< Job 42 >

1 Nígbà náà ní Jobu dá Olúwa lóhùn, ó sì wí pé,
És felelt Jób az Örökkévalónak és mondta:
2 “Èmi mọ̀ pé, ìwọ lè e ṣe ohun gbogbo, àti pé, kò si ìrò inú tí a lè fa sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
Tudom, hogy mindent tehetsz, s nem vonható meg tőled semmi szándék.
3 Ìwọ béèrè, ta ni ẹni tí ń fi ìgbìmọ̀ pamọ́ láìní ìmọ̀? Nítorí náà ní èmi ṣe ń sọ èyí tí èmi kò mọ̀, ohun tí ó ṣe ìyanu jọjọ níwájú mi, ti èmi kò mòye.
Ki az, ki elburkolja a tanácsot tudás nélkül? – Azért hát olyat hirdettem, mit nem értek, olyakat, a mik csodásak nekem s nem tudom. -
4 “Ìwọ wí pé, ‘Gbọ́ tèmi báyìí, èmi ó sì sọ; èmi ó béèrè lọ́wọ́ rẹ, ìwọ yóò sì dá mi lóhùn.’
Halljad csak, majd beszélek én, hadd kérdelek, s te tudasd velem. –
5 Etí mi sì ti gbọ́ nípa rẹ, ṣùgbọ́n nísinsin yìí ojú mi ti rí ọ.
Fülhallás szerint hallottam rólad, de most szemem látott téged.
6 Ǹjẹ́ nítorí náà èmi kórìíra ara mi, mo sì ronúpìwàdà nínú ekuru àti eérú.”
Azért elvetem és megbánom, porban és hamuban.
7 Bẹ́ẹ̀ ó sì rí, lẹ́yìn ìgbà tí Olúwa ti sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún Jobu, Olúwa sì wí fún Elifasi, ará Temani pé, mo bínú sí ọ, àti sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ méjèèjì, nítorí pé ẹ̀yin kò sọ̀rọ̀, ní ti èmi, ohun tí ó tọ́, bí Jobu ìránṣẹ́ mi ti sọ.
És volt, miután elmondta az Örökkévaló e szavakat Jóbnak, szólt az Örökkévaló a Témánbeli Élífáhzhoz: Föllobbant haragom ellened és két barátod ellen, mert nem beszéltetek rólam helyeset, úgy mint szolgám Jób.
8 Nítorí náà, ẹ mú akọ ẹgbọrọ màlúù méje, àti àgbò méje, kí ẹ sì tọ̀ Jobu ìránṣẹ́ mi lọ, kí ẹ sì fi rú ẹbọ sísun fún ara yín; Jobu ìránṣẹ́ mi yóò sì gbàdúrà fún yin; nítorí pé àdúrà rẹ̀ ní èmi yóò gbà; kí èmi kí ó má ba ṣe si yín bí ìṣìnà yín, ní ti pé ẹ̀yin kò sọ̀rọ̀ ohun tí ó tọ́ sí mi bi Jobu ìránṣẹ́ mi ti ṣe.
Most tehát vegyetek magatoknak hét tulkot és hét kost s menjetek szolgámhoz, Jóbhoz és hozzatok magatokért égőáldozatot; Jób szolgám pedig imádkozni fog értetek, mert csak az ő személyét tekintem, hogy valami csúfságot nem teszek veletek, mert nem beszéltetek rólam helyeset, úgy mint szolgám, Jób.
9 Bẹ́ẹ̀ ní Elifasi, ara Temani, àti Bilidadi, ará Ṣuhi, àti Sofari, ará Naama lọ, wọ́n sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn. Olúwa sì gbọ́ àdúrà Jobu.
És mentek a Témánbeli Élífáz, a Súachbeli Bildád és a Náamabeli Czófar és cselekedtek, a mint szólott hozzájok az Örökkévaló; és tekintettel volt az Örökkévaló Jób személyére.
10 Olúwa sì yí ìgbèkùn Jobu padà, nígbà tí ó gbàdúrà fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀; Olúwa sì bùsi ohun gbogbo ti Jobu ní rí ní ìṣẹ́po méjì ohun tí ó ní tẹ́lẹ̀ rí.
Az Örökkévaló pedig helyrehozta Jób veszteségét, midőn barátjaiért imádkozott; s megtoldotta az Örökkévaló mind azt, a mi Jóbé volt, kétszeresére.
11 Nígbà náà ní gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀, àti gbogbo àwọn arábìnrin rẹ̀, àti gbogbo àwọn tí ó ti ṣe ojúlùmọ̀ rẹ̀ rí; wọ́n bá a jẹun nínú ilé rẹ̀. Wọ́n sì ṣe ìdárò rẹ̀, wọ́n sì ṣìpẹ̀ fún un nítorí ibi gbogbo tí Olúwa ti mú bá a. Olúkúlùkù ènìyàn pẹ̀lú sì fún un ní ẹyọ owó kọ̀ọ̀kan àti olúkúlùkù ni òrùka wúrà etí kọ̀ọ̀kan.
Eljöttek hozzá mind a fivérei és mind a nővérei és mind az előbbi ismerősei s ettek kenyeret vele az ő házában, szánakoztak rajta és megvigasztalták őt mind azon veszedelem miatt, a melyet reá hozott az Örökkévaló, és adtak neki ki-ki egy keszítát és ki-ki egy arany gyűrűt.
12 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa bùkún ìgbẹ̀yìn Jobu ju ìṣáájú rẹ̀ lọ; ẹgbàá méje àgùntàn, ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ìbákasẹ, àti ẹgbẹ̀rún àjàgà ọ̀dá màlúù, àti ẹgbẹ̀rún abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
S az Örökkévaló megáldotta Jób végét, inkább mint a kezdetét; és volt neki tizennégyezer juha, hatezer tevéje, ezer iga marhája és ezer nőstény szamara.
13 Ó sì ní ọmọkùnrin méje àti ọmọbìnrin mẹ́ta.
S volt neki hét fia és három leánya.
14 Ó sì sọ orúkọ àkọ́bí ní Jemima, àti orúkọ èkejì ni Kesia àti orúkọ ẹ̀kẹta ní Kereni-Happuki.
És elnevezte az egyiket Jemímának, a másodiknak neve pedig Keczía és a harmadiknak neve Kéren-Happúkh.
15 Àti ní gbogbo ilẹ̀ náà, a kò rí obìnrin tí ó ní ẹwà bí ọmọ Jobu; baba wọ́n sì pínlẹ̀ fún wọn nínú àwọn arákùnrin wọn.
S nem találtattak oly szép nők, mint Jób leányai, az egész országban; s adott nekik atyjok birtokot fivéreik között.
16 Lẹ́yìn èyí Jobu wà ní ayé ní ogóje ọdún, ó sì rí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti ọmọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àní ìran mẹ́rin.
És élt Jób ezután száznegyven esztendőt, és látta gyermekeit és gyermekeinek gyermekeit: négy nemzedéket.
17 Bẹ́ẹ̀ ni Jobu kú, ó gbó, ó sì kún fún ọjọ́ púpọ̀.
És meghalt Jób öregen és napokkal telten.

< Job 42 >