< Job 5 >
1 “Ó jẹ́ pé nísinsin yìí bí ẹnìkan bá wà tí yóò dá wa lóhùn? Tàbí ta ni nínú àwọn ènìyàn mímọ́ tí ìwọ ó yípadà sí?
Sauc jel, vai būs kāds, kas tev atbild? Un pie kura no svētiem tu gribi griezties?
2 Nítorí pé ìbínú pa aláìmòye, ìrunú a sì pa òpè ènìyàn.
Jo sirdēsti nokauj ģeķi, un pārsteigšanās nonāvē nejēgu.
3 Èmi ti rí aláìmòye ti ó ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lulẹ̀, ṣùgbọ́n lójúkan náà mo fi ibùjókòó rẹ̀ bú.
Es redzēju ģeķi iesakņotu, bet piepeši nolādēju viņa namu.
4 Àwọn ọmọ rẹ̀ kò jìnnà sí ewu, a sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ lójú ibodè, bẹ́ẹ̀ ni kò sí aláàbò kan.
Viņa bērni palika tālu no pestīšanas un tapa satriekti vārtos, un nebija glābēja.
5 Ìkórè oko ẹni tí àwọn tí ebi ń pa sọ̀ di jíjẹ, tí wọ́n sì wọ inú ẹ̀gún lọ kó, àwọn ìgárá ọlọ́ṣà sì gbé ohun ìní wọn mì.
Viņa pļāvumu ēda izsalkuši, un pat no ērkšķu vidus to lasīja, un laupītāji aprija viņa padomu.
6 Bí ìpọ́njú kò bá ti inú erùpẹ̀ jáde wá ni, tí ìyọnu kò ti ilẹ̀ jáde wá.
Jo no pīšļiem neizaug nelaime, un no zemes neizplaukst grūtums.
7 Ṣùgbọ́n a bí ènìyàn sínú wàhálà, gẹ́gẹ́ bí ìpẹ́pẹ́ iná ti máa ń ta sókè.
Bet cilvēks uz grūtumu piedzimst, kā dzirksteles no oglēm paceļas skraidīt.
8 “Ṣùgbọ́n bí ó ṣe tèmi, ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ní èmi yóò ti ṣìpẹ̀, ní ọwọ́ Ọlọ́run ní èmi yóò máa fi ọ̀rọ̀ mi lé.
Bet es meklētu to stipro Dievu un Dievam pavēlētu savas lietas.
9 Ẹni tí ó ṣe ohun tí ó tóbi tí a kò lè ṣe àwárí, ohun ìyanu láìní iye.
Viņš dara lielas lietas, kas nav izprotamas, un brīnumus, ko nevar skaitīt.
10 Tí ń rọ̀jò sí orí ilẹ̀ ayé tí ó sì ń rán omi sínú ilẹ̀kílẹ̀.
Viņš dod lietu virs zemes un ūdenim liek nākt pār druvām.
11 Láti gbé àwọn orílẹ̀-èdè lékè kí á lè gbé àwọn ẹni ìbànújẹ́ ga sí ibi aláìléwu.
Zemos Viņš liek augstā vietā, un bēdīgie tiek celti laimē.
12 Ó yí ìmọ̀ àwọn alárékérekè po, bẹ́ẹ̀ ní ọwọ́ wọn kò lè mú ìdáwọ́lé wọn ṣẹ.
Viņš iznīcina viltniekiem padomu, ka viņu rokas nekā derīga nevar padarīt.
13 Ó mú àwọn ọlọ́gbọ́n nínú àrékérekè ara wọn, àti ìmọ̀ àwọn òǹrorò ní ó tì ṣubú ní ògèdèǹgbé.
Viņš satver gudros viņu viltībā, un netikliem padoms ātri krīt.
14 Wọ́n sáré wọ inú òkùnkùn ní ọ̀sán; wọ́n sì fọwọ́ tálẹ̀ ní ọ̀sán gangan bí ẹni pé ní òru ni.
Pa dienu tie skraida tumsā, un dienas vidū tie grābstās kā naktī.
15 Ṣùgbọ́n ó gba tálákà là ní ọwọ́ idà, lọ́wọ́ ẹnu wọn àti lọ́wọ́ àwọn alágbára.
Bet Viņš izglābj no zobena, no viņu mutes, un to bēdīgo no varenā rokas.
16 Bẹ́ẹ̀ ni ìrètí wà fún tálákà, àìṣòótọ́ sì pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
Tā nabagam nāk cerība, bet blēdībai būs turēt muti.
17 “Kíyèsi i, ìbùkún ni fún ẹni tí Ọlọ́run bá wí, nítorí náà, má ṣe gan ìbáwí Olódùmarè.
Redzi, svētīgs tas cilvēks, ko Dievs pārmāca, tāpēc neņem par ļaunu tā Visuvarenā pārmācību.
18 Nítorí pé òun a máa pa ni lára, síbẹ̀ òun a sì tún dì í ní ìdì ìtura, ó sá lọ́gbẹ́, a sì fi ọwọ́ rẹ̀ di ojú ọgbẹ̀ náà jiná.
Jo Viņš ievaino un atkal sasien, Viņš sadauza, un Viņa roka dziedina.
19 Yóò gbà ọ́ nínú ìpọ́njú mẹ́fà, àní nínú méje, ibi kan kì yóò bá ọ.
Sešās bēdās Viņš tevi izglābs, un septītā tevi ļaunums neaizskars.
20 Nínú ìyanu yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ ikú àti nínú ogun, yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ idà.
Bada laikā Viņš tevi izpestīs no nāves, un kara laikā no zobena cirtieniem.
21 A ó pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ iná ahọ́n, bẹ́ẹ̀ ní ìwọ kì yóò bẹ̀rù ìparun tí ó bá dé.
No ļaunām mēlēm tu tapsi paglābts, un nebīsies no posta, kad tas nāks.
22 Ìwọ yóò rẹ́rìn-ín nínú ìparun àti ìyàn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò bẹ̀rù ẹranko ilẹ̀ ayé.
Postīšanā un badā tu smiesies, un no zemes zvēriem tu nebīsies.
23 Nítorí pé ìwọ ti bá òkúta igbó mulẹ̀, àwọn ẹranko igbó yóò wà pẹ̀lú rẹ ní àlàáfíà.
Jo tev būs derība ar akmeņiem tīrumā, un zvēri laukā turēs ar tevi mieru.
24 Ìwọ ó sì mọ̀ pé àlàáfíà ni ibùjókòó rẹ wà, ìwọ yóò sì máa ṣe ìbẹ̀wò ibùjókòó rẹ, ìwọ kì yóò ṣìnà.
Un tu samanīsi, ka tavs dzīvoklis mierā, un apraudzīsi savu namu un trūkuma nebūs.
25 Ìwọ ó sì mọ̀ pẹ̀lú pé irú-ọmọ rẹ ó sì pọ̀ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ yóò rí bí koríko igbó.
Un tu samanīsi, ka tava dzimuma būs daudz, un tavi pēcnākamie kā zāle virs zemes.
26 Ìwọ yóò wọ isà òkú rẹ ní ògbólógbòó ọjọ́, bí síírí ọkà tí ó gbó tí á sì kó ní ìgbà ìkórè rẹ̀.
Vecumā tu iesi kapā, tā kā kūlīšus ieved savā laikā.
27 “Kíyèsi i, àwa ti wádìí rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ní ó rí! Gbà á gbọ́, kí o sì mọ̀ pé fún ìre ara rẹ ni.”
Redzi, to mēs esam izmeklējuši, tā tas ir; klausi tu un ņem to labi vērā.