< Job 40 >

1 Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé,
And he answered Yahweh Job and he said.
2 “Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́? Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”
¿ Will he contend with [the] Almighty a faultfinder [one who] corrects God let him answer him.
3 Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,
And he answered Job Yahweh and he said.
4 “Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà? Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.
Here! I am insignificant what? will I respond to you hand my I put to mouth my.
5 Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́; lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”
One [time] I have spoken and not I will answer and two [times] and not I will repeat.
6 Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé,
And he answered Yahweh Job (from - *Q(K)*) (a tempest *Q(k)*) and he said.
7 “Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin, èmi ó bi ọ léèrè, kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
Gird up please like a man loins your I will ask you and make known to me.
8 “Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán? Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo.
¿ Even will you annul justice my will you condemn as guilty? me so that you may be justified.
9 Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?
And or? [does] an arm like God - [belong] to you? and with a voice like him will you thunder?
10 Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́, tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.
Deck yourself please majesty and dignity and glory and honor you will be clothed.
11 Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde; kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
Scatter [the] furi of anger your and see every proud [person] and bring low him.
12 Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀ kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
See every proud [person] humble him and tread down wicked [people] in place their.
13 Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀, kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú.
Hide them in the dust together faces their bind up in the hidden [place].
14 Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé, ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.
And also I I will praise you that it will save you right [hand] your.
15 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti, tí mo dá pẹ̀lú rẹ, òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
There! please Behemoth which I made with you grass like ox it eats.
16 Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
There! please strength its [is] in loins its and power its in [the] muscles of belly its.
17 Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari, iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.
It stiffens tail its like a cedar [the] sinews of (thighs its *Q(K)*) they are intertwined.
18 Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ, Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
Bones its [are] tubes of bronze limbs its [are] like a rod of iron.
19 Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run; síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
It [is] [the] first of [the] ways of God the [one who] made it let him bring near sword his.
20 Nítòótọ́ òkè ńlá ńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá, níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.
For [the] beast[s] of [the] mountains they carry to it and every animal of the field they play there.
21 Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì, lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.
Under thorny lotus plants it lies in a hiding place of reed[s] and swamp.
22 Igi lótusì síji wọn bò o; igi arọrọ odò yí i káàkiri.
They cover it thorny lotus plants shade its they surround it [the] poplars of [the] wadi.
23 Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ; ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.
There! it is violent [the] river not it is alarmed it is confident - for it bursts forth [the] Jordan to mouth its.
24 Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀, tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?
By eyes its will anyone take? it with snares will anyone pierce? a nose.

< Job 40 >