< Job 42 >

1 Nígbà náà ní Jobu dá Olúwa lóhùn, ó sì wí pé,
Or Job, reprenant dit au Seigneur:
2 “Èmi mọ̀ pé, ìwọ lè e ṣe ohun gbogbo, àti pé, kò si ìrò inú tí a lè fa sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
Je sais que vous pouvez tout et que rien ne vous est impossible.
3 Ìwọ béèrè, ta ni ẹni tí ń fi ìgbìmọ̀ pamọ́ láìní ìmọ̀? Nítorí náà ní èmi ṣe ń sọ èyí tí èmi kò mọ̀, ohun tí ó ṣe ìyanu jọjọ níwájú mi, ti èmi kò mòye.
Qui peut vous cacher ses desseins? Croira-t-on que vous les ignorez, parce que l'on aura épargné les paroles? Qui me révélera ce que je ne savais pas, les grandes merveilles dont je n'avais pas connaissance?
4 “Ìwọ wí pé, ‘Gbọ́ tèmi báyìí, èmi ó sì sọ; èmi ó béèrè lọ́wọ́ rẹ, ìwọ yóò sì dá mi lóhùn.’
Ecoutez-moi, Seigneur, afin que je parle à mon tour; je vais vous interroger, instruisez-moi.
5 Etí mi sì ti gbọ́ nípa rẹ, ṣùgbọ́n nísinsin yìí ojú mi ti rí ọ.
J'ai entendu premièrement comme entend votre oreille, et maintenant mon œil vous voit.
6 Ǹjẹ́ nítorí náà èmi kórìíra ara mi, mo sì ronúpìwàdà nínú ekuru àti eérú.”
C'est pourquoi je me prends en mépris, je me consume, et je sens que je ne suis que cendre et poussière.
7 Bẹ́ẹ̀ ó sì rí, lẹ́yìn ìgbà tí Olúwa ti sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún Jobu, Olúwa sì wí fún Elifasi, ará Temani pé, mo bínú sí ọ, àti sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ méjèèjì, nítorí pé ẹ̀yin kò sọ̀rọ̀, ní ti èmi, ohun tí ó tọ́, bí Jobu ìránṣẹ́ mi ti sọ.
Or ceci advint; après que le Seigneur eut tenu à Job tout ce discours, le seigneur dit à Eliphaz le Thémanite: Tu as péché, toi et tes deux amis, car vous n'avez rien dit devant moi qui fût véritable, comme l'a fait Job mon serviteur.
8 Nítorí náà, ẹ mú akọ ẹgbọrọ màlúù méje, àti àgbò méje, kí ẹ sì tọ̀ Jobu ìránṣẹ́ mi lọ, kí ẹ sì fi rú ẹbọ sísun fún ara yín; Jobu ìránṣẹ́ mi yóò sì gbàdúrà fún yin; nítorí pé àdúrà rẹ̀ ní èmi yóò gbà; kí èmi kí ó má ba ṣe si yín bí ìṣìnà yín, ní ti pé ẹ̀yin kò sọ̀rọ̀ ohun tí ó tọ́ sí mi bi Jobu ìránṣẹ́ mi ti ṣe.
Allez donc chercher sept béliers et sept bœufs, et revenez auprès de Job mon serviteur; et il le sacrifiera pour vous, et Job mon serviteur priera pour vous; car je n'écouterai que lui. Si ce n'était en considération de Job, je vous détruirais, parce que vous n'avez rien dit qui fût véritable, comme Job mon serviteur.
9 Bẹ́ẹ̀ ní Elifasi, ara Temani, àti Bilidadi, ará Ṣuhi, àti Sofari, ará Naama lọ, wọ́n sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn. Olúwa sì gbọ́ àdúrà Jobu.
Et Eliphaz le Thémanite, et Baldad le Sauchite, et Sophar le Minéen partirent, et ils firent ce que leur avait prescrit le Seigneur, et il leur remit leurs péchés à cause de Job.
10 Olúwa sì yí ìgbèkùn Jobu padà, nígbà tí ó gbàdúrà fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀; Olúwa sì bùsi ohun gbogbo ti Jobu ní rí ní ìṣẹ́po méjì ohun tí ó ní tẹ́lẹ̀ rí.
Et le Seigneur fortifia Job, et à sa prière, il remit à ses amis leur péché. Et le Seigneur donna à Job le double de ce qu'il possédait auparavant; il doubla toute chose.
11 Nígbà náà ní gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀, àti gbogbo àwọn arábìnrin rẹ̀, àti gbogbo àwọn tí ó ti ṣe ojúlùmọ̀ rẹ̀ rí; wọ́n bá a jẹun nínú ilé rẹ̀. Wọ́n sì ṣe ìdárò rẹ̀, wọ́n sì ṣìpẹ̀ fún un nítorí ibi gbogbo tí Olúwa ti mú bá a. Olúkúlùkù ènìyàn pẹ̀lú sì fún un ní ẹyọ owó kọ̀ọ̀kan àti olúkúlùkù ni òrùka wúrà etí kọ̀ọ̀kan.
Et tous ses frères et sœurs apprirent ce qui lui était arrivé, et ils vinrent auprès de lui, et tous ceux qui le connaissaient précédemment. En mangeant et en buvant chez lui, ils le consolèrent et ils manifestèrent leur admiration au sujet de ce que le Seigneur lui avait envoyé, et chacun d'eux lui donna une brebis et un double sicle d'or non monnayé.
12 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa bùkún ìgbẹ̀yìn Jobu ju ìṣáájú rẹ̀ lọ; ẹgbàá méje àgùntàn, ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ìbákasẹ, àti ẹgbẹ̀rún àjàgà ọ̀dá màlúù, àti ẹgbẹ̀rún abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Et le Seigneur bénit Job en la fin de sa carrière plus que dans les commencements, et ses troupeaux furent: quatre mille brebis, six mille chamelles, mille paires de bœufs et mille ânesses au pâturage.
13 Ó sì ní ọmọkùnrin méje àti ọmọbìnrin mẹ́ta.
Et il lui naquit sept fils et trois filles.
14 Ó sì sọ orúkọ àkọ́bí ní Jemima, àti orúkọ èkejì ni Kesia àti orúkọ ẹ̀kẹta ní Kereni-Happuki.
Et il appela la première Héméra, et la seconde Casria, et la troisième Corne d'Almathée.
15 Àti ní gbogbo ilẹ̀ náà, a kò rí obìnrin tí ó ní ẹwà bí ọmọ Jobu; baba wọ́n sì pínlẹ̀ fún wọn nínú àwọn arákùnrin wọn.
Et en toute l'étendue que le ciel recouvre, on n'eût point trouvé de femmes plus belles que les filles de Job, et il leur donna des parts d'héritage comme à ses fils.
16 Lẹ́yìn èyí Jobu wà ní ayé ní ogóje ọdún, ó sì rí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti ọmọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àní ìran mẹ́rin.
Et Job après ses jours d'affliction, vécut cent soixante-dix ans; et la durée de toute sa vie fut de deux cent quarante ans. Et Job vit ses fils et les fils de ses fils jusqu'à la quatrième génération,
17 Bẹ́ẹ̀ ni Jobu kú, ó gbó, ó sì kún fún ọjọ́ púpọ̀.
et Job mourut très avancé en âge et plein de jours.

< Job 42 >