< Job 7 >

1 “Ṣé ìjà kò ha si fún ènìyàn lórí ilẹ̀? Ọjọ́ rẹ̀ pẹ̀lú kò ha dàbí ọjọ́ alágbàṣe?
Izali czas nie jest zamierzony człowiekowi na ziemi? a jako dni najemnicze nie są dni jego?
2 Bí ọmọ ọ̀dọ̀ tí máa ń kánjú bojú wo òjìji, àti bí alágbàṣe ti í kánjú wo ọ̀nà owó iṣẹ́ rẹ̀.
Jako sługa pragnie cienia, a jako najemnik czeka końca pracy swojej:
3 Bẹ́ẹ̀ ni a mú mi ní ìbànújẹ́ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oṣù, òru ìdáni-lágara ni a sì là sílẹ̀ fún mi.
Takiem ja prawem dziedzicznem wziął miesiące próżne, a nocy boleśne są mi naznaczone.
4 Nígbà ti mo dùbúlẹ̀, èmi wí pé, ‘Nígbà wo ni èmi ó dìde?’ Tí òru yóò sì kọjá, ó sì tó fún mi láti yí síyìn-ín yí sọ́hùn-ún, títí yóò fi di àfẹ̀mọ́júmọ́.
Układęli się, tedy mówię: Kiedyż wstanę? a rychło pominie noc? i pełen bywam myślenia aż do świtania.
5 Kòkòrò àti ògúlùtu erùpẹ̀ ni á fi wọ̀ mi ni aṣọ, awọ ara mi bù, o sì di bíbàjẹ́.
Obleczone jest ciało moje w robaki i w plugastwo z prochu; skóra moja popadała się, i rozsiadła się.
6 “Ọjọ́ mi yára jù ọkọ̀ ìhunṣọ lọ, o sì di lílò ní àìní ìrètí.
Dni moje prędsze są, niż czółnek tkacki, i strawione są bez nadziei.
7 Háà! Rántí pé afẹ́fẹ́ ni ẹ̀mí mi; ojú mi kì yóò padà rí rere mọ́.
Wspomnij, o Panie! iż wiatrem jest żywot mój, nie wróci się oko moje, aby widziało dobre rzeczy.
8 Ojú ẹni tí ó rí mi, kì yóò rí mi mọ́; ojú rẹ̀ tẹ̀ mọ́ra mi, èmi kò sí mọ́.
Ani mię ogląda oko, które mię widywało; oczy twoje obrócone będą na mię, a mnie nie będzie.
9 Bí ìkùùkuu tí i túká, tí í sì fò lọ, bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sí ipò òkú tí kì yóò padà wa mọ́. (Sheol h7585)
Jako niszczeje obłok i przemija, tak zstępujący do grobu nie wynijdzie; (Sheol h7585)
10 Kì yóò padà sínú ilé rẹ̀ mọ́, bẹ́ẹ̀ ní ipò rẹ̀ kì yóò mọ̀ ọn mọ́.
Nie wróci się więcej do domu swego, ani go więcej pozna miejsce jego.
11 “Nítorí náà èmi kì yóò pa ẹnu mi mọ́, èmi yóò máa sọ nínú ìrora ọkàn mi, èmi yóò máa ṣe ìráhùn nínú kíkorò ọkàn mi.
Przetoż ja nie mogę zawściągnąć ust moich; mówić będę w utrapieniu ducha mego, będę rozmawiał w gorzkości duszy mojej.
12 Èmi a máa ṣe Òkun tàbí ẹ̀mí búburú, tí ìwọ fi ń yan olùṣọ́ tì mi?
Izażem ja jest morze, albo wieloryb, zasię mię osadził strażą?
13 Nígbà tí mo wí pé, ibùsùn mi yóò tù mí lára, ìtẹ́ mi yóò mú ara mi fúyẹ́ pẹ̀lú.
Gdym rzekł: Pocieszy mię łoże moje, i ulży mi narzekania mego pościel moja:
14 Nígbà náà ni ìwọ fi àlá da yọ mi lénu bò mi, ìwọ sì fi ìran òru dẹ́rùbà mí.
Tedy mię straszysz przez sny, i przez widzenia trwożysz mną.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mí yàn láti fún pa àti ikú ju kí ń wà láààyè ní ipò tí ara mí wà yìí lọ.
A przetoż obrała sobie powieszenie dusz moja, a śmierć raczej, niż zostać w kościach.
16 O sú mi, èmi kò le wà títí: jọ̀wọ́ mi jẹ́, nítorí pé asán ni ọjọ́ mi.
Sprzykrzyłem sobie żywot, nie wiecznie będę żyw. Zaniechajże mię, bo marnością są dni moje.
17 “Kí ni ènìyàn tí ìwọ o máa kókìkí rẹ̀? Àti tí ìwọ ìbá fi gbé ọkàn rẹ lé e?
Cóż jest człowiek, że go tak wielce ważysz? a że przykładasz ku niemu serce twoje?
18 Àti ti ìwọ ó fi máa wá í bẹ̀ ẹ́ wò ni òròòwúrọ̀, ti ìwọ o sì máa dán an wò nígbàkígbà!
A że go nawiedzasz na każdy zaranek? i na każdą chwilę doświadczasz go?
19 Yóò ti pẹ́ tó kí ìwọ kí ó tó fi mí sílẹ̀ lọ, tí ìwọ o fi mí sílẹ̀ jẹ́ẹ́ títí èmi yóò fi lè dá itọ́ mi mì.
Pokądże się nie odwrócisz odemnie? a nie zaniechasz mię, ażbym przełknął ślinę moję?
20 Èmi ti ṣẹ̀, ki ní èmi ó ṣe sí ọ. Ìwọ Olùsójú ènìyàn? Èéṣe tí ìwọ fi fi mí ṣe àmì itasi níwájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi sì di ẹrẹ̀ wíwo fún ọ?
Zgrzeszyłem, cóż mam czynić? o stróżu ludzki! czemuś mię sobie za cel położył, abym był sam sobie ciężarem?
21 Èéṣe tí ìwọ kò sì dárí ìrékọjá mi jìn, kí ìwọ kí ó sì mú àìṣedéédéé mi kúrò? Ǹjẹ́ nísinsin yìí ni èmi ìbá sùn nínú erùpẹ̀, ìwọ ìbá sì wá mi kiri ní òwúrọ̀, èmi kì bá tí sí.”
Przecz nie odejmiesz przestępstwa mego, i nie przepuścisz nieprawości mojej? Bo się teraz w prochu położę, a choćbyś mię szukał rano, nie będzie mię.

< Job 7 >