< Job 8 >

1 Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, sì dáhùn wí pé,
Then Bildad the Shuhite answered,
2 “Ìwọ yóò ti máa sọ nǹkan wọ̀nyí pẹ́ tó? Tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ yóò sì máa bí ẹ̀fúùfù ńlá?
“How long will you speak these things? Shall the words of your mouth be a mighty wind?
3 Ọlọ́run a ha máa yí ìdájọ́ po bí? Tàbí Olódùmarè a máa gbé ẹ̀bi fún aláre?
Does God pervert justice? Or does the Almighty pervert righteousness?
4 Nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣẹ̀ sí i, ó sì gbá wọn kúrò nítorí ìrékọjá wọn.
If your children have sinned against him, he has delivered them into the hand of their disobedience.
5 Bí ìwọ bá sì ké pe Ọlọ́run ní àkókò, tí ìwọ sì gbàdúrà ẹ̀bẹ̀ sí Olódùmarè.
If you want to seek God diligently, make your supplication to the Almighty.
6 Ìwọ ìbá jẹ́ mímọ, kí ó sì dúró ṣinṣin: ǹjẹ́ nítòótọ́ nísinsin yìí òun yóò tají fún ọ, òun a sì sọ ibùjókòó òdodo rẹ di púpọ̀.
If you were pure and upright, surely now he would awaken for you, and make the habitation of your righteousness prosperous.
7 Ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ ìbá tilẹ̀ kéré si í, bẹ́ẹ̀ ìgbẹ̀yìn rẹ ìbá pọ̀ sí i gidigidi.
Though your beginning was small, yet your latter end would greatly increase.
8 “Èmi bẹ̀ ọ́ ǹjẹ́, béèrè lọ́wọ́ àwọn ará ìgbà nì kí o sì kíyèsi ìwádìí àwọn baba wọn.
“Please inquire of past generations. Find out about the learning of their fathers.
9 Nítorí pé ọmọ-àná ni àwa, a kò sì mọ nǹkan, nítorí pé òjìji ni ọjọ́ wa ni ayé.
(For we are but of yesterday, and know nothing, because our days on earth are a shadow.)
10 Àwọn kì yóò wa kọ ọ́, wọn kì yóò sì sọ fún ọ? Wọn kì yóò sì sọ̀rọ̀ láti inú òye wọn jáde wá?
Shall they not teach you, tell you, and utter words out of their heart?
11 Papirusi ha lè dàgbà láìní ẹrẹ̀ tàbí eèsún ha lè dàgbà láìlómi?
“Can the papyrus grow up without mire? Can the rushes grow without water?
12 Nígbà tí ó wà ní tútù, tí a kò ké e lulẹ̀, ó rọ dànù, ewéko gbogbo mìíràn hù dípò rẹ̀.
While it is yet in its greenness, not cut down, it withers before any other reed.
13 Bẹ́ẹ̀ ni ipa ọ̀nà gbogbo àwọn tí ó gbàgbé Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ìrètí àwọn àgàbàgebè yóò di òfo.
So are the paths of all who forget God. The hope of the godless man will perish,
14 Àbá ẹni tí a ó kèé kúrò, àti ìgbẹ́kẹ̀lé ẹni tí ó dàbí ilé aláǹtakùn.
whose confidence will break apart, whose trust is a spider’s web.
15 Yóò fi ara ti ilé rẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró, yóò fi di ara rẹ̀ mú ṣinṣin ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró pẹ́.
He will lean on his house, but it will not stand. He will cling to it, but it will not endure.
16 Ó tutù bí irúgbìn tí a bomirin níwájú oòrùn, ẹ̀ka rẹ̀ sì yọ jáde nínú ọgbà rẹ̀.
He is green before the sun. His shoots go out along his garden.
17 Gbòǹgbò rẹ̀ ta yí ebè ká, ó sì wó ibi òkúta wọ̀n-ọn-nì.
His roots are wrapped around the rock pile. He sees the place of stones.
18 Bí ó bá sì pa á run kúrò ní ipò rẹ̀, nígbà náà ni ipò náà yóò sọ, ‘Èmi kò ri ọ rí!’
If he is destroyed from his place, then it will deny him, saying, ‘I have not seen you.’
19 Kíyèsi i, ayé rẹ̀ gbẹ dànù àti láti inú ilẹ̀ ní irúgbìn òmíràn yóò hù jáde wá.
Behold, this is the joy of his way. Out of the earth, others will spring.
20 “Kíyèsi i, Ọlọ́run kì yóò ta ẹni òtítọ́ nù, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ran oníwà búburú lọ́wọ́
“Behold, God will not cast away a blameless man, neither will he uphold the evildoers.
21 títí yóò fi fi ẹ̀rín kún ọ ní ẹnu, àti ètè rẹ pẹ̀lú ìhó ayọ̀,
He will still fill your mouth with laughter, your lips with shouting.
22 ìtìjú ní a o fi bo àwọn tí ó kórìíra rẹ̀, àti ibùjókòó ènìyàn búburú kì yóò sí mọ́.”
Those who hate you will be clothed with shame. The tent of the wicked will be no more.”

< Job 8 >