< Job 4 >

1 Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani dáhùn wí pé,
Wtedy Elifaz z Temanu odpowiedział:
2 “Bí àwa bá fi ẹnu lé e, láti bá ọ sọ̀rọ̀, ìwọ o ha banújẹ́? Ṣùgbọ́n ta ni ó lè pa ọ̀rọ̀ mọ́ ẹnu láìsọ?
Jeśli będziemy rozmawiać z tobą, nie będzie ci przykro? Ale któż może się od mówienia powstrzymać?
3 Kíyèsi i, ìwọ sá ti kọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn, ìwọ ṣá ti mú ọwọ́ aláìlera le.
Oto nauczałeś wielu i ręce słabe umocniłeś.
4 Ọ̀rọ̀ rẹ ti gbé àwọn tí ń ṣubú lọ dúró, ìwọ sì ti mú eékún àwọn tí ń wárìrì lera.
Twoje słowa podnosiły upadającego, a omdlałe kolana wzmacniałeś.
5 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ó dé bá ọ, ó sì rẹ̀ ọ́, ó kọlù ọ́; ara rẹ kò lélẹ̀.
A teraz, gdy [to] przyszło na ciebie, opadasz z sił, dotknęło cię i się trwożysz.
6 Ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ kò ha jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ àti ìdúró ọ̀nà rẹ kò ha sì jẹ́ ìrètí rẹ?
Czy twoja bojaźń nie była twoją ufnością, a prawość twoich dróg – twoją nadzieją?
7 “Èmi bẹ̀ ọ́ rántí, ta ni ó ṣègbé rí láìṣẹ̀? Tàbí níbo ni a gbé gé olódodo kúrò rí?
Przypomnij sobie, proszę, czy kiedykolwiek zginął ktoś niewinny? Albo gdzie sprawiedliwych wytępiono?
8 Àní bí èmi ti rí i pé, àwọn tí ń ṣe ìtulẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀, tí wọ́n sì fún irúgbìn ìwà búburú, wọn a sì ká èso rẹ̀ náà.
Według tego, co zauważyłem, ci, którzy orzą zło i sieją niegodziwość, zbierają je.
9 Nípa ìfẹ́ sí Ọlọ́run wọn a ṣègbé, nípa èémí ìbínú rẹ̀ wọn a parun.
Od tchnienia Boga giną i od powiewu jego gniewu niszczeją.
10 Bíbú ramúramù kìnnìún àti ohùn òǹrorò kìnnìún àti eyín àwọn ẹgbọrọ kìnnìún ní a ká.
Ryk lwa, głos dzikiego lwa i zęby lwiątek są złamane.
11 Kìnnìún kígbe, nítorí àìrí ohun ọdẹ, àwọn ẹgbọrọ kìnnìún sísanra ni a túká kiri.
Lew ginie z braku łupu i młode lwicy rozpraszają się.
12 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí a fi ohun àṣírí kan hàn fún mi, etí mi sì gbà díẹ̀ nínú rẹ̀.
Oto potajemnie doszło do mnie słowo i moje ucho usłyszało szept.
13 Ní ìrò inú lójú ìran òru, nígbà tí oorun èjìká kùn ènìyàn.
W rozmyślaniu o nocnych widzeniach, gdy twardy sen spada na ludzi;
14 Ẹ̀rù bà mí àti ìwárìrì tí ó mú gbogbo egungun mi jí pépé.
Ogarnęły mnie strach i drżenie, od których wszystkie moje kości zadrżały.
15 Nígbà náà ni ẹ̀mí kan kọjá lọ ní iwájú mi, irun ara mi dìde dúró ṣánṣán.
Wtedy duch przeszedł przed moją twarzą, zjeżyły się włosy na moim ciele.
16 Ó dúró jẹ́ẹ́, ṣùgbọ́n èmi kò le wo àpẹẹrẹ ìrí rẹ̀, àwòrán kan hàn níwájú mi, ìdákẹ́rọ́rọ́ wà, mo sì gbóhùn kan wí pé,
Stanął, lecz nie rozpoznałem jego wyglądu, [tylko jakiś] kształt [był] przed moimi oczami; nastała cisza, a potem usłyszałem głos [mówiący]:
17 ‘Ẹni kíkú le jẹ́ olódodo ju Ọlọ́run, ènìyàn ha le mọ́ ju ẹlẹ́dàá rẹ̀ bí?
Czy śmiertelny człowiek może być sprawiedliwszy niż Bóg? Czy człowiek [może być] czystszy niż jego Stwórca?
18 Kíyèsi i, òun kò gbẹ́kẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, nínú àwọn angẹli rẹ̀ ní ó sì rí ẹ̀ṣẹ̀.
Oto swoim sługom nie ufa i w swoich aniołach dostrzega braki;
19 Mélòó mélòó àwọn tí ń gbé inú ilé amọ̀, ẹni tí ìpìlẹ̀ wọ́n jásí erùpẹ̀ tí yóò di rírun kòkòrò.
O ileż bardziej w tych, którzy mieszkają w domach glinianych, których podstawa jest w prochu – łatwiej [ich] zgnieść niż mola.
20 A pa wọ́n run láàrín òwúrọ̀ àti àṣálẹ́ wọ́n sì parun títí láé, láìrí ẹni kà á sí.
Od poranka aż do wieczora są gładzeni; giną na wieki, a nikt [tego] nie zauważa.
21 A kò ha ké okùn iye wọ́n kúrò bí? Wọ́n kú, àní láìlọ́gbọ́n?’
Czy ich wspaniałość nie przemija wraz z nimi? Umierają, ale nie w mądrości.

< Job 4 >