< Job 40 >

1 Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé,
A tak odpowiedział Pan Ijobowi, i rzekł:
2 “Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́? Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”
Izali ten, co wiedzie spór z Wszechmogącym, uczyć go będzie? a kto chce strofować Boga, niech na to odpowie.
3 Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,
Zatem odpowiedział Ijob Panu, i rzekł:
4 “Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà? Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.
Otom ja lichy, cóż ci mam odpowiedzieć? Rękę moję włożę na usta moje.
5 Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́; lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”
Mówiłem raz i drugi, ale więcej nie odpowiem, i nic więcej nie przydam.
6 Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé,
Nadto odpowiedział Pan Ijobowi z wichru, i rzekł:
7 “Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin, èmi ó bi ọ léèrè, kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
Przepasz teraz jako mąż biodra swe: będę cię pytał, a ty mi daj sprawę;
8 “Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán? Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo.
Izali wniwecz obrócisz sąd mój? a obwinisz mię, abyś się sam usprawiedliwił?
9 Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?
Izali masz ramię jako Bóg? a głosem zagrzmisz jako on?
10 Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́, tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.
Ozdóbże się teraz zacnością i dostojnością, a w chwałę i w ochędóstwo oblecz się.
11 Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde; kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
Rozpostrzyj popędliwość gniewu twego, a patrz na każdego pysznego, i poniż go.
12 Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀ kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
Spojrzyjże na każdego hardego a skróć go, a zetrzyj niepobożnych na miejscu ich.
13 Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀, kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú.
Zakryj ich pospołu w prochu, a oblicza ich zawiąż w skrytości.
14 Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé, ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.
Tedyć i Ja przyznam, że cię może zachować prawica twoja.
15 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti, tí mo dá pẹ̀lú rẹ, òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
Oto teraz słoń, któregom uczynił jako i ciebie, trawę je jako wół.
16 Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
Oto teraz moc jego jest w biodrach jego, a siła jego w pępku brzucha jego.
17 Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari, iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.
Rusza ogonem swoim, jako chce, choć jest jako drzewo cedrowe; żyły łona jego są powikłane jako latorośli.
18 Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ, Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
Kości jego jako trąby miedziane; gnaty jego jako drąg żelazny.
19 Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run; síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
On jest przedniejszym z uczynków Bożych; który go uczynił, sam nań natrzeć może mieczem swoim.
20 Nítòótọ́ òkè ńlá ńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá, níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.
Jemuć pastwę góry przynoszą, a wszystek zwierz polny tam igra.
21 Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì, lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.
Pod cienistem drzewem lega w skrytościach trzciny i błota.
22 Igi lótusì síji wọn bò o; igi arọrọ odò yí i káàkiri.
Okrywają go drzewa cieniste cieniem swoim, a ogarniają go wierzby nad potokami.
23 Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ; ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.
Oto zatrzymuje strumień, że się nie spieszy; tuszy sobie, iż Jordan wypije gębą swoją.
24 Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀, tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?
Azali go kto przed oczyma jego ułapi? albo powrozy przeciągnie przez nozdrze jego?

< Job 40 >