke o na akaniina arĩa aaganu.’
23 Bí ìjàǹbá bá pa ni lójijì, yóò rẹ́rìn-ín nínú ìdààmú aláìṣẹ̀.
Hĩndĩ ĩrĩa ihũũra rĩarehe gĩkuũ kĩa narua, nĩathekagĩrĩra kũũrwo nĩ hinya kwa arĩa matarĩ na mahĩtia.
24 Nígbà tí a bá fi ayé lé ọwọ́ ènìyàn búburú; ó sì bo àwọn onídàájọ́ rẹ̀ lójú; bí kò bá rí bẹ́ẹ̀ ǹjẹ́ ta ni?
Hĩndĩ ĩrĩa bũrũri wagĩa moko-inĩ ma andũ aaganu, nĩahingaga aciirithania maitho. Akorwo ti we-rĩ, nũũ wĩkaga ũguo?
25 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí ọjọ́ mi yára ju oníṣẹ́ lọ, wọ́n fò lọ, wọn kò rí ayọ̀.
“Matukũ makwa marahanyũka gũkĩra mũkinyia-ũhoro; mombũkaga matarĩ na gĩkeno o na kĩnini.
26 Wọ́n kọjá lọ bí ọkọ̀ eèsún papirusi tí ń sáré lọ; bí idì tí ń yára si ohùn ọdẹ.
Mahĩtũkaga na ihenya mũno ta tũtarũ twa irura, kana ta nderi igũcuuhũkĩra kĩndũ gĩa kũrĩa.
27 Bí èmi bá wí pé, ‘Èmi ó gbàgbé arò ìbìnújẹ́ mi, èmi ó fi ọkàn lélẹ̀, èmi ó sì rẹ ara mi lẹ́kún.’
Ingiuga atĩrĩ, ‘Nĩngũriganĩrwo nĩ mateta makwa, nĩngũtiga gũtukia gĩthiithi, ngene,’
28 Ẹ̀rù ìbànújẹ́ mi gbogbo bà mí, èmi mọ̀ pé ìwọ kì yóò mú mi bí aláìṣẹ̀.
no ngeetigĩra mĩnyamaro yakwa yothe, nĩgũkorwo nĩnjũũĩ ndũkandua atĩ ndiĩhĩtie.
29 Bí ó bá ṣe pé ènìyàn búburú ni èmi, ǹjẹ́ kí ni èmi ń ṣe làálàá lásán sí?
Kuona atĩ nĩndĩkĩtie gũtuuo mũhĩtia-rĩ, nĩ kĩĩ gĩgũtũma ndĩĩnogie tũhũ?
30 Bí mo tilẹ̀ fi ọṣẹ dídì wẹ ara mi, tí mo fi omi aró wẹ ọwọ́ mi mọ́,
O na ingĩĩthamba na thabuni, na ndĩĩthambe moko na igata-rĩ,
31 síbẹ̀ ìwọ ó gbé mi wọ inú ihò ọ̀gọ̀dọ̀ aṣọ ara mi yóò sọ mi di ìríra.
no ũndikirie irima rĩa gĩcoro nĩgeetha o na nguo ciakwa iithũũre.
32 “Nítorí Òun kì í ṣe ènìyàn bí èmi, tí èmi ó fi dá a lóhùn tí àwa o fi pàdé ní ìdájọ́.
“We ti mũndũ ta niĩ atĩ nĩguo ndĩmũcookerie, nĩguo tũngʼethanĩre igooti-inĩ.
33 Bẹ́ẹ̀ ni kò sí alátúnṣe kan ní agbede-méjì wa tí ìbá fi ọwọ́ rẹ̀ lé àwa méjèèjì lára.
Naarĩ korwo nĩ harĩ mũndũ ũngĩtũiguithania, atũigĩrĩre guoko gwake ithuĩ eerĩ,
34 Kí ẹnìkan sá à mú ọ̀pá Ọlọ́run kúrò lára mi, kí ìbẹ̀rù rẹ̀ kí ó má sì ṣe dáyà fò mí.
mũndũ wa kũnjehereria rũthanju rwa Ngai, nĩgeetha ndigacooke kũmakio nĩ itebeebania rĩake.
35 Nígbà náà ni èmi ìbá sọ̀rọ̀, èmi kì bá sì bẹ̀rù rẹ̀; ṣùgbọ́n bí ó tí dúró tì mí, kò ri bẹ́ẹ̀ fún mi.
Hĩndĩ ĩyo nĩingĩacooka kwaragia itekũmwĩtigĩra, no ũrĩa ndariĩ rĩu-rĩ, ndingĩhota.

< Job 9 >