< Job 8 >

1 Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, sì dáhùn wí pé,
پس بلدد شوحی در جواب گفت:۱
2 “Ìwọ yóò ti máa sọ nǹkan wọ̀nyí pẹ́ tó? Tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ yóò sì máa bí ẹ̀fúùfù ńlá?
«تا به کی این چیزها را خواهی گفت و سخنان دهانت باد شدید خواهد بود؟۲
3 Ọlọ́run a ha máa yí ìdájọ́ po bí? Tàbí Olódùmarè a máa gbé ẹ̀bi fún aláre?
آیا خداوندداوری را منحرف سازد؟ یا قادر مطلق انصاف رامنحرف نماید؟۳
4 Nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣẹ̀ sí i, ó sì gbá wọn kúrò nítorí ìrékọjá wọn.
چون فرزندان تو به او گناه ورزیدند، ایشان را به‌دست عصیان ایشان تسلیم نمود.۴
5 Bí ìwọ bá sì ké pe Ọlọ́run ní àkókò, tí ìwọ sì gbàdúrà ẹ̀bẹ̀ sí Olódùmarè.
اگر تو به جد و جهد خدا را طلب می‌کردی و نزد قادر مطلق تضرع می‌نمودی،۵
6 Ìwọ ìbá jẹ́ mímọ, kí ó sì dúró ṣinṣin: ǹjẹ́ nítòótọ́ nísinsin yìí òun yóò tají fún ọ, òun a sì sọ ibùjókòó òdodo rẹ di púpọ̀.
اگر پاک و راست می‌بودی، البته برای تو بیدارمی شد، و مسکن عدالت تو را برخوردارمی ساخت.۶
7 Ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ ìbá tilẹ̀ kéré si í, bẹ́ẹ̀ ìgbẹ̀yìn rẹ ìbá pọ̀ sí i gidigidi.
و اگر‌چه ابتدایت صغیر می‌بود، عاقبت تو بسیار رفیع می‌گردید.۷
8 “Èmi bẹ̀ ọ́ ǹjẹ́, béèrè lọ́wọ́ àwọn ará ìgbà nì kí o sì kíyèsi ìwádìí àwọn baba wọn.
زیرا که ازقرنهای پیشین سوال کن، و به آنچه پدران ایشان تفحص کردند توجه نما،۸
9 Nítorí pé ọmọ-àná ni àwa, a kò sì mọ nǹkan, nítorí pé òjìji ni ọjọ́ wa ni ayé.
چونکه ما دیروزی هستیم و هیچ نمی دانیم، و روزهای ما سایه‌ای برروی زمین است.۹
10 Àwọn kì yóò wa kọ ọ́, wọn kì yóò sì sọ fún ọ? Wọn kì yóò sì sọ̀rọ̀ láti inú òye wọn jáde wá?
آیا ایشان تو را تعلیم ندهند وبا تو سخن نرانند؟ و از دل خود کلمات بیرون نیارند؟۱۰
11 Papirusi ha lè dàgbà láìní ẹrẹ̀ tàbí eèsún ha lè dàgbà láìlómi?
آیا نی، بی‌خلاب می‌روید، یا قصب، بی‌آب نمو می‌کند؟۱۱
12 Nígbà tí ó wà ní tútù, tí a kò ké e lulẹ̀, ó rọ dànù, ewéko gbogbo mìíràn hù dípò rẹ̀.
هنگامی که هنوز سبزاست و بریده نشده، پیش از هر گیاه خشک می‌شود.۱۲
13 Bẹ́ẹ̀ ni ipa ọ̀nà gbogbo àwọn tí ó gbàgbé Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ìrètí àwọn àgàbàgebè yóò di òfo.
همچنین است راه جمیع فراموش کنندگان خدا. و امید ریاکار ضایع می شود،۱۳
14 Àbá ẹni tí a ó kèé kúrò, àti ìgbẹ́kẹ̀lé ẹni tí ó dàbí ilé aláǹtakùn.
که امید او منقطع می‌شود، واعتمادش خانه عنکبوت است.۱۴
15 Yóò fi ara ti ilé rẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró, yóò fi di ara rẹ̀ mú ṣinṣin ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró pẹ́.
بر خانه خودتکیه می‌کند و نمی ایستد، به آن متمسک می‌شودو لیکن قایم نمی ماند.۱۵
16 Ó tutù bí irúgbìn tí a bomirin níwájú oòrùn, ẹ̀ka rẹ̀ sì yọ jáde nínú ọgbà rẹ̀.
پیش روی آفتاب، تر وتازه می‌شود و شاخه هایش در باغش پهن می‌گردد.۱۶
17 Gbòǹgbò rẹ̀ ta yí ebè ká, ó sì wó ibi òkúta wọ̀n-ọn-nì.
ریشه هایش بر توده های سنگ درهم بافته می‌شود، و بر سنگلاخ نگاه می‌کند.۱۷
18 Bí ó bá sì pa á run kúrò ní ipò rẹ̀, nígbà náà ni ipò náà yóò sọ, ‘Èmi kò ri ọ rí!’
اگر ازجای خود کنده شود، او را انکار کرده، می‌گوید: تو را نمی بینم.۱۸
19 Kíyèsi i, ayé rẹ̀ gbẹ dànù àti láti inú ilẹ̀ ní irúgbìn òmíràn yóò hù jáde wá.
اینک خوشی طریقش همین است و دیگران از خاک خواهند رویید.۱۹
20 “Kíyèsi i, Ọlọ́run kì yóò ta ẹni òtítọ́ nù, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ran oníwà búburú lọ́wọ́
هماناخدا مرد کامل را حقیر نمی شمارد، و شریر رادستگیری نمی نماید،۲۰
21 títí yóò fi fi ẹ̀rín kún ọ ní ẹnu, àti ètè rẹ pẹ̀lú ìhó ayọ̀,
تا دهان تو را از خنده پرکند، و لبهایت را از آواز شادمانی.۲۱
22 ìtìjú ní a o fi bo àwọn tí ó kórìíra rẹ̀, àti ibùjókòó ènìyàn búburú kì yóò sí mọ́.”
خصمان توبه خجالت ملبس خواهند شد، و خیمه شریران نابود خواهد گردید.»۲۲

< Job 8 >