< Job 40 >
1 Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé,
Moreover the LORD answered Job, and said:
2 “Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́? Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”
Shall he that reproveth contend with the Almighty? He that argueth with God, let him answer it.
3 Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,
Then Job answered the LORD, and said:
4 “Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà? Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.
Behold, I am of small account; what shall I answer Thee? I lay my hand upon my mouth.
5 Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́; lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”
Once have I spoken, but I will not answer again; yea, twice, but I will proceed no further.
6 Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé,
Then the LORD answered Job out of the whirlwind, and said:
7 “Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin, èmi ó bi ọ léèrè, kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
Gird up thy loins now like a man; I will demand of thee, and declare thou unto Me.
8 “Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán? Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo.
Wilt thou even make void My judgment? Wilt thou condemn Me, that thou mayest be justified?
9 Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?
Or hast thou an arm like God? And canst thou thunder with a voice like Him?
10 Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́, tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.
Deck thyself now with majesty and excellency, and array thyself with glory and beauty.
11 Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde; kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
Cast abroad the rage of thy wrath; and look upon every one that is proud, and abase him.
12 Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀ kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
Look on every one that is proud, and bring him low; and tread down the wicked in their place.
13 Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀, kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú.
Hide them in the dust together; bind their faces in the hidden place.
14 Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé, ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.
Then will I also confess unto thee that thine own right hand can save thee.
15 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti, tí mo dá pẹ̀lú rẹ, òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
Behold now behemoth, which I made with thee; he eateth grass as an ox.
16 Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
Lo now, his strength is in his loins, and his force is in the stays of his body.
17 Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari, iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.
He straineth his tail like a cedar; the sinews of his thighs are knit together.
18 Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ, Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
His bones are as pipes of brass; his gristles are like bars of iron.
19 Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run; síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
He is the beginning of the ways of God; He only that made him can make His sword to approach unto him.
20 Nítòótọ́ òkè ńlá ńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá, níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.
Surely the mountains bring him forth food, and all the beasts of the field play there.
21 Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì, lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.
He lieth under the lotus-trees, in the covert of the reed, and fens.
22 Igi lótusì síji wọn bò o; igi arọrọ odò yí i káàkiri.
The lotus-trees cover him with their shadow; the willows of the brook compass him about.
23 Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ; ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.
Behold, if a river overflow, he trembleth not; he is confident, though the Jordan rush forth to his mouth.
24 Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀, tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?
Shall any take him by his eyes, or pierce through his nose with a snare?