< Job 8 >

1 Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, sì dáhùn wí pé,
Na Suhini Bildad buae se:
2 “Ìwọ yóò ti máa sọ nǹkan wọ̀nyí pẹ́ tó? Tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ yóò sì máa bí ẹ̀fúùfù ńlá?
“Wobɛkɔ so aka saa nsɛm yi akosi da bɛn? Wo nsɛm yɛ mframa huhuw.
3 Ọlọ́run a ha máa yí ìdájọ́ po bí? Tàbí Olódùmarè a máa gbé ẹ̀bi fún aláre?
Onyankopɔn kyea atɛntrenee ana? Otumfo kyea nea ɛteɛ ana?
4 Nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣẹ̀ sí i, ó sì gbá wọn kúrò nítorí ìrékọjá wọn.
Bere a wo mma yɛɛ bɔne tiaa no no, ogyaw wɔn maa wɔn bɔne so akatua.
5 Bí ìwọ bá sì ké pe Ọlọ́run ní àkókò, tí ìwọ sì gbàdúrà ẹ̀bẹ̀ sí Olódùmarè.
Nanso sɛ wode wʼani bɛto Onyankopɔn so na woabɔ Otumfo no mpae,
6 Ìwọ ìbá jẹ́ mímọ, kí ó sì dúró ṣinṣin: ǹjẹ́ nítòótọ́ nísinsin yìí òun yóò tají fún ọ, òun a sì sọ ibùjókòó òdodo rẹ di púpọ̀.
sɛ woyɛ kronkron, na woteɛ a, wo nti, ɔbɛma ne ho so mprempren na wama wo asi wo dedaw mu.
7 Ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ ìbá tilẹ̀ kéré si í, bẹ́ẹ̀ ìgbẹ̀yìn rẹ ìbá pọ̀ sí i gidigidi.
Wo mfiase bɛyɛ nkakrankakra na daakye woanya ama abu so.
8 “Èmi bẹ̀ ọ́ ǹjẹ́, béèrè lọ́wọ́ àwọn ará ìgbà nì kí o sì kíyèsi ìwádìí àwọn baba wọn.
“Bisa awo ntoatoaso a atwa mu no, na hwehwɛ nea wɔn agyanom hui,
9 Nítorí pé ọmọ-àná ni àwa, a kò sì mọ nǹkan, nítorí pé òjìji ni ọjọ́ wa ni ayé.
na wɔwoo yɛn nkyɛe na yennim hwee, yɛn nna wɔ asase yi so te sɛ sunsuma.
10 Àwọn kì yóò wa kọ ọ́, wọn kì yóò sì sọ fún ọ? Wọn kì yóò sì sọ̀rọ̀ láti inú òye wọn jáde wá?
Wɔrenkyerɛkyerɛ wo na wɔrenka nkyerɛ wo ana? Wɔremfi wɔn ntease mu nka nsɛm bi ana?
11 Papirusi ha lè dàgbà láìní ẹrẹ̀ tàbí eèsún ha lè dàgbà láìlómi?
So paparɔso betumi anyin akɔ soro wɔ baabi a ɛnyɛ ɔwora? Demmire betumi afifi baabi a nsu nni ana?
12 Nígbà tí ó wà ní tútù, tí a kò ké e lulẹ̀, ó rọ dànù, ewéko gbogbo mìíràn hù dípò rẹ̀.
Bere a ɛrenyin a wontwae no, ɛhyew ntɛm so sen sare.
13 Bẹ́ẹ̀ ni ipa ọ̀nà gbogbo àwọn tí ó gbàgbé Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ìrètí àwọn àgàbàgebè yóò di òfo.
Saa na wɔn a wɔn werɛ fi Onyankopɔn no awiei te; saa ara na wɔn a wonni nyamesu no anidaso nkosi hwee.
14 Àbá ẹni tí a ó kèé kúrò, àti ìgbẹ́kẹ̀lé ẹni tí ó dàbí ilé aláǹtakùn.
Biribiara a nʼani da so no nni ahoɔden; nea ɔde ne ho to so no yɛ ananse ntontan.
15 Yóò fi ara ti ilé rẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró, yóò fi di ara rẹ̀ mú ṣinṣin ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró pẹ́.
Otweri ne ntontan, nanso ɛtetew; oso mu dennen, nanso ɛnyɛ yie.
16 Ó tutù bí irúgbìn tí a bomirin níwájú oòrùn, ẹ̀ka rẹ̀ sì yọ jáde nínú ọgbà rẹ̀.
Ɔte sɛ afifide a wogugu so nsu yiye a esi owia mu, ɛtrɛtrɛw ne mman mu wɔ turo no so;
17 Gbòǹgbò rẹ̀ ta yí ebè ká, ó sì wó ibi òkúta wọ̀n-ọn-nì.
Ne ntin nyin fa abotan ho, na ɛhwehwɛ ɔkwan kɔ abo mu.
18 Bí ó bá sì pa á run kúrò ní ipò rẹ̀, nígbà náà ni ipò náà yóò sọ, ‘Èmi kò ri ọ rí!’
Nanso sɛ wotu fi ne sibea a, saa beae no nnim no bio na ɛka se, ‘Minhuu wo da.’
19 Kíyèsi i, ayé rẹ̀ gbẹ dànù àti láti inú ilẹ̀ ní irúgbìn òmíràn yóò hù jáde wá.
Ampa ara ne nkwa twa mu, na afifide foforo nyin asase no so.
20 “Kíyèsi i, Ọlọ́run kì yóò ta ẹni òtítọ́ nù, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ran oníwà búburú lọ́wọ́
“Ampa ara Onyankopɔn mpo onipa a ne ho nni asɛm na ɔnhyɛ amumɔyɛfo nsa mu den.
21 títí yóò fi fi ẹ̀rín kún ọ ní ẹnu, àti ètè rẹ pẹ̀lú ìhó ayọ̀,
Ɔbɛma woaserew bio, na wode ahosɛpɛw ateɛteɛ mu.
22 ìtìjú ní a o fi bo àwọn tí ó kórìíra rẹ̀, àti ibùjókòó ènìyàn búburú kì yóò sí mọ́.”
Wɔde aniwu befura wɔn a wɔtan wo, na amumɔyɛfo ntamadan bɛsɛe.”

< Job 8 >