< Job 40 >

1 Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé,
And Yahweh responded to Job, and said: —
2 “Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́? Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”
Shall a reprover contend, with the Almighty? He that disputeth with GOD, let him answer it!
3 Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,
Then Job responded to Yahweh, and said: —
4 “Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà? Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.
Lo! I am of no account, what shall I reply to thee? My hand, have I laid on my mouth:
5 Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́; lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”
Once, have I spoken, but I will not proceed, yea twice, but I will not add.
6 Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé,
So then Yahweh responded to Job, out of a storm, and said: —
7 “Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin, èmi ó bi ọ léèrè, kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
Gird, I pray thee—as a strong man—thy loins, I will ask thee, and inform thou me.
8 “Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán? Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo.
Wilt thou even frustrate my justice? Wilt thou condemn me, that thou mayest appear right?
9 Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?
But if, an arm like GOD, thou hast, and, with a voice like his, thou canst thunder,
10 Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́, tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.
Deck thyself, I pray thee, with majesty and grandeur, Yea, with dignity and splendour, thou shalt clothe thyself;
11 Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde; kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
Pour out thy transports of anger, and look on every one who is high, and lay him low;
12 Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀ kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
Look on every one who is high, and humble him, yea tread down the lawless, on the spot:
13 Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀, kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú.
Hide them in the dust all together, Their faces, bind thou in darkness;
14 Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé, ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.
And, even I myself, will praise thee, in that thine own right hand can bring thee salvation.
15 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti, tí mo dá pẹ̀lú rẹ, òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
Behold, I pray thee, the Hippopotamus, which I made with thee, Grass—like the ox, he eateth;
16 Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
Behold, I pray thee, his strength in his loins, and his force, in the muscles of his belly;
17 Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari, iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.
He bendeth down his tail like a cedar, the sinews of his thighs, are twisted together;
18 Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ, Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
His bones, are barrels of bronze, his frame, is like hammered bars of iron:
19 Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run; síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
He, is the beginning of the ways of GOD, Let his maker, present him his sword:
20 Nítòótọ́ òkè ńlá ńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá, níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.
Surely the mountains bring, produce, to him, where, all the wild beasts of the field, do play;
21 Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì, lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.
Under the lotus-trees, he lieth down, in a covert of reed and swamp;
22 Igi lótusì síji wọn bò o; igi arọrọ odò yí i káàkiri.
The lotus-trees cover him with their shade, the willows of the torrent-bed compass him about;
23 Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ; ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.
Lo! the river becometh insolent—he is not alarmed! He is confident, though a Jordan burst forth to his mouth:
24 Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀, tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?
Before his eyes, shall he be caught? With a hook, can one pierce his nose?

< Job 40 >