< Job 42 >

1 Nígbà náà ní Jobu dá Olúwa lóhùn, ó sì wí pé,
Then Job responded to Yahweh, and said: —
2 “Èmi mọ̀ pé, ìwọ lè e ṣe ohun gbogbo, àti pé, kò si ìrò inú tí a lè fa sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
I know that, all things, thou canst do, and that no purpose can be withholden from thee.
3 Ìwọ béèrè, ta ni ẹni tí ń fi ìgbìmọ̀ pamọ́ láìní ìmọ̀? Nítorí náà ní èmi ṣe ń sọ èyí tí èmi kò mọ̀, ohun tí ó ṣe ìyanu jọjọ níwájú mi, ti èmi kò mòye.
Who is it that hideth counsel without knowledge? Therefore, have I declared, but not understood, things too wonderful for me, which I could not know.
4 “Ìwọ wí pé, ‘Gbọ́ tèmi báyìí, èmi ó sì sọ; èmi ó béèrè lọ́wọ́ rẹ, ìwọ yóò sì dá mi lóhùn.’
Hear thou, I pray thee, and, I, will speak, I will ask thee, and inform thou me.
5 Etí mi sì ti gbọ́ nípa rẹ, ṣùgbọ́n nísinsin yìí ojú mi ti rí ọ.
By the hearing of the ear, had I heard thee, but, now, mine own eye, hath seen thee.
6 Ǹjẹ́ nítorí náà èmi kórìíra ara mi, mo sì ronúpìwàdà nínú ekuru àti eérú.”
For this cause, I tremble and repent, on dust and ashes.
7 Bẹ́ẹ̀ ó sì rí, lẹ́yìn ìgbà tí Olúwa ti sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún Jobu, Olúwa sì wí fún Elifasi, ará Temani pé, mo bínú sí ọ, àti sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ méjèèjì, nítorí pé ẹ̀yin kò sọ̀rọ̀, ní ti èmi, ohun tí ó tọ́, bí Jobu ìránṣẹ́ mi ti sọ.
And it came to pass, after Yahweh had spoken these words unto Job, that Yahweh, said unto Eliphaz the Temanite, Kindled is mine anger against thee and against thy two friends, for ye have not spoken concerning me the thing that is right, like my servant Job.
8 Nítorí náà, ẹ mú akọ ẹgbọrọ màlúù méje, àti àgbò méje, kí ẹ sì tọ̀ Jobu ìránṣẹ́ mi lọ, kí ẹ sì fi rú ẹbọ sísun fún ara yín; Jobu ìránṣẹ́ mi yóò sì gbàdúrà fún yin; nítorí pé àdúrà rẹ̀ ní èmi yóò gbà; kí èmi kí ó má ba ṣe si yín bí ìṣìnà yín, ní ti pé ẹ̀yin kò sọ̀rọ̀ ohun tí ó tọ́ sí mi bi Jobu ìránṣẹ́ mi ti ṣe.
Now, therefore, take unto you seven bullocks and seven rams, and go unto my servant Job, and ye shall offer up an ascending-sacrifice in your own behalf, and, Job my servant, shall pray over you, —for, him, will I accept, that I may not deal out to you disgrace, because ye have not spoken concerning me the thing that is right, like my servant Job.
9 Bẹ́ẹ̀ ní Elifasi, ara Temani, àti Bilidadi, ará Ṣuhi, àti Sofari, ará Naama lọ, wọ́n sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn. Olúwa sì gbọ́ àdúrà Jobu.
So Eliphaz the Temanite and Bildad the Shuhite [and] Zophar the Naamathite went, and did according to that which Yahweh had spoken unto them, —and Yahweh accepted Job.
10 Olúwa sì yí ìgbèkùn Jobu padà, nígbà tí ó gbàdúrà fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀; Olúwa sì bùsi ohun gbogbo ti Jobu ní rí ní ìṣẹ́po méjì ohun tí ó ní tẹ́lẹ̀ rí.
And, Yahweh himself, turned the captivity of Job, when he prayed in behalf of his friends, —and Yahweh increased all that Job had possessed, unto twice as much.
11 Nígbà náà ní gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀, àti gbogbo àwọn arábìnrin rẹ̀, àti gbogbo àwọn tí ó ti ṣe ojúlùmọ̀ rẹ̀ rí; wọ́n bá a jẹun nínú ilé rẹ̀. Wọ́n sì ṣe ìdárò rẹ̀, wọ́n sì ṣìpẹ̀ fún un nítorí ibi gbogbo tí Olúwa ti mú bá a. Olúkúlùkù ènìyàn pẹ̀lú sì fún un ní ẹyọ owó kọ̀ọ̀kan àti olúkúlùkù ni òrùka wúrà etí kọ̀ọ̀kan.
Then came unto him all his brethren and all his sisters, and all his former acquaintances, and they did eat bread with him in his house, —and shewed sympathy with him and comforted him, over all the calamity which Yahweh had brought upon him, —and they gave him, every one a weight of money, and every one, a ring of gold.
12 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa bùkún ìgbẹ̀yìn Jobu ju ìṣáájú rẹ̀ lọ; ẹgbàá méje àgùntàn, ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ìbákasẹ, àti ẹgbẹ̀rún àjàgà ọ̀dá màlúù, àti ẹgbẹ̀rún abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
And, Yahweh, blessed the latter end of Job, more than his beginning, —and so he came to have fourteen thousand sheep, and six thousand camels, and a thousand yoke of oxen, and a thousand she-asses.
13 Ó sì ní ọmọkùnrin méje àti ọmọbìnrin mẹ́ta.
And he came to have seven sons, and three daughters;
14 Ó sì sọ orúkọ àkọ́bí ní Jemima, àti orúkọ èkejì ni Kesia àti orúkọ ẹ̀kẹta ní Kereni-Happuki.
and he called the name of the first Jemima, and the name of the second Kezia, —and the name of the third, Keren-happuch.
15 Àti ní gbogbo ilẹ̀ náà, a kò rí obìnrin tí ó ní ẹwà bí ọmọ Jobu; baba wọ́n sì pínlẹ̀ fún wọn nínú àwọn arákùnrin wọn.
And there were found no women so fair as the daughters of Job, in all the land, —and their father gave them an inheritance, in the midst of their brethren.
16 Lẹ́yìn èyí Jobu wà ní ayé ní ogóje ọdún, ó sì rí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti ọmọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àní ìran mẹ́rin.
And Job lived, after this, a hundred and forty years, —and saw his sons and his sons’ sons, four generations.
17 Bẹ́ẹ̀ ni Jobu kú, ó gbó, ó sì kún fún ọjọ́ púpọ̀.
So Job died, old and satisfied with days.

< Job 42 >