< Job 40 >

1 Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé,
Afei Awurade buaa Hiob se,
2 “Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́? Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”
“Nea ɔne Otumfo no wɔ asɛm no bɛteɛ ne so ana? Ma nea ɔbɔ Onyankopɔn kwaadu no mmua no ɛ!”
3 Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,
Na Hiob buaa Awurade se,
4 “Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà? Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.
“Mensɛ na memfata, ɛbɛyɛ dɛn na matumi anya mmuae? Mede me nsa mua mʼano.
5 Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́; lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”
Makasa baako, nanso minni mmuae mprenu so, na merenkasa bio.”
6 Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé,
Afei, Awurade fi ahum mu buaa Hiob se,
7 “Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin, èmi ó bi ọ léèrè, kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
“Hyɛ wo ho den sɛ ɔbarima; mebisa wo nsɛm, na ɛsɛ sɛ wubua me.
8 “Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán? Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo.
“Wobɛka mʼatemmu ho asɛm bɔne ana? Wubebu me fɔ de abu wo ho bem ana?
9 Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?
Wowɔ abasa te sɛ Onyankopɔn de, na wo nne betumi abobɔ mu sɛ ne de ana?
10 Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́, tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.
Ɛno de fa anuonyam ne ɔhyerɛn hyehyɛ wo ho, na fura nidi ne kɛseyɛ.
11 Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde; kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
Hwie wʼabufuwhyew mmoroso no gu, hwɛ ɔhantanni biara na brɛ no ase,
12 Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀ kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
hwɛ ɔhantanni biara na si no fam na tiatia amumɔyɛfo so wɔ faako a wogyina hɔ.
13 Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀, kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú.
Sie wɔn nyinaa bɔ mu wɔ mfutuma mu; kata wɔn anim wɔ ɔda mu.
14 Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé, ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.
Na afei mʼankasa megye ato mu sɛ wo ara wo basa nifa betumi agye wo nkwa.
15 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti, tí mo dá pẹ̀lú rẹ, òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
“Hwɛ susono, nea meyɛɛ no kaa wo ho na ɔwe sare te sɛ nantwi.
16 Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
Hwɛ ahoɔden a ɔwɔ wɔ nʼasen mu ne ahoɔden a ɛwɔ ne yafunu so were mu!
17 Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari, iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.
Ne dua hinhim sɛ sida; ne srɛ mu ntin yɛ peperee.
18 Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ, Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
Ne nnompe te sɛ kɔbere mfrafrae dorobɛn, nʼabasa ne ne nʼanan te sɛ nnade praban.
19 Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run; síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
Odi Onyankopɔn nsa ano adwuma mu kan, nanso ne Yɛfo betumi de nʼafoa akɔ ne so.
20 Nítòótọ́ òkè ńlá ńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá, níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.
Nkoko fifi wɔn nnɔbae ma no, na wuram mmoa nyinaa goru bɛn hɔ.
21 Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì, lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.
Nsɔensɔe nnua ase na ɔda, na dontori mu demmire akata no so.
22 Igi lótusì síji wọn bò o; igi arọrọ odò yí i káàkiri.
Nsɔensɔe nwini no kata ne so; na nsunoa nnua twa ne ho hyia.
23 Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ; ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.
Nsu nworoso nhaw no; mpo sɛ Yordan bobɔ ba nʼano a, onni ɔhaw.
24 Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀, tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?
Obi betumi akyere no animono; anaa obi betumi de afiri ayi no na wabɔre ne hwene mu ana?

< Job 40 >