< Job 5 >

1 “Ó jẹ́ pé nísinsin yìí bí ẹnìkan bá wà tí yóò dá wa lóhùn? Tàbí ta ni nínú àwọn ènìyàn mímọ́ tí ìwọ ó yípadà sí?
“Wenda gwĩtana, ĩtana, no rĩrĩ, nũũ ũngĩgwĩtĩka? Nĩ ũrĩkũ wa arĩa atheru ũngĩũrĩra kũrĩ we?
2 Nítorí pé ìbínú pa aláìmòye, ìrunú a sì pa òpè ènìyàn.
Rũngʼathio rũũragaga kĩrimũ, naguo ũiru ũkooraga mũndũ ũrĩa mũkĩĩgu.
3 Èmi ti rí aláìmòye ti ó ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lulẹ̀, ṣùgbọ́n lójúkan náà mo fi ibùjókòó rẹ̀ bú.
Niĩ mwene nĩnyonete kĩrimũ gĩkĩgĩa na mĩri, no-o rĩmwe nyũmba yakĩo ĩkĩrumwo.
4 Àwọn ọmọ rẹ̀ kò jìnnà sí ewu, a sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ lójú ibodè, bẹ́ẹ̀ ni kò sí aláàbò kan.
Ciana ciake nĩiraihanĩrĩirie na ũgitĩri, ihatĩrĩirio igooti-inĩ itarĩ na mũndũ wa gũciciirĩrĩra.
5 Ìkórè oko ẹni tí àwọn tí ebi ń pa sọ̀ di jíjẹ, tí wọ́n sì wọ inú ẹ̀gún lọ kó, àwọn ìgárá ọlọ́ṣà sì gbé ohun ìní wọn mì.
Ũrĩa mũhũtu arĩĩaga magetha make, amoyaga o na marĩ mĩigua-inĩ, nao arĩa anyootu makahũmagĩra ũtonga wao.
6 Bí ìpọ́njú kò bá ti inú erùpẹ̀ jáde wá ni, tí ìyọnu kò ti ilẹ̀ jáde wá.
Nĩgũkorwo hatĩka ndĩkunũkaga kuuma thĩ, kana thĩĩna ũkamera tĩĩri-inĩ.
7 Ṣùgbọ́n a bí ènìyàn sínú wàhálà, gẹ́gẹ́ bí ìpẹ́pẹ́ iná ti máa ń ta sókè.
No rĩrĩ, mũndũ aciaragwo arĩ wa kuonaga thĩĩna, o ta ũrĩa na ma thandĩ cia mwaki irathũkaga na igũrũ.
8 “Ṣùgbọ́n bí ó ṣe tèmi, ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ní èmi yóò ti ṣìpẹ̀, ní ọwọ́ Ọlọ́run ní èmi yóò máa fi ọ̀rọ̀ mi lé.
“No rĩrĩ, korwo nĩ niĩ ingĩthaitha Mũrungu; ingĩneana ciira wakwa kũrĩ we.
9 Ẹni tí ó ṣe ohun tí ó tóbi tí a kò lè ṣe àwárí, ohun ìyanu láìní iye.
We ekaga maũndũ ma magegania marĩa mataangĩmenyeka, na akaringa ciama itangĩtarĩka.
10 Tí ń rọ̀jò sí orí ilẹ̀ ayé tí ó sì ń rán omi sínú ilẹ̀kílẹ̀.
Nĩwe uuragĩria thĩ mbura; na nĩwe ũrehagĩra bũrũri maaĩ.
11 Láti gbé àwọn orílẹ̀-èdè lékè kí á lè gbé àwọn ẹni ìbànújẹ́ ga sí ibi aláìléwu.
Arĩa menyiihagia nĩwe ũmatũũgagĩria, nao arĩa marĩ na kĩeha moyagwo na igũrũ makagitĩrwo.
12 Ó yí ìmọ̀ àwọn alárékérekè po, bẹ́ẹ̀ ní ọwọ́ wọn kò lè mú ìdáwọ́lé wọn ṣẹ.
Nĩwe ũthaatagia mĩbango ya arĩa marĩ waara, nĩgeetha moko mao matikagĩe na ũhootani.
13 Ó mú àwọn ọlọ́gbọ́n nínú àrékérekè ara wọn, àti ìmọ̀ àwọn òǹrorò ní ó tì ṣubú ní ògèdèǹgbé.
Nĩanyiitaga arĩa oogĩ waara-inĩ wao, namo mathugunda ma arĩa oingumania akaameheria biũ.
14 Wọ́n sáré wọ inú òkùnkùn ní ọ̀sán; wọ́n sì fọwọ́ tálẹ̀ ní ọ̀sán gangan bí ẹni pé ní òru ni.
Nduma ĩmakoraga kũrĩ o mũthenya; mũthenya barigici makahambataga taarĩ ũtukũ.
15 Ṣùgbọ́n ó gba tálákà là ní ọwọ́ idà, lọ́wọ́ ẹnu wọn àti lọ́wọ́ àwọn alágbára.
Nĩahonokagia arĩa abatari kuuma kũrĩ rũhiũ rwa njora rũrĩa rũrĩ tũnua-inĩ twao; amahonokagia moko-inĩ ma arĩa marĩ hinya.
16 Bẹ́ẹ̀ ni ìrètí wà fún tálákà, àìṣòótọ́ sì pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
Nĩ ũndũ ũcio athĩĩni makagĩa na kĩĩrĩgĩrĩro, naguo ciira ũtarĩ wa kĩhooto ũgatumia kanua.
17 “Kíyèsi i, ìbùkún ni fún ẹni tí Ọlọ́run bá wí, nítorí náà, má ṣe gan ìbáwí Olódùmarè.
“Kũrathimwo nĩ mũndũ ũrĩa ũrũngagwo nĩ Ngai; nĩ ũndũ ũcio ndũkamene irũithia rĩa Mwene-Hinya-Wothe.
18 Nítorí pé òun a máa pa ni lára, síbẹ̀ òun a sì tún dì í ní ìdì ìtura, ó sá lọ́gbẹ́, a sì fi ọwọ́ rẹ̀ di ojú ọgbẹ̀ náà jiná.
Nĩgũkorwo nĩaguraranagia, no rĩrĩ, acookaga akooha nguraro ĩyo wega; nĩatiihanagia, no moko make no mo mahonanagia.
19 Yóò gbà ọ́ nínú ìpọ́njú mẹ́fà, àní nínú méje, ibi kan kì yóò bá ọ.
Nĩagagũteithũra harĩ mĩtino ĩtandatũ; o na ĩrĩ mũgwanja-rĩ, gũtirĩ ũũru ũgaagũkora.
20 Nínú ìyanu yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ ikú àti nínú ogun, yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ idà.
Hĩndĩ ya ngʼaragu nĩagagũkũũra kuuma kũrĩ gĩkuũ, ningĩ hĩndĩ ya mbaara agũkũũre ndũkooragwo na rũhiũ rwa njora.
21 A ó pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ iná ahọ́n, bẹ́ẹ̀ ní ìwọ kì yóò bẹ̀rù ìparun tí ó bá dé.
Nĩũkagitĩrwo harĩ rũcamiũ rwa rũrĩmĩ, na ndũgetigĩra hĩndĩ ĩrĩa mwanangĩko ũgooka.
22 Ìwọ yóò rẹ́rìn-ín nínú ìparun àti ìyàn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò bẹ̀rù ẹranko ilẹ̀ ayé.
Nĩũgathekerera mwanangĩko na ngʼaragu, na ndũgetigĩra nyamũ cia gũkũ thĩ.
23 Nítorí pé ìwọ ti bá òkúta igbó mulẹ̀, àwọn ẹranko igbó yóò wà pẹ̀lú rẹ ní àlàáfíà.
Nĩgũkorwo nĩũkagĩa na kĩrĩkanĩro na mahiga ma werũ-inĩ, nacio nyamũ cia gĩthaka itũũre irĩ na thayũ nawe.
24 Ìwọ ó sì mọ̀ pé àlàáfíà ni ibùjókòó rẹ wà, ìwọ yóò sì máa ṣe ìbẹ̀wò ibùjókòó rẹ, ìwọ kì yóò ṣìnà.
Nawe ũikarage ũũĩ atĩ hema yaku nĩ ngitĩre; nawe nĩũkooya ithabu rĩa indo ciaku ũkore hatirĩ kĩndũ kĩũrĩte.
25 Ìwọ ó sì mọ̀ pẹ̀lú pé irú-ọmọ rẹ ó sì pọ̀ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ yóò rí bí koríko igbó.
Nĩũkamenya atĩ ciana ciaku nĩikaingĩha, nacio njiaro ciaku cingĩhe o ta nyeki ya gũkũ thĩ.
26 Ìwọ yóò wọ isà òkú rẹ ní ògbólógbòó ọjọ́, bí síírí ọkà tí ó gbó tí á sì kó ní ìgbà ìkórè rẹ̀.
Ũgaathiĩ mbĩrĩra-inĩ ũrĩ o na hinya, ũhaana ta itĩĩa cia ngano ĩgethetwo hĩndĩ ya magetha.
27 “Kíyèsi i, àwa ti wádìí rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ní ó rí! Gbà á gbọ́, kí o sì mọ̀ pé fún ìre ara rẹ ni.”
“Nĩtũtuĩrĩtie ũhoro ũyũ, na nĩ wa ma. Nĩ ũndũ ũcio kĩũigue na ũũmenye wee mwene.”

< Job 5 >