< Job 7 >
1 “Ṣé ìjà kò ha si fún ènìyàn lórí ilẹ̀? Ọjọ́ rẹ̀ pẹ̀lú kò ha dàbí ọjọ́ alágbàṣe?
A OLE anei he kaua no ke kanaka ma ka honua? A like kona mau la me na la o ka mea hoolimalima?
2 Bí ọmọ ọ̀dọ̀ tí máa ń kánjú bojú wo òjìji, àti bí alágbàṣe ti í kánjú wo ọ̀nà owó iṣẹ́ rẹ̀.
E like me ke kauwa i makemake nui i ka malu, A me ka hoolimalima i nana i ka uku o kana hana;
3 Bẹ́ẹ̀ ni a mú mi ní ìbànújẹ́ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oṣù, òru ìdáni-lágara ni a sì là sílẹ̀ fún mi.
Pela no e lilo mai ai ia'u na malama luuluu, A e loaa ia'u na po kaumaha.
4 Nígbà ti mo dùbúlẹ̀, èmi wí pé, ‘Nígbà wo ni èmi ó dìde?’ Tí òru yóò sì kọjá, ó sì tó fún mi láti yí síyìn-ín yí sọ́hùn-ún, títí yóò fi di àfẹ̀mọ́júmọ́.
A i ka wa i moe ai au ilalo, i iho no au, Ahea la au e ala'e iluna? Ahea la e hala'e ka po? Ua piha au i ka hiaa ana a hiki i ka wanaao.
5 Kòkòrò àti ògúlùtu erùpẹ̀ ni á fi wọ̀ mi ni aṣọ, awọ ara mi bù, o sì di bíbàjẹ́.
Ua paapu ko'u kino i ka ilo a me ka papaa lepo; Ke ola mai nei kuu ili, alaila puha hou ae la.
6 “Ọjọ́ mi yára jù ọkọ̀ ìhunṣọ lọ, o sì di lílò ní àìní ìrètí.
Ua oi ka mama o kuu mau la mamua o ka laau ulana lole, A holo aku me ke manaolana ole.
7 Háà! Rántí pé afẹ́fẹ́ ni ẹ̀mí mi; ojú mi kì yóò padà rí rere mọ́.
E hoomanao oe, he makani kuu ola: Aole e ike hou ko'u maka i ka maikai.
8 Ojú ẹni tí ó rí mi, kì yóò rí mi mọ́; ojú rẹ̀ tẹ̀ mọ́ra mi, èmi kò sí mọ́.
O ka maka o ka mea i ike ia'u, aole ia e ike hou ia'u: Maluna o'u kou mau maka, a e ole auanei au.
9 Bí ìkùùkuu tí i túká, tí í sì fò lọ, bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sí ipò òkú tí kì yóò padà wa mọ́. (Sheol )
E like me ke ao e nalowale ana a e hele aku ana; Pela ka mea e iho ana i ka luakupapau, aole ia e ea hou ae iluna. (Sheol )
10 Kì yóò padà sínú ilé rẹ̀ mọ́, bẹ́ẹ̀ ní ipò rẹ̀ kì yóò mọ̀ ọn mọ́.
Aole ia e hoi hou i kona hale, Aole hoi e ike hou kona wahi ia ia.
11 “Nítorí náà èmi kì yóò pa ẹnu mi mọ́, èmi yóò máa sọ nínú ìrora ọkàn mi, èmi yóò máa ṣe ìráhùn nínú kíkorò ọkàn mi.
Nolaila aole au e hoopaa i kuu waha; E olelo aku au ma ka pilikia o kuu uhane; E ulono ana au no ka awaawa o kuu naau.
12 Èmi a máa ṣe Òkun tàbí ẹ̀mí búburú, tí ìwọ fi ń yan olùṣọ́ tì mi?
He kai anei au, a he ia nui, I hoonoho mai ai oe i ke kiai maluna o'u?
13 Nígbà tí mo wí pé, ibùsùn mi yóò tù mí lára, ìtẹ́ mi yóò mú ara mi fúyẹ́ pẹ̀lú.
A i iho au, E hooluolu kuu wahi moe ia'u, E lawe aku kuu moe i ko'u ulono ana:
14 Nígbà náà ni ìwọ fi àlá da yọ mi lénu bò mi, ìwọ sì fi ìran òru dẹ́rùbà mí.
Alaila hoomakau mai oe ia'u ma na moeuhane, A hooweliweli mai oe ia'u i na mea hihio.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mí yàn láti fún pa àti ikú ju kí ń wà láààyè ní ipò tí ara mí wà yìí lọ.
Nolaila ke koho nei kuu naau i ke kaawe, A me ka make mamua o kuu ola ana.
16 O sú mi, èmi kò le wà títí: jọ̀wọ́ mi jẹ́, nítorí pé asán ni ọjọ́ mi.
Ke hoopailua nei au ia mea; aole au makemake e ola loa; E waiho mai ia'u; no ka mea, he hanu wale no kuu mau la.
17 “Kí ni ènìyàn tí ìwọ o máa kókìkí rẹ̀? Àti tí ìwọ ìbá fi gbé ọkàn rẹ lé e?
Heaha la ke kanaka, i hoonui mai ai oe ia ia? A i kau mai ai oe i kou manao ia ia?
18 Àti ti ìwọ ó fi máa wá í bẹ̀ ẹ́ wò ni òròòwúrọ̀, ti ìwọ o sì máa dán an wò nígbàkígbà!
A i ike mai ai oe ia ia i kela kakahiaka keia kakahiaka, A i hoao mau mai ai oe ia ia?
19 Yóò ti pẹ́ tó kí ìwọ kí ó tó fi mí sílẹ̀ lọ, tí ìwọ o fi mí sílẹ̀ jẹ́ẹ́ títí èmi yóò fi lè dá itọ́ mi mì.
Pehea ka loihi o kou nana ole ana mai io'u aku nei, A kuu ole mai ia'u, a moni iho au i kuu kuha?
20 Èmi ti ṣẹ̀, ki ní èmi ó ṣe sí ọ. Ìwọ Olùsójú ènìyàn? Èéṣe tí ìwọ fi fi mí ṣe àmì itasi níwájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi sì di ẹrẹ̀ wíwo fún ọ?
Ua hana hewa au; heaha ka'u e hana aku ai ia oe, E ka Meakiai i na kanaka? No keaha la oe e hooku ae ia'u, i mea e hopu ai nou, I lilo ai hoi au i mea kaumaha no'u iho?
21 Èéṣe tí ìwọ kò sì dárí ìrékọjá mi jìn, kí ìwọ kí ó sì mú àìṣedéédéé mi kúrò? Ǹjẹ́ nísinsin yìí ni èmi ìbá sùn nínú erùpẹ̀, ìwọ ìbá sì wá mi kiri ní òwúrọ̀, èmi kì bá tí sí.”
No keaha la oe i kala ole mai ai i kuu hala, A i lawe aku hoi i ko'u hewa? No ka mea, ano e moe auanei au i ka lepo; A e imi mai oe ia'u, aole hoi wau.