< Job 6 >

1 Jobu sì dáhùn ó si wí pé,
Hiob zaś odpowiedział tymi słowami:
2 “Háà! À bá lè wọ́n ìbìnújẹ́ mi nínú òsùwọ̀n, kí a sì le gbé ọ̀fọ̀ mi lé orí òsùwọ̀n ṣọ̀kan pọ̀!
O gdyby dokładnie zważono moją udrękę i włożono na szalę całe moje nieszczęście!
3 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ìbá wúwo jú iyanrìn òkun lọ, nítorí náà ni ọ̀rọ̀ mi ṣe ń tàsé.
Byłoby to cięższe niż piasek morski. Dlatego moje słowa plączą się.
4 Nítorí pé ọfà Olódùmarè wọ̀ mi nínú, oró èyí tí ọkàn mi mú; ìpayà-ẹ̀rù Ọlọ́run dúró tì mí.
[Tkwią] we mnie bowiem strzały Wszechmocnego, których jad osuszył mego ducha, [a] strachy Boże walczą przeciwko mnie.
5 Ǹjẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó á máa dún nígbà tí ó bá ní koríko, tàbí ọ̀dá màlúù a máa dún lórí ìjẹ rẹ̀?
Czy dziki osioł ryczy, gdy ma trawę? Czy wół ryczy nad swoją paszą?
6 A ha lè jẹ ohun tí kò ní adùn ní àìní iyọ̀, tàbí adùn ha wà nínú funfun ẹyin?
Czy można zjeść niesmaczną rzecz bez soli? Czy ma jakiś smak białko jajka?
7 Ohun ti ọ̀kan mi kọ̀ láti tọ́wò, òun ni ó dàbí oúnjẹ tí ó mú mi ṣàárẹ̀.
[Czego się przedtem] moja dusza nie chciała dotknąć, jest to [teraz] moim bolesnym pokarmem.
8 “Háà! èmi ìbá lè rí ìbéèrè mi gbà; àti pé, kí Ọlọ́run lè fi ohun tí èmi ṣàfẹ́rí fún mi.
Oby się spełniła moja prośba i Bóg dał mi to, czego pragnę!
9 Àní Ọlọ́run ìbá jẹ́ pa mí run, tí òun ìbá jẹ́ ṣíwọ́ rẹ̀ kì ó sì ké mi kúrò.
Oby się Bogu spodobało to, aby mnie zniszczyć, aby opuścić rękę i mnie odciąć!
10 Nígbà náà ní èmi ìbá ní ìtùnú síbẹ̀, àní, èmi ìbá mú ọkàn mi le nínú ìbànújẹ́ mi ti kò dá ni sí: nítorí èmi kò fi ọ̀rọ̀ ẹni mímọ́ ni sin rí.
Wtedy miałbym jeszcze pociechę – chociaż pałam boleścią, niech [Bóg] mi nie folguje – nie zataiłem bowiem słów Świętego.
11 “Kí ní agbára mi tí èmi ó fi retí? Kí sì ní òpin mi tí èmi ó fi ní sùúrù?
Jaka [jest] moja siła, abym miał wytrwać? Jaki jest mój koniec, abym przedłużał swoje życie?
12 Agbára mi ha ṣe agbára òkúta bí? Ẹran-ara mi í ṣe idẹ?
Czy moja siła jest siłą kamieni? Czy moje ciało jest ze spiżu?
13 Ìrànlọ́wọ́ mi kò ha wà nínú mi: ọgbọ́n kò ha ti sálọ kúrò lọ́dọ̀ mi bí?
Czy moja obrona nie jest we mnie? Czy mój rozsądek odszedł ode mnie?
14 “Ẹni tí àyà rẹ̀ yọ́ dànù, ta ni a bá máa ṣàánú fún láti ọ̀dọ̀ ọ̀rẹ́ rẹ̀ wá, kí ó má ba à kọ ìbẹ̀rù Olódùmarè sílẹ̀?
Strapionemu należy się litość od przyjaciela, ale on opuścił bojaźń Wszechmogącego.
15 Àwọn ará mi dàbí odò tí kò ṣe gbẹ́kẹ̀lé bí ìṣàn omi odò, wọ́n sàn kọjá lọ.
Moi bracia zawiedli jak potok, odpływają jak gwałtowne potoki;
16 Tí ó dúdú nítorí omi dídì, àti níbi tí yìnyín dídì gbé di yíyọ́.
Które są mętne od lodu, w których śnieg się ukrywa;
17 Nígbàkígbà tí wọ́n bá gbóná wọn a sì yọ́ sàn lọ, nígbà tí oòrùn bá mú, wọn a sì gbẹ kúrò ni ipò wọn.
W czasie roztopów znikają; [w czasie] upałów nikną ze swego miejsca.
18 Àwọn oníṣòwò yà kúrò ní ọ̀nà wọn, wọ́n gòkè sí ibi asán, wọ́n sì run.
Wiją się ścieżki ich dróg; rozpływają się w nicość i giną.
19 Ẹgbẹ́ oníṣòwò Tema ń wá omi, àwọn oníṣòwò Ṣeba ń dúró dè wọ́n ní ìrètí.
Podróżni z Temy wypatrywali ich; wędrowcy z Seby pokładali w nich nadzieję.
20 Wọ́n káàárẹ̀, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e; wọ́n dé bẹ̀, wọ́n sì dààmú.
Ale zawiedli się w oczekiwaniu, przyszli tam i zawstydzili się.
21 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ̀yin dàbí wọn; ẹ̀yin rí ìrẹ̀sílẹ̀ mi àyà sì fò mí.
Staliście się niczym; widzicie moją niedolę i lękacie się.
22 Èmi ó ha wí pé, ‘Ẹ mú ohun fún mi wá, tàbí pé ẹ fún mi ní ẹ̀bùn nínú ohun ìní yín?
Czy powiedziałem: Przynieście mi [coś]? lub: Dajcie mi z waszego majątku?
23 Tàbí, ẹ gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá ni, tàbí, ẹ rà mí padà kúrò lọ́wọ́ alágbára nì’?
Lub: Wybawcie mnie z rąk wroga? lub: Wykupcie mnie z rąk okrutników?
24 “Ẹ kọ́ mi, èmi ó sì pa ẹnu mi mọ́ kí ẹ sì mú mi wòye níbi tí mo gbé ti ṣìnà.
Pouczcie mnie, a zamilknę; pokażcie mi, w czym zbłądziłem.
25 Wò ó! Bí ọ̀rọ̀ òtítọ́ ti lágbára tó ṣùgbọ́n kí ni àròyé ìbáwí yín jásí?
O jak mocne są słowa prawdziwe! Ale cóż sprawi wasze obwinianie?
26 Ẹ̀yin ṣè bí ẹ tún ọ̀rọ̀ mi ṣe àti ohùn ẹnu tí ó dàbí afẹ́fẹ́ ṣe àárẹ̀.
Czy zamierzacie ganić [moje] słowa i mowę zrozpaczonego, jakby były wiatrem?
27 Àní ẹ̀yin ṣe gẹ́gẹ́ bí aláìní baba, ẹ̀yin sì da iye lé ọ̀rẹ́ yín.
Nawet sierotę przytłaczacie i kopiecie [doły] pod swoim przyjacielem.
28 “Nítorí náà, kí èyí kí ó tó fún yín. Ẹ má wò mi! Nítorí pé ó hàn gbangba pé, ní ojú yín ni èmi kì yóò ṣèké.
Teraz więc zechciejcie spojrzeć na mnie, a [zobaczycie], czy kłamię wam w oczy.
29 Èmi ń bẹ̀ yín, ẹ padà, kí ó má sì ṣe jásí ẹ̀ṣẹ̀; àní, ẹ sì tún padà, àre mi ń bẹ nínú ọ̀rọ̀ yìí.
Zawróćcie, proszę, a niech nie będzie [w was] nieprawości; zawróćcie, a [poznacie] moją sprawiedliwość w tym.
30 Àìṣedéédéé ha wà ní ahọ́n mi? Ǹjẹ́ ìtọ́wò ẹnu mi kò kúkú le mọ ohun ti ó burú jù?
Czy w moim języku jest nieprawość? Czy moje podniebienie nie rozeznaje przewrotności?

< Job 6 >