< Job 40 >

1 Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé,
És felelt az Örökkévaló Jóbnak és mondta:
2 “Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́? Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”
Pörölni mer-e a Mindenhatóval a gáncsoló? Istennek a feddője feleljen rá!
3 Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,
S felelt Jób az Örökkévalónak és mondta:
4 “Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà? Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.
Lám, csekély vagyok, mit válaszoljak neked? Szájamra tettem kezemet;
5 Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́; lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”
egyet szóltam – nem felelhetek, kettőt, de nem teszem többé.
6 Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé,
S felelt az Örökkévaló Jóbnak a viharból és mondta:
7 “Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin, èmi ó bi ọ léèrè, kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
Övezd csak fel férfiként ágyékidat, hadd kérdelek s te tudasd velem.
8 “Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán? Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo.
Vajon ítéletemet bontod-e meg, kárhoztatsz engem, hogy neked legyen igazad?
9 Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?
Hát van-e karod olyan mint Istené, és olyan hanggal. dörögsz-e mint ő?
10 Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́, tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.
Ékesítsd csak magadat büszkeséggel és fenséggel, dicsőséget és díszt ölts fel!
11 Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde; kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
Szórd szét haragod kitöréseit, s láss minden büszkét és alacsonyítsd le;
12 Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀ kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
láss minden büszkét és alázd meg és zúzd össze a gonoszokat a maguk helyén;
13 Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀, kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú.
rejtsd el őket a porba egyaránt, kötözd le arczukat a rejtekbe:
14 Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé, ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.
akkor én is magasztallak téged, hogy tenjobbod segít neked.
15 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti, tí mo dá pẹ̀lú rẹ, òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
Íme csak a víziló, melyet alkottam, mint tégedet: füvet eszik mint a marha.
16 Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
Íme csak, derekában van az ereje, és hatalma hasának izmaiban.
17 Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari, iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.
Mereszti farkát, akár a czédrus, czombjainak inai összefonódnak.
18 Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ, Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
Csontjai érczcsatornák, tagjai akár a vasdorong.
19 Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run; síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
Ő Isten útjainak eleje, a ki alkotta, oda nyújtotta kardját
20 Nítòótọ́ òkè ńlá ńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá, níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.
Mert takarmányt a hegyek teremnek neki, s a mező minden vadja játszadozik ott.
21 Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì, lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.
Lótuscserjék alatt fekszik, nádnak és mocsárnak rejtekében.
22 Igi lótusì síji wọn bò o; igi arọrọ odò yí i káàkiri.
Befödik őt árnyékául lótus-cserjék, a patak fűzei körülveszik őt.
23 Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ; ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.
Ha folyam szorongatja, nem ijed meg, bizakodik, midőn egy Jordán tör szájába.
24 Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀, tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?
Szemei láttára megfoghatni-e őt, tőrökkel átlyukasztva az orrát?

< Job 40 >