< Job 41 >

1 “Ǹjẹ́ ìwọ le è fi ìwọ̀ fa Lefitani jáde? Tàbí ìwọ lè fi okùn so ahọ́n rẹ̀ mọ́lẹ̀?
Prendras-tu le serpent à l'hameçon? passeras-tu dans ses dents une bride?
2 Ìwọ lè fi okùn bọ̀ ọ́ ní í mú, tàbí fi ìwọ̀ ẹ̀gún gun ní ẹ̀rẹ̀kẹ́?
Attacheras-tu à son nez un anneau? perceras-tu ses lèvres d'un cercle?
3 Òun ha jẹ́ bẹ ẹ̀bẹ̀ fún àánú lọ́dọ̀ rẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ bí òun ha bá ọ sọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́?
Te parlera-t-il, te priera-t-il, te fera-t-il entendre de douces supplications?
4 Òun ha bá ọ dá májẹ̀mú bí? Ìwọ ó ha máa mú ṣe ẹrú láéláé bí?
S'engagera-t-il avec toi par un pacte? En feras-tu ton esclave dans les siècles des siècles?
5 Ìwọ ha lè ba sáré bí ẹni pé ẹyẹ ni, tàbí ìwọ ó dè é fún àwọn ọmọbìnrin ìránṣẹ́ rẹ̀?
Te joueras-tu de lui comme d'un oisillon, le mettras-tu en cage comme un passereau pour ton petit enfant?
6 Ẹgbẹ́ àwọn apẹja yóò ha máa tà á bí? Wọn ó ha pín láàrín àwọn oníṣòwò?
Les nations s'en nourrissent; les peuples phéniciens se le partagent.
7 Ìwọ ha lè fi ọ̀kọ̀-irin gun awọ rẹ̀, tàbí orí rẹ̀ pẹ̀lú ọ̀kọ̀ ìpẹja.
Ils attachent de sa peau à leurs navires, et sa tête à leurs barques de pêcheurs.
8 Fi ọwọ́ rẹ lé e lára, ìwọ ó rántí ìjà náà, ìwọ kì yóò sì ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́.
Tu le maîtriseras en te souvenant de la guerre qu'il a causée, et qu'elle ne se renouvelle plus.
9 Kíyèsi, ìgbìyànjú láti mú un ní asán; ní kìkì ìrí rẹ̀ ara kì yóò ha rọ̀ ọ́ wẹ̀sì?
Ne l'as-tu pas vu? N'as-tu pas été surpris de ce qui a été dit?
10 Kò sí ẹni aláyà lílé tí ó lè ru sókè. Ǹjẹ́ ta ni ó lè dúró níwájú mi.
N'as-tu pas été effrayé parce que je l'avais préparé? car quel est celui qui s'était opposé à moi?
11 Ta ni ó kọ́kọ́ ṣe fún mi, tí èmi ìbá fi san án fún un? Ohunkóhun ti ń bẹ lábẹ́ ọ̀run gbogbo, tèmi ni.
Et qui donc après m'avoir contredit persistera, puisque tout ce que le ciel recouvre m'appartient?
12 “Èmi kì yóò fi ẹ̀yà ara Lefitani, tàbí ipá rẹ, tàbí ìhámọ́ra rẹ tí ó ní ẹwà pamọ́.
Je ne me tairai point à cause lui, et la puissance de mes paroles, justes à son regard, excitera sa compassion.
13 Ta ni yóò lè rídìí aṣọ àpáta rẹ̀? Tàbí ta ni ó lè súnmọ́ ọ̀nà méjì eyín rẹ̀?
Qui découvrira la face que voile son vêtement? qui pénétrera jusqu'au fond de sa poitrine?
14 Ta ni ó lè ṣí ìlẹ̀kùn iwájú rẹ̀? Àyíká ẹ̀yin rẹ ni ìbẹ̀rù ńlá.
Qui ouvrira les portes qui le cachent? Le grincement de ses dents inspire à l'entour la terreur.
15 Ìpẹ́ lílé ní ìgbéraga rẹ̀; ó pàdé pọ̀ tímọ́tímọ́ bí àmì èdìdì.
Ses entrailles sont des aspics d'airain; son ensemble est comme de la pierre d'émeri.
16 Èkínní fi ara mọ́ èkejì tó bẹ́ẹ̀ tí afẹ́fẹ́ kò lè wọ àárín wọn.
Les aspérités de son corps sont tout d'une pièce; jamais l'esprit de l'a traversé.
17 Èkínní fi ara mọ́ èkejì rẹ̀; wọ́n lè wọ́n pọ̀ tí a kò lè mọ̀ wọ́n.
Tel un homme est uni à son frère, tels ces deux frères sont toujours inséparables.
18 Nípa sí sin rẹ̀ ìmọ́lẹ̀ á mọ́, ojú rẹ̀ a sì dàbí ìpéǹpéjú òwúrọ̀.
S'il éternue des étincelles jaillissent; ses yeux brillent comme l'étoile du matin.
19 Láti ẹnu rẹ ni ọ̀wọ́-iná ti jáde wá, ìpẹ́pẹ́ iná a sì ta jáde.
Sa bouche vomit comme des lampes, leur flamme se répand à l'entour, comme des brasiers pleins de feu.
20 Láti ihò imú rẹ ni èéfín ti jáde wá, bí ẹni pé láti inú ìkòkò tí a fẹ́ iná ìfèéfèé lábẹ́ rẹ̀.
De ses narines sort une fumée semblable à celle d'une fournaise où brûle de l'anthracite.
21 Èémí rẹ̀ tiná bọ ẹ̀yin iná, ọ̀wọ́-iná sì ti ẹnu rẹ̀ jáde.
Son âme est de charbon embrasé; sa bouche exhale du feu.
22 Ní ọrùn rẹ̀ ní agbára kù sí, àti ìbànújẹ́ àyà sì padà di ayọ̀ níwájú rẹ̀.
La force réside en son encolure; la perdition court devant lui.
23 Jabajaba ẹran rẹ̀ dìjọ pọ̀, wọ́n múra gírí fún ara wọn, a kò lè sí wọn ní ipò.
Les chairs de son corps forment un bloc; elles ont été coulées sur lui; rien ne peut les émouvoir.
24 Àyà rẹ̀ dúró gbagidi bí òkúta, àní, ó le bi ìyá ọlọ.
Son cœur est condensé comme une pierre; il est inflexible comme une enclume.
25 Nígbà tí ó bá gbé ara rẹ̀ sókè, àwọn alágbára bẹ̀rù; nítorí ìbẹ̀rù ńlá, wọ́n dààmú.
S'il se retourne, il répand l'effroi, parmi les bêtes fauves qui bondissent sur la terre.
26 Ọ̀kọ̀ tàbí idà, tàbí ọfà, ẹni tí ó ṣá a kò lè rán an.
Les javelines, les traits, les cuirasses ne peuvent rien contre lui.
27 Ó ká irin sí ibi koríko gbígbẹ àti idẹ si bi igi híhù.
Il fait cas de l'airain comme du bois pourri, et du fer comme de la paille.
28 Ọfà kò lè mú un sá; òkúta kànnakánná lọ́dọ̀ rẹ̀ dàbí àgékù koríko.
La flèche ne le percera pas; la pierre d'une fronde lui fait l'effet d'un brin d'herbe.
29 Ó ka ẹṣin sí bí àgékù ìdì koríko; ó rẹ́rìn-ín sí mímì ọ̀kọ̀.
Les marteaux sont pour lui comme des joncs; il rit des tremblements de terre et des éruptions de flammes.
30 Òkúta mímú ń bẹ nísàlẹ̀ abẹ́ rẹ̀, ó sì tẹ́ ohun mímú ṣóńṣó sórí ẹrẹ̀.
Il a pour couche des obélisques aigus; l'or de la mer qu'il foule aux pieds lui semble une boue dont on ne dit rien.
31 Ó mú ibú omi hó bí ìkòkò; ó sọ̀ agbami òkun dàbí kólòbó ìkunra.
Il fait bouillir l'abîme comme une marmite; il prend la mer pour un vase à parfums,
32 Ó mú ipa ọ̀nà tan lẹ́yìn rẹ̀; ènìyàn a máa ka ibú sí ewú arúgbó.
Le Tartare de l'abîme pour un captif, l'abîme pour un lieu de promenade.
33 Lórí ilẹ̀ ayé kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀, tí a dá láìní ìbẹ̀rù.
Il n'est rien sur la terre de semblable à lui qui a été créé pour être raillé par mes anges.
34 Ó bojú wo ohun gíga gbogbo, ó sì nìkan jásí ọba lórí gbogbo àwọn ọmọ ìgbéraga.”
Il voit tout ce qui s'élève; il est roi de tout ce que contiennent les eaux.

< Job 41 >