< Job 5 >

1 “Ó jẹ́ pé nísinsin yìí bí ẹnìkan bá wà tí yóò dá wa lóhùn? Tàbí ta ni nínú àwọn ènìyàn mímọ́ tí ìwọ ó yípadà sí?
فریاد برآور و کمک بطلب، ولی آیا کسی گوش می‌دهد؟ کدام یک از فرشتگان به دادت می‌رسد.
2 Nítorí pé ìbínú pa aláìmòye, ìrunú a sì pa òpè ènìyàn.
سرانجام در عجز و درماندگی از غصه می‌میرند.
3 Èmi ti rí aláìmòye ti ó ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lulẹ̀, ṣùgbọ́n lójúkan náà mo fi ibùjókòó rẹ̀ bú.
کسانی که از خدا برمی‌گردند، ظاهراً کامیاب هستند، ولی بلای ناگهانی بر آنها نازل می‌شود.
4 Àwọn ọmọ rẹ̀ kò jìnnà sí ewu, a sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ lójú ibodè, bẹ́ẹ̀ ni kò sí aláàbò kan.
فرزندان ایشان بی‌پناه می‌گردند و در محکمه محکوم می‌شوند و کسی از آنها حمایت نمی‌کند.
5 Ìkórè oko ẹni tí àwọn tí ebi ń pa sọ̀ di jíjẹ, tí wọ́n sì wọ inú ẹ̀gún lọ kó, àwọn ìgárá ọlọ́ṣà sì gbé ohun ìní wọn mì.
محصولاتشان را گرسنگان می‌خورند و ثروتشان را حریصان غارت می‌کنند.
6 Bí ìpọ́njú kò bá ti inú erùpẹ̀ jáde wá ni, tí ìyọnu kò ti ilẹ̀ jáde wá.
بلا و بدبختی هرگز بدون علّت دامنگیر انسان نمی‌شود.
7 Ṣùgbọ́n a bí ènìyàn sínú wàhálà, gẹ́gẹ́ bí ìpẹ́pẹ́ iná ti máa ń ta sókè.
بدبختی از خود انسان سرچشمه می‌گیرد، همچنانکه شعله از آتش برمی‌خیزد.
8 “Ṣùgbọ́n bí ó ṣe tèmi, ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ní èmi yóò ti ṣìpẹ̀, ní ọwọ́ Ọlọ́run ní èmi yóò máa fi ọ̀rọ̀ mi lé.
اگر من جای تو بودم، مشکل خود را نزد خدا می‌بردم.
9 Ẹni tí ó ṣe ohun tí ó tóbi tí a kò lè ṣe àwárí, ohun ìyanu láìní iye.
زیرا او معجزات شگفت‌انگیز می‌کند و کارهای عجیب و خارق‌العادهٔ بی‌شمار انجام می‌دهد.
10 Tí ń rọ̀jò sí orí ilẹ̀ ayé tí ó sì ń rán omi sínú ilẹ̀kílẹ̀.
بر زمین باران می‌باراند و کشتزارها را سیراب می‌کند،
11 Láti gbé àwọn orílẹ̀-èdè lékè kí á lè gbé àwọn ẹni ìbànújẹ́ ga sí ibi aláìléwu.
فروتنان را سرافراز می‌گرداند و رنجدیدگان را شادی می‌بخشد.
12 Ó yí ìmọ̀ àwọn alárékérekè po, bẹ́ẹ̀ ní ọwọ́ wọn kò lè mú ìdáwọ́lé wọn ṣẹ.
او نقشه‌های اشخاص حیله‌گر را نقش بر آب می‌کند تا کاری از پیش نبرند.
13 Ó mú àwọn ọlọ́gbọ́n nínú àrékérekè ara wọn, àti ìmọ̀ àwọn òǹrorò ní ó tì ṣubú ní ògèdèǹgbé.
حکیمان را در زیرکیِ خودشان به دام می‌اندازد و توطئه‌های ایشان را خنثی می‌نماید.
14 Wọ́n sáré wọ inú òkùnkùn ní ọ̀sán; wọ́n sì fọwọ́ tálẹ̀ ní ọ̀sán gangan bí ẹni pé ní òru ni.
روز روشن برای آنها مانند شب تاریک است و در آن کورمال کورمال راه می‌روند.
15 Ṣùgbọ́n ó gba tálákà là ní ọwọ́ idà, lọ́wọ́ ẹnu wọn àti lọ́wọ́ àwọn alágbára.
خدا مظلومان و فقیران را از چنگ ظالمان می‌رهاند.
16 Bẹ́ẹ̀ ni ìrètí wà fún tálákà, àìṣòótọ́ sì pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
او به فقیران امید می‌بخشد و دهان ظالمان را می‌بندد.
17 “Kíyèsi i, ìbùkún ni fún ẹni tí Ọlọ́run bá wí, nítorí náà, má ṣe gan ìbáwí Olódùmarè.
خوشا به حال کسی که خدای قادرمطلق تأدیبش می‌کند. پس وقتی او تو را تأدیب می‌نماید، دلگیر نشو.
18 Nítorí pé òun a máa pa ni lára, síbẹ̀ òun a sì tún dì í ní ìdì ìtura, ó sá lọ́gbẹ́, a sì fi ọwọ́ rẹ̀ di ojú ọgbẹ̀ náà jiná.
اگر خدا تو را مجروح کند خودش هم زخمهایت را می‌بندد و تو را شفا می‌بخشد.
19 Yóò gbà ọ́ nínú ìpọ́njú mẹ́fà, àní nínú méje, ibi kan kì yóò bá ọ.
او تو را از هر بلایی می‌رهاند تا گزندی به تو نرسد.
20 Nínú ìyanu yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ ikú àti nínú ogun, yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ idà.
خدا تو را هنگام قحطی از مرگ نجات خواهد داد و در موقع جنگ از دم شمشیر خواهد رهانید.
21 A ó pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ iná ahọ́n, bẹ́ẹ̀ ní ìwọ kì yóò bẹ̀rù ìparun tí ó bá dé.
از زخم زبان در امان خواهی بود و وقتی هلاکت آید، از آن نخواهی ترسید.
22 Ìwọ yóò rẹ́rìn-ín nínú ìparun àti ìyàn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò bẹ̀rù ẹranko ilẹ̀ ayé.
بر هلاکت و قحطی خواهی خندید و از حیوانات وحشی هراس به دل راه نخواهی داد.
23 Nítorí pé ìwọ ti bá òkúta igbó mulẹ̀, àwọn ẹranko igbó yóò wà pẹ̀lú rẹ ní àlàáfíà.
زمینی که شخم می‌زنی خالی از سنگ خواهد بود و جانوران خطرناک با تو در صلح و صفا به سر خواهند برد.
24 Ìwọ ó sì mọ̀ pé àlàáfíà ni ibùjókòó rẹ wà, ìwọ yóò sì máa ṣe ìbẹ̀wò ibùjókòó rẹ, ìwọ kì yóò ṣìnà.
خانهٔ تو در امان خواهد بود و از اموال تو چیزی دزدیده نخواهد شد.
25 Ìwọ ó sì mọ̀ pẹ̀lú pé irú-ọmọ rẹ ó sì pọ̀ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ yóò rí bí koríko igbó.
نسل تو مانند علف صحرا زیاد خواهند بود،
26 Ìwọ yóò wọ isà òkú rẹ ní ògbólógbòó ọjọ́, bí síírí ọkà tí ó gbó tí á sì kó ní ìgbà ìkórè rẹ̀.
و تو همچون خوشهٔ گندم که تا وقتش نرسد درو نمی‌شود، در کمال پیری، کامیاب از دنیا خواهی رفت.
27 “Kíyèsi i, àwa ti wádìí rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ní ó rí! Gbà á gbọ́, kí o sì mọ̀ pé fún ìre ara rẹ ni.”
تجربه به من ثابت کرده است که همهٔ اینها حقیقت دارد؛ پس به خاطر خودت نصیحت مرا بشنو.

< Job 5 >