< Job 6 >

1 Jobu sì dáhùn ó si wí pé,
Felelt Jób és mondta:
2 “Háà! À bá lè wọ́n ìbìnújẹ́ mi nínú òsùwọ̀n, kí a sì le gbé ọ̀fọ̀ mi lé orí òsùwọ̀n ṣọ̀kan pọ̀!
Vajha mérve mérnék bosszúságomat a gyötrelmemet mérlegre vetnék egyaránt!
3 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ìbá wúwo jú iyanrìn òkun lọ, nítorí náà ni ọ̀rọ̀ mi ṣe ń tàsé.
Mert most tengerek fövenyénél nehezebb, azért megzavarodtak szavaim.
4 Nítorí pé ọfà Olódùmarè wọ̀ mi nínú, oró èyí tí ọkàn mi mú; ìpayà-ẹ̀rù Ọlọ́run dúró tì mí.
Mert a Mindenható nyilai vannak bennem, a melyeknek mérgét lelkem issza; Isten ijedelmei sorakoznak ellenem.
5 Ǹjẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó á máa dún nígbà tí ó bá ní koríko, tàbí ọ̀dá màlúù a máa dún lórí ìjẹ rẹ̀?
Ordít-e a vadszamár a pázsiton, avagy bőg-e az ökör abraka mellett?
6 A ha lè jẹ ohun tí kò ní adùn ní àìní iyọ̀, tàbí adùn ha wà nínú funfun ẹyin?
Ehető-e a mi ízetlen, só nélkül, avagy van-e íz a tojás fehérjében?
7 Ohun ti ọ̀kan mi kọ̀ láti tọ́wò, òun ni ó dàbí oúnjẹ tí ó mú mi ṣàárẹ̀.
Vonakodott hozzá nyúlni a lelkem; azok az én kórságos ételem.
8 “Háà! èmi ìbá lè rí ìbéèrè mi gbà; àti pé, kí Ọlọ́run lè fi ohun tí èmi ṣàfẹ́rí fún mi.
Bárcsak beteljesednék kérésem s reményemet megadná Isten;
9 Àní Ọlọ́run ìbá jẹ́ pa mí run, tí òun ìbá jẹ́ ṣíwọ́ rẹ̀ kì ó sì ké mi kúrò.
s tetszenék Istennek, hogy összezúzzon engem, megoldaná kezét, hogy véget vessen nekem!
10 Nígbà náà ní èmi ìbá ní ìtùnú síbẹ̀, àní, èmi ìbá mú ọkàn mi le nínú ìbànújẹ́ mi ti kò dá ni sí: nítorí èmi kò fi ọ̀rọ̀ ẹni mímọ́ ni sin rí.
Akkor volna még vigasztalásom – fölszökném kíméletlen fájdalomban – hogy nem tagadtam meg a Szentnek szavait.
11 “Kí ní agbára mi tí èmi ó fi retí? Kí sì ní òpin mi tí èmi ó fi ní sùúrù?
Mi az erőm, hogy várakozzam, s mi a végem, hogy türtessem magam?
12 Agbára mi ha ṣe agbára òkúta bí? Ẹran-ara mi í ṣe idẹ?
Avagy kövek ereje-e az én erőm, vagy ércz az én húsom?
13 Ìrànlọ́wọ́ mi kò ha wà nínú mi: ọgbọ́n kò ha ti sálọ kúrò lọ́dọ̀ mi bí?
Hiszen segítségem nincs bennem, és üdvösségem elutasíttatott tőlem.
14 “Ẹni tí àyà rẹ̀ yọ́ dànù, ta ni a bá máa ṣàánú fún láti ọ̀dọ̀ ọ̀rẹ́ rẹ̀ wá, kí ó má ba à kọ ìbẹ̀rù Olódùmarè sílẹ̀?
Az elcsüggedőt barátjától szeretet illeti, ha el is hagyja a Mindenható félelmét!
15 Àwọn ará mi dàbí odò tí kò ṣe gbẹ́kẹ̀lé bí ìṣàn omi odò, wọ́n sàn kọjá lọ.
Testvéreim hűtelenek lettek mint a patak, mint a hogy medrükben a patakok eltűnnek.
16 Tí ó dúdú nítorí omi dídì, àti níbi tí yìnyín dídì gbé di yíyọ́.
A melyek sötétlenek a jégtől, bennök rejtőzik el a hó;
17 Nígbàkígbà tí wọ́n bá gbóná wọn a sì yọ́ sàn lọ, nígbà tí oòrùn bá mú, wọn a sì gbẹ kúrò ni ipò wọn.
mikor hőség éri, megsemmisülnek, midőn meleg van, elenyésznek helyükből.
18 Àwọn oníṣòwò yà kúrò ní ọ̀nà wọn, wọ́n gòkè sí ibi asán, wọ́n sì run.
Kanyarodnak útjuk ösvényei, elhúzódnak a pusztaságban és elvesznek.
19 Ẹgbẹ́ oníṣòwò Tema ń wá omi, àwọn oníṣòwò Ṣeba ń dúró dè wọ́n ní ìrètí.
Ide tekintettek Téma karavánjai, Sába vándorcsapatai reménykedtek bennük;
20 Wọ́n káàárẹ̀, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e; wọ́n dé bẹ̀, wọ́n sì dààmú.
megszégyenültek, hogy bíztak, elérkeztek odáig és elpirultak.
21 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ̀yin dàbí wọn; ẹ̀yin rí ìrẹ̀sílẹ̀ mi àyà sì fò mí.
Mert most az övéi vagytok, láttok rettegést és féltek.
22 Èmi ó ha wí pé, ‘Ẹ mú ohun fún mi wá, tàbí pé ẹ fún mi ní ẹ̀bùn nínú ohun ìní yín?
Hát mondtam-e: adjatok nékem, és vagyontokból vesztegetést ajáljatok értem,
23 Tàbí, ẹ gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá ni, tàbí, ẹ rà mí padà kúrò lọ́wọ́ alágbára nì’?
és szabadítsatok ki szorongatónak kezéből s zsarnokok kezétől váltsatok meg engem?
24 “Ẹ kọ́ mi, èmi ó sì pa ẹnu mi mọ́ kí ẹ sì mú mi wòye níbi tí mo gbé ti ṣìnà.
Tanítsatok engem s én elhallgatok, és ha mit tévedtem, értessétek meg velem.
25 Wò ó! Bí ọ̀rọ̀ òtítọ́ ti lágbára tó ṣùgbọ́n kí ni àròyé ìbáwí yín jásí?
Mi hathatósak az egyenes beszédek, de miképp fedne feddés, minő a tietek?
26 Ẹ̀yin ṣè bí ẹ tún ọ̀rọ̀ mi ṣe àti ohùn ẹnu tí ó dàbí afẹ́fẹ́ ṣe àárẹ̀.
Szókat tekintetek-e feddésnek és szélnek az elcsüggedettnek beszédeit?
27 Àní ẹ̀yin ṣe gẹ́gẹ́ bí aláìní baba, ẹ̀yin sì da iye lé ọ̀rẹ́ yín.
Még árvának is nekiestek és áskálódtok barátotok ellen.
28 “Nítorí náà, kí èyí kí ó tó fún yín. Ẹ má wò mi! Nítorí pé ó hàn gbangba pé, ní ojú yín ni èmi kì yóò ṣèké.
Most hát egyezzetek bele, forduljatok felém, arczotokba vajon hazudom-e?
29 Èmi ń bẹ̀ yín, ẹ padà, kí ó má sì ṣe jásí ẹ̀ṣẹ̀; àní, ẹ sì tún padà, àre mi ń bẹ nínú ọ̀rọ̀ yìí.
Térjetek meg, kérlek, ne essék jogtalanság, igen, térjetek meg, folyton áll ebben az igazam!
30 Àìṣedéédéé ha wà ní ahọ́n mi? Ǹjẹ́ ìtọ́wò ẹnu mi kò kúkú le mọ ohun ti ó burú jù?
Van-e nyelvemen jogtalanság, avagy ínyem nem érezné-e a gyötrelmeket?

< Job 6 >