< Job 7 >

1 “Ṣé ìjà kò ha si fún ènìyàn lórí ilẹ̀? Ọjọ́ rẹ̀ pẹ̀lú kò ha dàbí ọjọ́ alágbàṣe?
“Githĩ mũndũ ndakoragwo na ũtungata mũritũ gũkũ thĩ? Githĩ matukũ make matihaana o ta ma mũndũ mwandĩke wĩra?
2 Bí ọmọ ọ̀dọ̀ tí máa ń kánjú bojú wo òjìji, àti bí alágbàṣe ti í kánjú wo ọ̀nà owó iṣẹ́ rẹ̀.
O ta ngombo ĩkwĩrirĩria ciĩruru cia hwaĩ-inĩ, o na kana ta mũndũ mwandĩke ũgũthethũkĩra mũcaara wake-rĩ,
3 Bẹ́ẹ̀ ni a mú mi ní ìbànújẹ́ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oṣù, òru ìdáni-lágara ni a sì là sílẹ̀ fún mi.
ũguo nĩguo niĩ ngaĩirwo mĩeri ya tũhũ, na ngatuĩrwo atĩ ũtukũ ndaarage ndĩ na kĩeha.
4 Nígbà ti mo dùbúlẹ̀, èmi wí pé, ‘Nígbà wo ni èmi ó dìde?’ Tí òru yóò sì kọjá, ó sì tó fún mi láti yí síyìn-ín yí sọ́hùn-ún, títí yóò fi di àfẹ̀mọ́júmọ́.
Rĩrĩa ndakoma ndĩyũragia atĩrĩ, ‘Ndĩrĩũkĩra rĩ?’ Ũtukũ ũkaraiha, na ngaraara ngĩĩgarũra nginya gũgakĩa.
5 Kòkòrò àti ògúlùtu erùpẹ̀ ni á fi wọ̀ mi ni aṣọ, awọ ara mi bù, o sì di bíbàjẹ́.
Mwĩrĩ wakwa ũiyũrĩtwo nĩ igunyũ na ngũcĩ, nakĩo gĩkonde gĩakwa gĩatũkangĩte na gĩgatogota.
6 “Ọjọ́ mi yára jù ọkọ̀ ìhunṣọ lọ, o sì di lílò ní àìní ìrètí.
“Matukũ makwa maraathira na ihenya rĩkĩrĩte rĩa kanyamũ karĩa gakonjithanagia uuthi ngoora ĩgĩtumwo, magagĩkinya mũthia itarĩ na kĩĩrĩgĩrĩro.
7 Háà! Rántí pé afẹ́fẹ́ ni ẹ̀mí mi; ojú mi kì yóò padà rí rere mọ́.
Wee Ngai-rĩ, ririkana atĩ muoyo wakwa no ta mĩhũmũ; namo maitho makwa matigacooka kuona ũndũ mwega rĩngĩ.
8 Ojú ẹni tí ó rí mi, kì yóò rí mi mọ́; ojú rẹ̀ tẹ̀ mọ́ra mi, èmi kò sí mọ́.
Riitho rĩrĩa rĩranyona rĩtigacooka kũnyona rĩngĩ; mũkaanjaria, no ndigakorwo ho.
9 Bí ìkùùkuu tí i túká, tí í sì fò lọ, bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sí ipò òkú tí kì yóò padà wa mọ́. (Sheol h7585)
O ta ũrĩa itu rĩthiiaga rĩkabuĩria, ũguo noguo ũrĩa ũthiiaga mbĩrĩra-inĩ atacookaga kuoneka. (Sheol h7585)
10 Kì yóò padà sínú ilé rẹ̀ mọ́, bẹ́ẹ̀ ní ipò rẹ̀ kì yóò mọ̀ ọn mọ́.
Ndagacooka kũinũka gwake mũciĩ; harĩa aaikaraga ndagacooka kuonwo ho.
11 “Nítorí náà èmi kì yóò pa ẹnu mi mọ́, èmi yóò máa sọ nínú ìrora ọkàn mi, èmi yóò máa ṣe ìráhùn nínú kíkorò ọkàn mi.
“Nĩ ũndũ ũcio-rĩ, ndigũkira; ngwaria nĩ ũndũ wa ũrĩa roho wakwa ũrĩ na ruo, ndĩtetere nĩ ũndũ wa ũrĩa ngoro yakwa ĩrĩ na marũrũ.
12 Èmi a máa ṣe Òkun tàbí ẹ̀mí búburú, tí ìwọ fi ń yan olùṣọ́ tì mi?
Niĩ-rĩ, ndĩ iria rĩa maaĩ, kana nyamũ ĩrĩa nene ĩtũũraga iria thĩinĩ kũrĩa kũriku, atĩ nĩkĩo nangagĩrwo?
13 Nígbà tí mo wí pé, ibùsùn mi yóò tù mí lára, ìtẹ́ mi yóò mú ara mi fúyẹ́ pẹ̀lú.
Rĩrĩa ngwĩciiria ũrĩrĩ wakwa nĩguo ũkũũhooreria, na atĩ gĩtanda gĩakwa no kĩĩniinĩre gũteta-rĩ,
14 Nígbà náà ni ìwọ fi àlá da yọ mi lénu bò mi, ìwọ sì fi ìran òru dẹ́rùbà mí.
o na hĩndĩ ĩyo ũũmakagia na irooto, o na ũkanjiguithia guoya na cioneki,
15 Bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mí yàn láti fún pa àti ikú ju kí ń wà láààyè ní ipò tí ara mí wà yìí lọ.
nĩ ũndũ ũcio ngathuura kaba gũitwo, na gĩkuũ, handũ ha gũikara na mwĩrĩ ũyũ wakwa.
16 O sú mi, èmi kò le wà títí: jọ̀wọ́ mi jẹ́, nítorí pé asán ni ọjọ́ mi.
Nĩthũire muoyo wakwa; ndikwenda gũtũũra nginya tene. Tigana na niĩ tondũ matukũ makwa no ma tũhũ.
17 “Kí ni ènìyàn tí ìwọ o máa kókìkí rẹ̀? Àti tí ìwọ ìbá fi gbé ọkàn rẹ lé e?
“Mũndũ-rĩ, akĩrĩ kĩ, tondũ ũmwĩkĩrĩire ũguo, na ũkamũrũmbũyia mũno ũguo,
18 Àti ti ìwọ ó fi máa wá í bẹ̀ ẹ́ wò ni òròòwúrọ̀, ti ìwọ o sì máa dán an wò nígbàkígbà!
atĩ ũmũthuthuuragia ngoro o rũciinĩ, na ũkamũgeragia mahinda mothe?
19 Yóò ti pẹ́ tó kí ìwọ kí ó tó fi mí sílẹ̀ lọ, tí ìwọ o fi mí sílẹ̀ jẹ́ẹ́ títí èmi yóò fi lè dá itọ́ mi mì.
Kaĩ gũtarĩ hĩndĩ ũgaatiga gũikara ũndorete, kana ũtigane na niĩ o na kahinda kanini?
20 Èmi ti ṣẹ̀, ki ní èmi ó ṣe sí ọ. Ìwọ Olùsójú ènìyàn? Èéṣe tí ìwọ fi fi mí ṣe àmì itasi níwájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi sì di ẹrẹ̀ wíwo fún ọ?
Angĩkorwo nĩnjĩhĩtie-rĩ, nĩ atĩa niĩ ngwĩkĩte, Wee mũrori wa andũ? Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte ũnjorote? Kaĩ nduĩkĩte mũrigo harĩwe?
21 Èéṣe tí ìwọ kò sì dárí ìrékọjá mi jìn, kí ìwọ kí ó sì mú àìṣedéédéé mi kúrò? Ǹjẹ́ nísinsin yìí ni èmi ìbá sùn nínú erùpẹ̀, ìwọ ìbá sì wá mi kiri ní òwúrọ̀, èmi kì bá tí sí.”
Nĩ kĩĩ kĩragiria ũnjohere mahĩtia makwa na ũndekere mehia makwa? Nĩgũkorwo ndĩ hakuhĩ gũkoma tĩĩri-inĩ; nawe nĩũkanjaria no ndigakorwo ho.”

< Job 7 >