< Job 40 >

1 Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé,
Então o SENHOR respondeu mais a Jó, dizendo:
2 “Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́? Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”
Por acaso quem briga contra o Todo-Poderoso pode ensiná-lo? Quem quer repreender a Deus, responda a isto.
3 Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,
Então Jó respondeu ao SENHOR, dizendo:
4 “Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà? Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.
Eis que eu sou insignificante; o que eu te responderia? Ponho minha mão sobre minha boca.
5 Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́; lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”
Uma vez falei, porém não responderei; até duas vezes, porém não prosseguirei.
6 Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé,
Então o SENHOR respondeu a Jó desde o redemoinho, dizendo:
7 “Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin, èmi ó bi ọ léèrè, kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
Cinge-te agora os teus lombos como homem; eu te perguntarei, e tu me explica.
8 “Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán? Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo.
Por acaso tu anularias o meu juízo? Tu me condenarias, para te justificares?
9 Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?
Tens tu braço como Deus? Ou podes tu trovejar com [tua] voz como ele?
10 Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́, tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.
Orna-te, pois, de excelência e alteza; e veste-te de majestade e glória.
11 Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde; kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
Espalha os furores de tua ira; olha a todo soberbo, e abate-o.
12 Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀ kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
Olha a todo soberbo, e humilha-o; e esmaga aos perversos em seu lugar.
13 Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀, kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú.
Esconde-os juntamente no pó; ata seus rostos no oculto.
14 Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé, ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.
E eu também te reconhecerei; pois tua mão direita te terá livrado.
15 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti, tí mo dá pẹ̀lú rẹ, òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
Observa o beemote, ao qual eu fiz contigo; ele come erva come como o boi.
16 Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
Eis que sua força está em seus lombos, e seu poder na musculatura de seu ventre.
17 Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari, iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.
Ele torna sua cauda dura como o cedro, e os nervos de suas coxas são entretecidos.
18 Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ, Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
Seus ossos são [como] tubos de bronze; seus membros, como barras de ferro.
19 Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run; síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
Ele é a obra-prima dos caminhos de Deus; aquele que o fez o proveu de sua espada.
20 Nítòótọ́ òkè ńlá ńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá, níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.
Pois os montes lhe produzem pasto; por isso todos os animais do campo ali se alegram.
21 Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì, lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.
Ele se deita debaixo das árvores sombrias; no esconderijo das canas e da lama.
22 Igi lótusì síji wọn bò o; igi arọrọ odò yí i káàkiri.
As árvores sombrias o cobrem, cada uma com sua sombra; os salgueiros do ribeiro o cercam.
23 Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ; ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.
Ainda que o rio se torne violento, ele não se apressa; confia ainda que o Jordão transborde até sua boca.
24 Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀, tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?
Poderiam, por acaso, capturá-lo à vista de seus olhos, [ou] com laços furar suas narinas?

< Job 40 >