< Job 39 >
1 “Ìwọ mọ àkókò ìgbà tí àwọn ewúrẹ́ orí àpáta ń bímọ? Ìwọ sì lè kíyèsi ìgbà tí abo àgbọ̀nrín ń bímọ?
Cunoști timpul când nasc caprele sălbatice de stâncă? Sau poți însemna când fată căprioarele?
2 Ìwọ lè ka iye òṣùpá tí wọn ń pé, ìwọ sì mọ àkókò ìgbà tí wọn ń bímọ.
Poți număra lunile împlinite de ele, sau știi timpul când ele nasc?
3 Wọ́n tẹ ara wọn ba, wọ́n bímọ, wọ́n sì mú ìkáàánú wọn jáde.
Ele se apleacă, își nasc puii, își leapădă întristările.
4 Àwọn ọmọ wọn rí dáradára, wọ́n dàgbà nínú ọ̀dàn; wọ́n jáde lọ, wọn kò sì tún padà wá sọ́dọ̀ wọn.
Puii lor arată bine, cresc cu grâne; pleacă și nu se mai întorc la ele.
5 “Ta ni ó jọ̀wọ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ oko lọ́wọ́? Tàbí ta ní ó tú ìdè kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó,
Cine a trimis liber măgarul sălbatic, sau cine a dezlegat legăturile măgarului sălbatic?
6 èyí tí mo fi aginjù ṣe ilé fún, àti ilẹ̀ iyọ̀ ní ibùgbé rẹ̀.
Căruia i-am făcut pustia casă și ținutul sterp locuințele lui.
7 Ó rẹ́rìn-ín sí ariwo ìlú, bẹ́ẹ̀ ni òun kò sì gbọ́ igbe darandaran.
El batjocorește mulțimea din cetate și nu ia aminte la strigătul celui ce [îl] mână.
8 Orí àtòlé òkè ńlá ni ibùjẹ oko rẹ̀, òun a sì máa wá ewé tútù gbogbo rí.
Lanțul munților este pășunea lui și caută fiecare verdeață.
9 “Àgbáǹréré ha jẹ́ sìn ọ́ bí? Tàbí ó jẹ́ dúró ní ibùjẹ ẹran rẹ ní òru?
Va voi unicornul să te servească, sau să rămână lângă ieslea ta?
10 Ìwọ le fi òkun tata de àgbáǹréré nínú aporo? Tàbí ó jẹ́ máa fa ìtulẹ̀ nínú aporo oko tọ̀ ọ́ lẹ́yìn?
Poți lega unicornul cu frânghia lui în brazdă, sau va grăpa el văile după tine?
11 Ìwọ ó gbẹ́kẹ̀lé e nítorí agbára rẹ̀ pọ̀? Ìwọ ó sì fi iṣẹ́ rẹ lé e lọ́wọ́?
Te vei încrede în el, deoarece tăria lui este mare, sau îi vei lăsa munca ta?
12 Ìwọ le gbẹ́kẹ̀lé pé, yóò mú èso oko rẹ̀ wá sílé, àti pé yóò sì kó ọ jọ sínú àká rẹ?
Îl vei crede, că îți va aduce acasă sămânța și o va aduna în grânarul tău?
13 “Ìwọ ni yóò ha fi ìyẹ́ dáradára fún ọ̀kín bí, tàbí ìyẹ́ àti ìhùhù bo ògòǹgò?
Ai dat tu păunului aripile frumoase, sau aripi și pene struțului?
14 Ó yé ẹ̀yìn rẹ̀ sílẹ̀ lórí ilẹ̀, a sì mú wọn gbóná nínú ekuru;
Care își lasă ouăle în pământ și le încălzește în țărână,
15 tí ó sì gbàgbé pé, ẹsẹ̀ lè tẹ̀ wọ́n fọ́, tàbí pé ẹranko igbó lè tẹ̀ wọ́n fọ́.
Și uită că piciorul le poate zdrobi, sau că fiara sălbatică le poate sparge.
16 Kò ní àánú sí àwọn ọmọ rẹ̀ bí ẹni pé wọn kì í ṣe tirẹ̀; asán ni iṣẹ́ rẹ̀ láìní ìbẹ̀rù;
Ea se împietrește împotriva puilor ei, ca și cum nu ar fi ai ei; munca ei este în zadar, fără de teamă;
17 nítorí pé Ọlọ́run kò fún un ní ọgbọ́n, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi ìpín òye fún un.
Căci Dumnezeu a lipsit-o de înțelepciune și nu i-a împărțit înțelegere.
18 Nígbà tí ó gbé ara sókè, ó gan ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin.
În timp ce se ridică în înalt, ea batjocorește calul și pe călărețul său.
19 “Ìwọ ni ó fi agbára fún ẹṣin bí, tàbí ṣé ìwọ ni ó fi gọ̀gọ̀ wọ ọrùn rẹ̀ ní aṣọ?
Ai dat tu calului tărie, i-ai îmbrăcat gâtul cu tunet?
20 Ìwọ le mú fò sókè bí ẹlẹ́ǹgà? Ògo èémí imú rẹ ní ẹ̀rù ńlá.
Îl poți înspăimânta ca pe o lăcustă? Gloria nărilor lui este teribilă.
21 Ó fi ẹsẹ̀ halẹ̀ nínú àfonífojì, ó sì yọ̀ nínú agbára rẹ̀; ó lọ jáde láti pàdé àwọn ìhámọ́ra ogun.
El bate din copite în vale și se bucură în tăria lui; el merge să îi întâlnească pe cei înarmați.
22 Ó fi ojú kékeré wo ẹ̀rù, àyà kò sì fò ó; bẹ́ẹ̀ ni kì í sì í padà sẹ́yìn kúrò lọ́wọ́ idà.
Batjocorește frica și nu se înspăimântă; nici nu întoarce spatele dinaintea sabiei.
23 Lọ́dọ̀ rẹ ni apó-ọfà ń mì pẹkẹpẹkẹ, àti ọ̀kọ̀ dídán àti àpáta.
Tolba zăngănește lovindu-se de el, sulița lucitoare și scutul.
24 Ó fi kíkorò ojú àti ìbínú ńlá gbé ilé mi, bẹ́ẹ̀ ni òun kò sì gbà á gbọ́ pé, ìró ìpè ni.
El înghite pământul cu înverșunare și furie; și nu crede că [este] sunetul trâmbiței.
25 Ó wí nígbà ìpè pé, Háà! Háà! Ó sì gbóhùn ogun lókèèrè réré, igbe àwọn balógun àti ìhó ayọ̀ ogun wọn.
El spune printre trâmbițe: Ha, ha; și miroase bătălia de departe, tunetul căpeteniilor și strigătul luptei.
26 “Àwòdì ha máa ti ipa ọgbọ́n rẹ̀ fò sókè, tí ó sì na ìyẹ́ apá rẹ̀ sí ìhà gúúsù?
Zboară șoimul prin înțelepciunea ta [și] își întinde aripile spre sud?
27 Idì ha máa fi àṣẹ rẹ̀ fò sókè, kí ó sì lọ tẹ́ ìtẹ́ rẹ̀ sí òkè gíga?
Se înalță acvila la porunca ta și își face cuibul în înalt?
28 Ó ń gbé, ó sì ń wò ní orí àpáta, lórí pàlàpálá òkúta àti ibi orí òkè.
Ea locuiește și rămâne pe stâncă, pe vârful stâncii și pe întăritură.
29 Láti ibẹ̀ lọ ni ó ti ń wá oúnjẹ kiri, ojú rẹ̀ sì ríran rí òkè réré.
De acolo ea caută prada și ochii ei privesc departe.
30 Àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú a máa mu ẹ̀jẹ̀, níbi tí òkú bá gbé wà, níbẹ̀ ni òun wà pẹ̀lú.”
Puii ei de asemenea sug sânge; și unde sunt cei uciși, acolo este și ea.