< Job 6 >

1 Jobu sì dáhùn ó si wí pé,
Отвещав же Иов, рече:
2 “Háà! À bá lè wọ́n ìbìnújẹ́ mi nínú òsùwọ̀n, kí a sì le gbé ọ̀fọ̀ mi lé orí òsùwọ̀n ṣọ̀kan pọ̀!
аще бы кто веся извесил гнев мой, болезни же моя взял бы на мерило вкупе,
3 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ìbá wúwo jú iyanrìn òkun lọ, nítorí náà ni ọ̀rọ̀ mi ṣe ń tàsé.
то песка морскаго тяжчайшии были бы: но, якоже мнится, словеса моя зла суть.
4 Nítorí pé ọfà Olódùmarè wọ̀ mi nínú, oró èyí tí ọkàn mi mú; ìpayà-ẹ̀rù Ọlọ́run dúró tì mí.
Стрелы бо Господни в теле моем суть, ихже ярость испивает кровь мою: егда начну глаголати, бодут мя.
5 Ǹjẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó á máa dún nígbà tí ó bá ní koríko, tàbí ọ̀dá màlúù a máa dún lórí ìjẹ rẹ̀?
Что бо? Еда вотще возревет дивий осел, разве брашна прося? Или возревет гласом вол, в яслех имеяй брашно?
6 A ha lè jẹ ohun tí kò ní adùn ní àìní iyọ̀, tàbí adùn ha wà nínú funfun ẹyin?
Снестся ли хлеб без соли? Или есть вкус во тщих словесех?
7 Ohun ti ọ̀kan mi kọ̀ láti tọ́wò, òun ni ó dàbí oúnjẹ tí ó mú mi ṣàárẹ̀.
Не может бо утишитися душа моя: смрад бо зрю брашна моя, якоже воню львову.
8 “Háà! èmi ìbá lè rí ìbéèrè mi gbà; àti pé, kí Ọlọ́run lè fi ohun tí èmi ṣàfẹ́rí fún mi.
Аще бо дал бы, да приидет прошение мое, и надежду мою дал бы Господь.
9 Àní Ọlọ́run ìbá jẹ́ pa mí run, tí òun ìbá jẹ́ ṣíwọ́ rẹ̀ kì ó sì ké mi kúrò.
Начен Господь да уязвляет мя, до конца же да не убиет мя.
10 Nígbà náà ní èmi ìbá ní ìtùnú síbẹ̀, àní, èmi ìbá mú ọkàn mi le nínú ìbànújẹ́ mi ti kò dá ni sí: nítorí èmi kò fi ọ̀rọ̀ ẹni mímọ́ ni sin rí.
Буди же ми град гроб, на егоже стенах скаках в нем: не пощажу: не солгах бо во словесех святых Бога моего.
11 “Kí ní agbára mi tí èmi ó fi retí? Kí sì ní òpin mi tí èmi ó fi ní sùúrù?
Кая бо крепость моя, яко терплю? Или кое ми время, яко терпит моя душа?
12 Agbára mi ha ṣe agbára òkúta bí? Ẹran-ara mi í ṣe idẹ?
Еда крепость камения крепость моя? Или плоти моя суть медяны?
13 Ìrànlọ́wọ́ mi kò ha wà nínú mi: ọgbọ́n kò ha ti sálọ kúrò lọ́dọ̀ mi bí?
Или не уповах на него? Помощь же от мене отступи,
14 “Ẹni tí àyà rẹ̀ yọ́ dànù, ta ni a bá máa ṣàánú fún láti ọ̀dọ̀ ọ̀rẹ́ rẹ̀ wá, kí ó má ba à kọ ìbẹ̀rù Olódùmarè sílẹ̀?
отречеся от мене милость, посещение же Господне презре мя.
15 Àwọn ará mi dàbí odò tí kò ṣe gbẹ́kẹ̀lé bí ìṣàn omi odò, wọ́n sàn kọjá lọ.
Не воззреша на мя ближнии мои: якоже поток оскудеваяй, или якоже волны преидоша мя:
16 Tí ó dúdú nítorí omi dídì, àti níbi tí yìnyín dídì gbé di yíyọ́.
иже мене бояхуся, ныне нападоша на мя:
17 Nígbàkígbà tí wọ́n bá gbóná wọn a sì yọ́ sàn lọ, nígbà tí oòrùn bá mú, wọn a sì gbẹ kúrò ni ipò wọn.
якоже снег или лед смерзлый, егда истает теплоте бывшей, не ктому познавается, что бе:
18 Àwọn oníṣòwò yà kúrò ní ọ̀nà wọn, wọ́n gòkè sí ibi asán, wọ́n sì run.
тако и аз оставлен есмь от всех, погибох же и бездомок бых:
19 Ẹgbẹ́ oníṣòwò Tema ń wá omi, àwọn oníṣòwò Ṣeba ń dúró dè wọ́n ní ìrètí.
видите пути Феманския, на стези Савонския смотрящии,
20 Wọ́n káàárẹ̀, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e; wọ́n dé bẹ̀, wọ́n sì dààmú.
и студа исполнени будут на грады и на имения надеющиися.
21 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ̀yin dàbí wọn; ẹ̀yin rí ìrẹ̀sílẹ̀ mi àyà sì fò mí.
Ныне же и вы наидосте на мя немилостивно: убо видевше мой струп убойтеся.
22 Èmi ó ha wí pé, ‘Ẹ mú ohun fún mi wá, tàbí pé ẹ fún mi ní ẹ̀bùn nínú ohun ìní yín?
Что бо? Еда что у вас просих, или вашея крепости требую,
23 Tàbí, ẹ gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá ni, tàbí, ẹ rà mí padà kúrò lọ́wọ́ alágbára nì’?
да спасете мя от врагов, или из руки сильных избавите мя?
24 “Ẹ kọ́ mi, èmi ó sì pa ẹnu mi mọ́ kí ẹ sì mú mi wòye níbi tí mo gbé ti ṣìnà.
Научите мя, аз же умолчу: аще что погреших, скажите ми.
25 Wò ó! Bí ọ̀rọ̀ òtítọ́ ti lágbára tó ṣùgbọ́n kí ni àròyé ìbáwí yín jásí?
Но, якоже мнится, зла (суть) мужа истиннаго словеса, не от вас бо крепости прошу:
26 Ẹ̀yin ṣè bí ẹ tún ọ̀rọ̀ mi ṣe àti ohùn ẹnu tí ó dàbí afẹ́fẹ́ ṣe àárẹ̀.
ниже обличение ваше словесы мя утолит, ниже бо вещания вашего словес стерплю.
27 Àní ẹ̀yin ṣe gẹ́gẹ́ bí aláìní baba, ẹ̀yin sì da iye lé ọ̀rẹ́ yín.
Обаче яко на сира нападаете, наскачете же на друга вашего.
28 “Nítorí náà, kí èyí kí ó tó fún yín. Ẹ má wò mi! Nítorí pé ó hàn gbangba pé, ní ojú yín ni èmi kì yóò ṣèké.
Ныне же воззрев на лица ваша, не солжу.
29 Èmi ń bẹ̀ yín, ẹ padà, kí ó má sì ṣe jásí ẹ̀ṣẹ̀; àní, ẹ sì tún padà, àre mi ń bẹ nínú ọ̀rọ̀ yìí.
Сядите ныне, и да не будет неправедно, и паки ко праведному снидитеся.
30 Àìṣedéédéé ha wà ní ahọ́n mi? Ǹjẹ́ ìtọ́wò ẹnu mi kò kúkú le mọ ohun ti ó burú jù?
Ибо несть в языце моем неправды, и гортань мой не разуму ли поучается?

< Job 6 >