< Job 4 >

1 Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani dáhùn wí pé,
Then Eliphaz the Temanite answered and said,
2 “Bí àwa bá fi ẹnu lé e, láti bá ọ sọ̀rọ̀, ìwọ o ha banújẹ́? Ṣùgbọ́n ta ni ó lè pa ọ̀rọ̀ mọ́ ẹnu láìsọ?
[If] we essay to commune with thee, wilt thou be grieved? but who can refrain from speaking?
3 Kíyèsi i, ìwọ sá ti kọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn, ìwọ ṣá ti mú ọwọ́ aláìlera le.
Behold, thou hast instructed many, and thou hast strengthened the weak hands.
4 Ọ̀rọ̀ rẹ ti gbé àwọn tí ń ṣubú lọ dúró, ìwọ sì ti mú eékún àwọn tí ń wárìrì lera.
Thy words have upheld him that was falling, and thou hast strengthened the feeble knees.
5 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ó dé bá ọ, ó sì rẹ̀ ọ́, ó kọlù ọ́; ara rẹ kò lélẹ̀.
But now it hath come upon thee, and thou faintest; it toucheth thee, and thou art troubled.
6 Ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ kò ha jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ àti ìdúró ọ̀nà rẹ kò ha sì jẹ́ ìrètí rẹ?
[Is] not [this] thy fear, thy confidence, thy hope, and the uprightness of thy ways?
7 “Èmi bẹ̀ ọ́ rántí, ta ni ó ṣègbé rí láìṣẹ̀? Tàbí níbo ni a gbé gé olódodo kúrò rí?
Remember, I pray thee, who [ever] perished, being innocent? or where were the righteous cut off;
8 Àní bí èmi ti rí i pé, àwọn tí ń ṣe ìtulẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀, tí wọ́n sì fún irúgbìn ìwà búburú, wọn a sì ká èso rẹ̀ náà.
Even as I have seen, they that plow iniquity, and sow wickedness, reap the same.
9 Nípa ìfẹ́ sí Ọlọ́run wọn a ṣègbé, nípa èémí ìbínú rẹ̀ wọn a parun.
By the blast of God they perish, and by the breath of his nostrils are they consumed.
10 Bíbú ramúramù kìnnìún àti ohùn òǹrorò kìnnìún àti eyín àwọn ẹgbọrọ kìnnìún ní a ká.
The roaring of the lion, and the voice of the fierce lion, and the teeth of the young lions, are broken.
11 Kìnnìún kígbe, nítorí àìrí ohun ọdẹ, àwọn ẹgbọrọ kìnnìún sísanra ni a túká kiri.
The old lion perisheth for lack of prey, and the stout lion's whelps are scattered abroad.
12 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí a fi ohun àṣírí kan hàn fún mi, etí mi sì gbà díẹ̀ nínú rẹ̀.
Now a thing was secretly brought to me, and my ear received a small sound of it.
13 Ní ìrò inú lójú ìran òru, nígbà tí oorun èjìká kùn ènìyàn.
In thoughts from the visions of the night, when deep sleep falleth on men.
14 Ẹ̀rù bà mí àti ìwárìrì tí ó mú gbogbo egungun mi jí pépé.
Fear came upon me, and trembling, which made all my bones to shake.
15 Nígbà náà ni ẹ̀mí kan kọjá lọ ní iwájú mi, irun ara mi dìde dúró ṣánṣán.
Then a spirit passed before my face; the hair of my flesh stood up:
16 Ó dúró jẹ́ẹ́, ṣùgbọ́n èmi kò le wo àpẹẹrẹ ìrí rẹ̀, àwòrán kan hàn níwájú mi, ìdákẹ́rọ́rọ́ wà, mo sì gbóhùn kan wí pé,
It stood still, but I could not discern its form: an image [was] before my eyes, [there was] silence, and I heard a voice, [saying],
17 ‘Ẹni kíkú le jẹ́ olódodo ju Ọlọ́run, ènìyàn ha le mọ́ ju ẹlẹ́dàá rẹ̀ bí?
Shall mortal man be more just than God? shall a man be more pure than his maker?
18 Kíyèsi i, òun kò gbẹ́kẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, nínú àwọn angẹli rẹ̀ ní ó sì rí ẹ̀ṣẹ̀.
Behold, he put no trust in his servants; and his angels he charged with folly:
19 Mélòó mélòó àwọn tí ń gbé inú ilé amọ̀, ẹni tí ìpìlẹ̀ wọ́n jásí erùpẹ̀ tí yóò di rírun kòkòrò.
How much less [in] them that dwell in houses of clay, whose foundation [is] in the dust, [who] are crushed before the moth?
20 A pa wọ́n run láàrín òwúrọ̀ àti àṣálẹ́ wọ́n sì parun títí láé, láìrí ẹni kà á sí.
They are destroyed from morning to evening: they perish for ever without any regarding [it].
21 A kò ha ké okùn iye wọ́n kúrò bí? Wọ́n kú, àní láìlọ́gbọ́n?’
Doth not their excellence [which is] in them depart? they die, even without wisdom.

< Job 4 >