< Job 8 >
1 Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, sì dáhùn wí pé,
Alors Baldad de Suhé prit la parole et dit:
2 “Ìwọ yóò ti máa sọ nǹkan wọ̀nyí pẹ́ tó? Tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ yóò sì máa bí ẹ̀fúùfù ńlá?
Jusques à quand tiendras-tu ces discours, et tes paroles seront-elles comme un souffle de tempête?
3 Ọlọ́run a ha máa yí ìdájọ́ po bí? Tàbí Olódùmarè a máa gbé ẹ̀bi fún aláre?
Est-ce que Dieu fait fléchir le droit, ou bien le Tout-Puissant renverse-t-il la justice?
4 Nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣẹ̀ sí i, ó sì gbá wọn kúrò nítorí ìrékọjá wọn.
Si tes fils ont péché contre lui, il les a livrés aux mains de leur iniquité.
5 Bí ìwọ bá sì ké pe Ọlọ́run ní àkókò, tí ìwọ sì gbàdúrà ẹ̀bẹ̀ sí Olódùmarè.
Pour toi, si tu as recours à Dieu, si tu implores le Tout-Puissant,
6 Ìwọ ìbá jẹ́ mímọ, kí ó sì dúró ṣinṣin: ǹjẹ́ nítòótọ́ nísinsin yìí òun yóò tají fún ọ, òun a sì sọ ibùjókòó òdodo rẹ di púpọ̀.
si tu es droit et pur, alors il veillera sur toi, il rendra le bonheur à la demeure de ta justice;
7 Ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ ìbá tilẹ̀ kéré si í, bẹ́ẹ̀ ìgbẹ̀yìn rẹ ìbá pọ̀ sí i gidigidi.
ton premier état semblera peu de chose, tant le second sera florissant.
8 “Èmi bẹ̀ ọ́ ǹjẹ́, béèrè lọ́wọ́ àwọn ará ìgbà nì kí o sì kíyèsi ìwádìí àwọn baba wọn.
Interroge les générations passées, sois attentif à l’expérience des pères: —
9 Nítorí pé ọmọ-àná ni àwa, a kò sì mọ nǹkan, nítorí pé òjìji ni ọjọ́ wa ni ayé.
car nous sommes d’hier, et nous ne savons rien, nos jours sur la terre passent comme l’ombre; —
10 Àwọn kì yóò wa kọ ọ́, wọn kì yóò sì sọ fún ọ? Wọn kì yóò sì sọ̀rọ̀ láti inú òye wọn jáde wá?
ne vont-ils pas t’enseigner, te parler, et de leur cœur tirer des sentences:
11 Papirusi ha lè dàgbà láìní ẹrẹ̀ tàbí eèsún ha lè dàgbà láìlómi?
« Le papyrus croît-il en dehors des marais? Le jonc s’élève-t-il sans eau?
12 Nígbà tí ó wà ní tútù, tí a kò ké e lulẹ̀, ó rọ dànù, ewéko gbogbo mìíràn hù dípò rẹ̀.
Encore tendre, sans qu’on le coupe, il sèche avant toute herbe.
13 Bẹ́ẹ̀ ni ipa ọ̀nà gbogbo àwọn tí ó gbàgbé Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ìrètí àwọn àgàbàgebè yóò di òfo.
Telles sont les voies de tous ceux qui oublient Dieu; l’espérance de l’impie périra.
14 Àbá ẹni tí a ó kèé kúrò, àti ìgbẹ́kẹ̀lé ẹni tí ó dàbí ilé aláǹtakùn.
Sa confiance sera brisée; son assurance ressemble à la toile de l’araignée.
15 Yóò fi ara ti ilé rẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró, yóò fi di ara rẹ̀ mú ṣinṣin ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró pẹ́.
Il s’appuie sur sa maison, et elle ne tient pas; il s’y attache, et elle ne reste pas debout.
16 Ó tutù bí irúgbìn tí a bomirin níwájú oòrùn, ẹ̀ka rẹ̀ sì yọ jáde nínú ọgbà rẹ̀.
Il est plein de vigueur, au soleil, ses rameaux s’étendent sur son jardin,
17 Gbòǹgbò rẹ̀ ta yí ebè ká, ó sì wó ibi òkúta wọ̀n-ọn-nì.
ses racines s’entrelacent parmi les pierres, il plonge jusqu’aux profondeurs du roc.
18 Bí ó bá sì pa á run kúrò ní ipò rẹ̀, nígbà náà ni ipò náà yóò sọ, ‘Èmi kò ri ọ rí!’
Si Dieu l’arrache de sa place, sa place le renie: Je ne t’ai jamais vu.
19 Kíyèsi i, ayé rẹ̀ gbẹ dànù àti láti inú ilẹ̀ ní irúgbìn òmíràn yóò hù jáde wá.
C’est là que sa joie se termine, et du même sol d’autres s’élèveront après lui. »
20 “Kíyèsi i, Ọlọ́run kì yóò ta ẹni òtítọ́ nù, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ran oníwà búburú lọ́wọ́
Non, Dieu ne rejette pas l’innocent, il ne prend pas la main des malfaiteurs.
21 títí yóò fi fi ẹ̀rín kún ọ ní ẹnu, àti ètè rẹ pẹ̀lú ìhó ayọ̀,
Il remplira ta bouche d’éclats de rire, et mettra sur tes lèvres des chants d’allégresse.
22 ìtìjú ní a o fi bo àwọn tí ó kórìíra rẹ̀, àti ibùjókòó ènìyàn búburú kì yóò sí mọ́.”
Tes ennemis seront couverts de honte, et la tente des méchants disparaîtra.