< Job 4 >

1 Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani dáhùn wí pé,
Därefter tog Elifas från Teman till orda och sade:
2 “Bí àwa bá fi ẹnu lé e, láti bá ọ sọ̀rọ̀, ìwọ o ha banújẹ́? Ṣùgbọ́n ta ni ó lè pa ọ̀rọ̀ mọ́ ẹnu láìsọ?
Misstycker du, om man dristar tala till dig? Vem kan hålla tillbaka sina ord?
3 Kíyèsi i, ìwọ sá ti kọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn, ìwọ ṣá ti mú ọwọ́ aláìlera le.
Se, många har du visat till rätta, och maktlösa händer har du stärkt;
4 Ọ̀rọ̀ rẹ ti gbé àwọn tí ń ṣubú lọ dúró, ìwọ sì ti mú eékún àwọn tí ń wárìrì lera.
dina ord hava upprättat den som stapplade, och åt vacklande knän har du givit kraft.
5 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ó dé bá ọ, ó sì rẹ̀ ọ́, ó kọlù ọ́; ara rẹ kò lélẹ̀.
Men nu, då det gäller dig själv, bliver du otålig, när det är dig det drabbar, förskräckes du.
6 Ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ kò ha jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ àti ìdúró ọ̀nà rẹ kò ha sì jẹ́ ìrètí rẹ?
Skulle då icke din gudsfruktan vara din tillförsikt och dina vägars ostrafflighet ditt hopp?
7 “Èmi bẹ̀ ọ́ rántí, ta ni ó ṣègbé rí láìṣẹ̀? Tàbí níbo ni a gbé gé olódodo kúrò rí?
Tänk efter: när hände det att en oskyldig fick förgås? och var skedde det att de redliga måste gå under?
8 Àní bí èmi ti rí i pé, àwọn tí ń ṣe ìtulẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀, tí wọ́n sì fún irúgbìn ìwà búburú, wọn a sì ká èso rẹ̀ náà.
Nej, så har jag sett det gå, att de som plöja fördärv och de som utså olycka, de skörda och sådant;
9 Nípa ìfẹ́ sí Ọlọ́run wọn a ṣègbé, nípa èémí ìbínú rẹ̀ wọn a parun.
för Guds andedräkt förgås de och för en fnysning av hans näsa försvinna de.
10 Bíbú ramúramù kìnnìún àti ohùn òǹrorò kìnnìún àti eyín àwọn ẹgbọrọ kìnnìún ní a ká.
Ja, lejonets skri och rytarens röst måste tystna, och unglejonens tänder brytas ut;
11 Kìnnìún kígbe, nítorí àìrí ohun ọdẹ, àwọn ẹgbọrọ kìnnìún sísanra ni a túká kiri.
Det gamla lejonet förgås, ty det finner intet rov, och lejoninnans ungar bliva förströdda.
12 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí a fi ohun àṣírí kan hàn fún mi, etí mi sì gbà díẹ̀ nínú rẹ̀.
Men till mig smög sakta ett ord, mitt öra förnam det likasom en viskning,
13 Ní ìrò inú lójú ìran òru, nígbà tí oorun èjìká kùn ènìyàn.
När tankarna svävade om vid nattens syner och sömnen föll tung på människorna,
14 Ẹ̀rù bà mí àti ìwárìrì tí ó mú gbogbo egungun mi jí pépé.
då kom en förskräckelse och bävan över mig, med rysning fyllde den alla ben i min kropp.
15 Nígbà náà ni ẹ̀mí kan kọjá lọ ní iwájú mi, irun ara mi dìde dúró ṣánṣán.
En vindpust for fram över mitt ansikte, därvid reste sig håren på min kropp.
16 Ó dúró jẹ́ẹ́, ṣùgbọ́n èmi kò le wo àpẹẹrẹ ìrí rẹ̀, àwòrán kan hàn níwájú mi, ìdákẹ́rọ́rọ́ wà, mo sì gbóhùn kan wí pé,
Och något trädde inför mina ögon, en skepnad vars form jag icke skönjde; och jag hörde en susning och en röst:
17 ‘Ẹni kíkú le jẹ́ olódodo ju Ọlọ́run, ènìyàn ha le mọ́ ju ẹlẹ́dàá rẹ̀ bí?
"Kan då en människa hava rätt mot Gud eller en man vara ren inför sin skapare?
18 Kíyèsi i, òun kò gbẹ́kẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, nínú àwọn angẹli rẹ̀ ní ó sì rí ẹ̀ṣẹ̀.
Se, ej ens på sina tjänare kan han förlita sig, jämväl sina änglar måste han tillvita fel;
19 Mélòó mélòó àwọn tí ń gbé inú ilé amọ̀, ẹni tí ìpìlẹ̀ wọ́n jásí erùpẹ̀ tí yóò di rírun kòkòrò.
huru mycket mer då dem som bo i hyddor av ler, dem som hava sin grundval i stoftet! De krossas sönder så lätt som mal;
20 A pa wọ́n run láàrín òwúrọ̀ àti àṣálẹ́ wọ́n sì parun títí láé, láìrí ẹni kà á sí.
när morgon har bytts till afton, ligga de slagna; innan man aktar därpå, hava de förgåtts för alltid.
21 A kò ha ké okùn iye wọ́n kúrò bí? Wọ́n kú, àní láìlọ́gbọ́n?’
Ja, deras hyddas fäste ryckes bort för dem, oförtänkt måste de dö."

< Job 4 >