< Job 40 >
1 Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé,
INkosi yasiphendula uJobe yathi:
2 “Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́? Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”
Ophikisana loSomandla uzamqondisa yini? Osola uNkulunkulu kakuphendule.
3 Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,
UJobe waseyiphendula iNkosi wathi:
4 “Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà? Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.
Khangela, ngiphansi; ngingakuphendula ngithini? Ngibeka isandla sami emlonyeni wami.
5 Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́; lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”
Ngikhulumile kanye, kodwa kangiyikuphendula; kumbe kabili, kodwa kangiyikuqhubeka.
6 Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé,
INkosi yasimphendula uJobe isesivunguzaneni yathi:
7 “Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin, èmi ó bi ọ léèrè, kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
Bopha khathesi ukhalo lwakho njengendoda; ngizakubuza, ubusungazisa.
8 “Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán? Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo.
Isibili, uzachitha isahlulelo sami yini? Ungilahle, ukuze ube ngolungileyo yini?
9 Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?
Njalo ulengalo yini njengoNkulunkulu? Kumbe ungaduma yini ngelizwi njengaye?
10 Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́, tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.
Khathesi zicecise ngobukhosi lokuphakama, uzembese ngodumo lenkazimulo.
11 Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde; kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
Usabalalise intukuthelo zolaka lwakho, ukhangele wonke ozigqajayo, umthobise.
12 Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀ kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
Khangela wonke ozigqajayo, umehlisele phansi, unyathelele phansi ababi endaweni yabo.
13 Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀, kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú.
Ubafihle bonke ethulini, ubophe ubuso babo ngasese.
14 Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé, ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.
Khona lami ngizavuma kuwe, ukuthi isandla sakho sokunene singakusindisa.
15 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti, tí mo dá pẹ̀lú rẹ, òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
Ake ukhangele imvubu engayenza kanye lawe; idla utshani njengenkabi.
16 Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
Ake ukhangele, amandla ayo asekhalweni lwayo, lokuqina kwayo kusemisipheni yesisu sayo.
17 Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari, iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.
Iyagobisa umsila wayo njengomsedari; imisipha yemilenze yayo yelukene.
18 Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ, Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
Amathambo ayo anjengempompi zethusi, amathambo ayo anjengemigoqo yensimbi.
19 Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run; síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
Ingeyokuqala yezindlela zikaNkulunkulu; owayenzayo wasondeza inkemba yayo.
20 Nítòótọ́ òkè ńlá ńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá, níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.
Ngoba intaba ziyayivezela ukudla, lapho okudlala khona inyamazana zonke zeganga.
21 Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì, lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.
Ilala phansi kwesihlahla esiluhlaza, ekusithekeni kwemihlanga lamaxhaphozi.
22 Igi lótusì síji wọn bò o; igi arọrọ odò yí i káàkiri.
Izihlahla eziluhlaza ziyayisibekela ngomthunzi wazo; imidubu yesifula iyayiphahla.
23 Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ; ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.
Khangela, umfula uyayicindezela, kayiphangisi; ilesibindi lanxa iJordani ingaphuphumela emlonyeni wayo.
24 Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀, tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?
Ongayibamba yini ngamehlo ayo? Ongahlaba yini amakhala ayo ngemijibila?