< Job 41 >
1 “Ǹjẹ́ ìwọ le è fi ìwọ̀ fa Lefitani jáde? Tàbí ìwọ lè fi okùn so ahọ́n rẹ̀ mọ́lẹ̀?
Wyciągnieszże wędą wieloryba? albo sznurem utopionym w języku jego?
2 Ìwọ lè fi okùn bọ̀ ọ́ ní í mú, tàbí fi ìwọ̀ ẹ̀gún gun ní ẹ̀rẹ̀kẹ́?
Izali zawleczesz kolce przez nozdrza jego? albo hakiem przekoleszli czeluść jego?
3 Òun ha jẹ́ bẹ ẹ̀bẹ̀ fún àánú lọ́dọ̀ rẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ bí òun ha bá ọ sọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́?
Izalić się będzie wiele modlił, albo z tobą łagodnie mówić będzie?
4 Òun ha bá ọ dá májẹ̀mú bí? Ìwọ ó ha máa mú ṣe ẹrú láéláé bí?
Izali uczyni przymierze z tobą, a przyjmiesz go za sługę wiecznego?
5 Ìwọ ha lè ba sáré bí ẹni pé ẹyẹ ni, tàbí ìwọ ó dè é fún àwọn ọmọbìnrin ìránṣẹ́ rẹ̀?
Izali z nim będziesz igrał jako z ptaszkiem, a uwiążesz go dziatkom twoim?
6 Ẹgbẹ́ àwọn apẹja yóò ha máa tà á bí? Wọn ó ha pín láàrín àwọn oníṣòwò?
Sprawiże sobie nad nim towarzystwo ucztę, a podzielą go między kupców?
7 Ìwọ ha lè fi ọ̀kọ̀-irin gun awọ rẹ̀, tàbí orí rẹ̀ pẹ̀lú ọ̀kọ̀ ìpẹja.
Izali zawadzisz hakami za skórę jego, a widelcami rybackiemi za głowę jego?
8 Fi ọwọ́ rẹ lé e lára, ìwọ ó rántí ìjà náà, ìwọ kì yóò sì ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́.
Połóż tylko nań rękę twą, ślubujęć, że nie wspomnisz więcej na bitwę.
9 Kíyèsi, ìgbìyànjú láti mú un ní asán; ní kìkì ìrí rẹ̀ ara kì yóò ha rọ̀ ọ́ wẹ̀sì?
Oto nadzieja ułowienia jego omylna jest; izali i wejrzawszy nań człowiek nie upada?
10 Kò sí ẹni aláyà lílé tí ó lè ru sókè. Ǹjẹ́ ta ni ó lè dúró níwájú mi.
Niemasz tak śmiałego, coby go obudził; owszem któż się stawi przed twarzą moją?
11 Ta ni ó kọ́kọ́ ṣe fún mi, tí èmi ìbá fi san án fún un? Ohunkóhun ti ń bẹ lábẹ́ ọ̀run gbogbo, tèmi ni.
Któż mi co dał, abym mu oddał? cokolwiek jest pod wszystkiem niebem, moje jest.
12 “Èmi kì yóò fi ẹ̀yà ara Lefitani, tàbí ipá rẹ, tàbí ìhámọ́ra rẹ tí ó ní ẹwà pamọ́.
Nie zamilczę członków jego, ani silnej mocy jego, a grzecznego kształtu jego.
13 Ta ni yóò lè rídìí aṣọ àpáta rẹ̀? Tàbí ta ni ó lè súnmọ́ ọ̀nà méjì eyín rẹ̀?
Któż odkryje wierzch odzienia jego? z dwoistemi wędzidłami swemi któż przystąpi do niego?
14 Ta ni ó lè ṣí ìlẹ̀kùn iwájú rẹ̀? Àyíká ẹ̀yin rẹ ni ìbẹ̀rù ńlá.
Wrota gęby jego któż otworzy? bo strach około zębów jego.
15 Ìpẹ́ lílé ní ìgbéraga rẹ̀; ó pàdé pọ̀ tímọ́tímọ́ bí àmì èdìdì.
Łuski jego mocne jako tarcze, bardzo ściśle spojone.
16 Èkínní fi ara mọ́ èkejì tó bẹ́ẹ̀ tí afẹ́fẹ́ kò lè wọ àárín wọn.
Jedna z drugą tak spojona, że wiatr nie wchodzi między nie.
17 Èkínní fi ara mọ́ èkejì rẹ̀; wọ́n lè wọ́n pọ̀ tí a kò lè mọ̀ wọ́n.
Jedna do drugiej przylgnęła, ujęły się, a nie dzielą się.
18 Nípa sí sin rẹ̀ ìmọ́lẹ̀ á mọ́, ojú rẹ̀ a sì dàbí ìpéǹpéjú òwúrọ̀.
Kichanie jego czyni blask, a oczy jego są jako powieki zorzy.
19 Láti ẹnu rẹ ni ọ̀wọ́-iná ti jáde wá, ìpẹ́pẹ́ iná a sì ta jáde.
Z ust jego lampy wychodzą, a iskry ogniste wyrywają się.
20 Láti ihò imú rẹ ni èéfín ti jáde wá, bí ẹni pé láti inú ìkòkò tí a fẹ́ iná ìfèéfèé lábẹ́ rẹ̀.
Z nozdrzy jego wychodzi dym, jako z garnca wrzącego, albo kotła.
21 Èémí rẹ̀ tiná bọ ẹ̀yin iná, ọ̀wọ́-iná sì ti ẹnu rẹ̀ jáde.
Dech jego węgle rozpala, a płomień z ust jego wychodzi.
22 Ní ọrùn rẹ̀ ní agbára kù sí, àti ìbànújẹ́ àyà sì padà di ayọ̀ níwájú rẹ̀.
W szyi jego przemieszkuje moc, a boleść przed nim ucieka.
23 Jabajaba ẹran rẹ̀ dìjọ pọ̀, wọ́n múra gírí fún ara wọn, a kò lè sí wọn ní ipò.
Sztuki ciała jego spoiły się, całowite są w nim, że się nie porusza.
24 Àyà rẹ̀ dúró gbagidi bí òkúta, àní, ó le bi ìyá ọlọ.
Serce jego twarde jako kamień, tak twarde, jako sztuka spodniego kamienia młyńskiego.
25 Nígbà tí ó bá gbé ara rẹ̀ sókè, àwọn alágbára bẹ̀rù; nítorí ìbẹ̀rù ńlá, wọ́n dààmú.
Gdy się podnosi, drżą mocarze, a od strachu oczyszczają się.
26 Ọ̀kọ̀ tàbí idà, tàbí ọfà, ẹni tí ó ṣá a kò lè rán an.
Miecz, który go sięga, nie ostoi się, ani drzewce, ani strzała, ani pancerz.
27 Ó ká irin sí ibi koríko gbígbẹ àti idẹ si bi igi híhù.
Żelazo poczyta sobie za plewę, a miedź za drzewo zbótwiałe.
28 Ọfà kò lè mú un sá; òkúta kànnakánná lọ́dọ̀ rẹ̀ dàbí àgékù koríko.
Nie upłoszy go strzała, a jako źdźbło są u niego kamienie z procy.
29 Ó ka ẹṣin sí bí àgékù ìdì koríko; ó rẹ́rìn-ín sí mímì ọ̀kọ̀.
Strzelbę sobie poczyta jako słomę, a pośmiewa się z szermowania włócznią.
30 Òkúta mímú ń bẹ nísàlẹ̀ abẹ́ rẹ̀, ó sì tẹ́ ohun mímú ṣóńṣó sórí ẹrẹ̀.
Pod nim są ostre skorupy; ściele sobie na rzeczach ostrych jako na błocie.
31 Ó mú ibú omi hó bí ìkòkò; ó sọ̀ agbami òkun dàbí kólòbó ìkunra.
Czyni, że wre głębokość jako garniec, a że się mąci morze jako w moździerzu.
32 Ó mú ipa ọ̀nà tan lẹ́yìn rẹ̀; ènìyàn a máa ka ibú sí ewú arúgbó.
Za sobą jasną ścieszkę czyni, tak, że się zdaje, iż przepaść ma siwiznę.
33 Lórí ilẹ̀ ayé kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀, tí a dá láìní ìbẹ̀rù.
Niemasz na ziemi równego mu, który tak stworzony jest, że się niczego nie boi.
34 Ó bojú wo ohun gíga gbogbo, ó sì nìkan jásí ọba lórí gbogbo àwọn ọmọ ìgbéraga.”
Wszelką rzecz wysoką lekce waży; on jest królem nad wszystkiemi srogiemi zwierzętami.