< Job 8 >

1 Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, sì dáhùn wí pé,
Wtedy Bildad z Szuach odpowiedział:
2 “Ìwọ yóò ti máa sọ nǹkan wọ̀nyí pẹ́ tó? Tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ yóò sì máa bí ẹ̀fúùfù ńlá?
Jak długo będziesz mówił takie rzeczy? [Jak długo] słowa z twoich ust [będą jak] gwałtowny wiatr?
3 Ọlọ́run a ha máa yí ìdájọ́ po bí? Tàbí Olódùmarè a máa gbé ẹ̀bi fún aláre?
Czy Bóg wypacza sąd? Czy Wszechmocny wypacza sprawiedliwość?
4 Nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣẹ̀ sí i, ó sì gbá wọn kúrò nítorí ìrékọjá wọn.
Jeśli twoi synowie zgrzeszyli przeciwko niemu, a on ich odrzucił za ich nieprawość;
5 Bí ìwọ bá sì ké pe Ọlọ́run ní àkókò, tí ìwọ sì gbàdúrà ẹ̀bẹ̀ sí Olódùmarè.
Jeśli zwrócisz się pilnie do Boga i będziesz błagać Wszechmocnego;
6 Ìwọ ìbá jẹ́ mímọ, kí ó sì dúró ṣinṣin: ǹjẹ́ nítòótọ́ nísinsin yìí òun yóò tají fún ọ, òun a sì sọ ibùjókòó òdodo rẹ di púpọ̀.
Jeśli jesteś czysty i prawy, wtedy na pewno obudzi się dla ciebie i poszczęści mieszkaniu twojej sprawiedliwości.
7 Ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ ìbá tilẹ̀ kéré si í, bẹ́ẹ̀ ìgbẹ̀yìn rẹ ìbá pọ̀ sí i gidigidi.
A [choćby] twój początek był niewielki, jednak twój koniec bardzo się rozmnoży.
8 “Èmi bẹ̀ ọ́ ǹjẹ́, béèrè lọ́wọ́ àwọn ará ìgbà nì kí o sì kíyèsi ìwádìí àwọn baba wọn.
Bo zapytaj, proszę, dawnych pokoleń i rozważ doświadczenie ich ojców;
9 Nítorí pé ọmọ-àná ni àwa, a kò sì mọ nǹkan, nítorí pé òjìji ni ọjọ́ wa ni ayé.
(My bowiem jesteśmy wczorajsi i nic nie wiemy, ponieważ nasze dni na ziemi są [jak] cień).
10 Àwọn kì yóò wa kọ ọ́, wọn kì yóò sì sọ fún ọ? Wọn kì yóò sì sọ̀rọ̀ láti inú òye wọn jáde wá?
Czy oni nie pouczą cię i nie powiedzą ci, i czy z ich serc nie wypłyną słowa?
11 Papirusi ha lè dàgbà láìní ẹrẹ̀ tàbí eèsún ha lè dàgbà láìlómi?
Czy sitowie urośnie bez wilgoci? Czy trzcina urośnie bez wody?
12 Nígbà tí ó wà ní tútù, tí a kò ké e lulẹ̀, ó rọ dànù, ewéko gbogbo mìíràn hù dípò rẹ̀.
Chociaż jeszcze jest świeża i nieskoszona, prędzej usycha niż inna trawa.
13 Bẹ́ẹ̀ ni ipa ọ̀nà gbogbo àwọn tí ó gbàgbé Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ìrètí àwọn àgàbàgebè yóò di òfo.
Takie [są] drogi wszystkich, którzy zapominają Boga, i [tak] zginie nadzieja obłudnika.
14 Àbá ẹni tí a ó kèé kúrò, àti ìgbẹ́kẹ̀lé ẹni tí ó dàbí ilé aláǹtakùn.
Jego nadzieja zostanie podcięta, a jego ufność [będzie] jak pajęczyna.
15 Yóò fi ara ti ilé rẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró, yóò fi di ara rẹ̀ mú ṣinṣin ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró pẹ́.
Oprze się o swój dom, ale się nie ostoi; uchwyci się go, ale nie przetrwa.
16 Ó tutù bí irúgbìn tí a bomirin níwájú oòrùn, ẹ̀ka rẹ̀ sì yọ jáde nínú ọgbà rẹ̀.
Zieleni się na słońcu i w ogrodzie jego świeża latorośl wyrasta.
17 Gbòǹgbò rẹ̀ ta yí ebè ká, ó sì wó ibi òkúta wọ̀n-ọn-nì.
Jego korzenie są splątane wśród kamieni i wyrastają spośród nich.
18 Bí ó bá sì pa á run kúrò ní ipò rẹ̀, nígbà náà ni ipò náà yóò sọ, ‘Èmi kò ri ọ rí!’
Ale gdy go wyrwą z jego miejsca, wtedy miejsce to wyprze się go, [mówiąc]: Nie widziałem cię.
19 Kíyèsi i, ayé rẹ̀ gbẹ dànù àti láti inú ilẹ̀ ní irúgbìn òmíràn yóò hù jáde wá.
Takie oto [jest] szczęście jego drogi, a z ziemi wyrosną inni.
20 “Kíyèsi i, Ọlọ́run kì yóò ta ẹni òtítọ́ nù, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ran oníwà búburú lọ́wọ́
Oto Bóg nie odrzuci [człowieka] prawego, ale złoczyńcom nie poda ręki;
21 títí yóò fi fi ẹ̀rín kún ọ ní ẹnu, àti ètè rẹ pẹ̀lú ìhó ayọ̀,
Aż się napełnią twoje usta uśmiechem, a twoje wargi radością.
22 ìtìjú ní a o fi bo àwọn tí ó kórìíra rẹ̀, àti ibùjókòó ènìyàn búburú kì yóò sí mọ́.”
Gdyż ci, którzy cię nienawidzą, okryją się hańbą, a namiotu niegodziwych [już] nie będzie.

< Job 8 >