< Job 4 >
1 Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani dáhùn wí pé,
Then Eliphaz the Thaemanite answered and said,
2 “Bí àwa bá fi ẹnu lé e, láti bá ọ sọ̀rọ̀, ìwọ o ha banújẹ́? Ṣùgbọ́n ta ni ó lè pa ọ̀rọ̀ mọ́ ẹnu láìsọ?
Hast you been often spoken to in distress? but who shall endure the force of your words?
3 Kíyèsi i, ìwọ sá ti kọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn, ìwọ ṣá ti mú ọwọ́ aláìlera le.
For whereas you have instructed many, and have strengthened the hands of the weak one,
4 Ọ̀rọ̀ rẹ ti gbé àwọn tí ń ṣubú lọ dúró, ìwọ sì ti mú eékún àwọn tí ń wárìrì lera.
and have supported the failing with words, and have imparted courage to feeble knees.
5 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ó dé bá ọ, ó sì rẹ̀ ọ́, ó kọlù ọ́; ara rẹ kò lélẹ̀.
Yet now [that] pain has come upon you, and touched you, you are troubled.
6 Ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ kò ha jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ àti ìdúró ọ̀nà rẹ kò ha sì jẹ́ ìrètí rẹ?
Is not your fear [founded] in folly, your hope also, and the mischief of your way?
7 “Èmi bẹ̀ ọ́ rántí, ta ni ó ṣègbé rí láìṣẹ̀? Tàbí níbo ni a gbé gé olódodo kúrò rí?
Remember then who has perished, being pure? or when were the true-hearted utterly destroyed?
8 Àní bí èmi ti rí i pé, àwọn tí ń ṣe ìtulẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀, tí wọ́n sì fún irúgbìn ìwà búburú, wọn a sì ká èso rẹ̀ náà.
Accordingly as I have seen men ploughing barren places, and they that sow them will reap sorrows for themselves.
9 Nípa ìfẹ́ sí Ọlọ́run wọn a ṣègbé, nípa èémí ìbínú rẹ̀ wọn a parun.
They shall perish by the command of the Lord, and shall be utterly consumed by the breath of his wrath.
10 Bíbú ramúramù kìnnìún àti ohùn òǹrorò kìnnìún àti eyín àwọn ẹgbọrọ kìnnìún ní a ká.
The strength of the lion, and the voice of the lioness, and the exulting cry of serpents are quenched.
11 Kìnnìún kígbe, nítorí àìrí ohun ọdẹ, àwọn ẹgbọrọ kìnnìún sísanra ni a túká kiri.
The old lion has perished for lack of food, and the lions' whelps have forsaken one another.
12 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí a fi ohun àṣírí kan hàn fún mi, etí mi sì gbà díẹ̀ nínú rẹ̀.
But if there had been any truth in your words, none of these evils would have befallen you. Shall not mine ear receive excellent [revelations] from him?
13 Ní ìrò inú lójú ìran òru, nígbà tí oorun èjìká kùn ènìyàn.
But [as when] terror falls upon men, with dread and a sound in the night,
14 Ẹ̀rù bà mí àti ìwárìrì tí ó mú gbogbo egungun mi jí pépé.
horror and trembling seized me, and caused all my bones greatly to shake.
15 Nígbà náà ni ẹ̀mí kan kọjá lọ ní iwájú mi, irun ara mi dìde dúró ṣánṣán.
And a spirit came before my face; and my hair and flesh quivered.
16 Ó dúró jẹ́ẹ́, ṣùgbọ́n èmi kò le wo àpẹẹrẹ ìrí rẹ̀, àwòrán kan hàn níwájú mi, ìdákẹ́rọ́rọ́ wà, mo sì gbóhùn kan wí pé,
I arose and perceived it not: I looked, and there, was no form before my eyes: but I only heard a breath and a voice, [saying],
17 ‘Ẹni kíkú le jẹ́ olódodo ju Ọlọ́run, ènìyàn ha le mọ́ ju ẹlẹ́dàá rẹ̀ bí?
What, shall a mortal be pure before the Lord? or a man be blameless in regard to his works?
18 Kíyèsi i, òun kò gbẹ́kẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, nínú àwọn angẹli rẹ̀ ní ó sì rí ẹ̀ṣẹ̀.
Whereas he trust not in his servants, and perceives perverseness in his angels.
19 Mélòó mélòó àwọn tí ń gbé inú ilé amọ̀, ẹni tí ìpìlẹ̀ wọ́n jásí erùpẹ̀ tí yóò di rírun kòkòrò.
But [as for] them that dwell in houses of clay, of whom we also are formed of the same clay, he smites them like a moth.
20 A pa wọ́n run láàrín òwúrọ̀ àti àṣálẹ́ wọ́n sì parun títí láé, láìrí ẹni kà á sí.
And from the morning to evening they no longer exist: they have perished, because they can’t help themselves.
21 A kò ha ké okùn iye wọ́n kúrò bí? Wọ́n kú, àní láìlọ́gbọ́n?’
For he blows upon them, and they are withered: they have perished for lack of wisdom.