< Job 39 >

1 “Ìwọ mọ àkókò ìgbà tí àwọn ewúrẹ́ orí àpáta ń bímọ? Ìwọ sì lè kíyèsi ìgbà tí abo àgbọ̀nrín ń bímọ?
Connais-tu le temps où enfantent les chamois des roches? Le temps où les biches mettent bas, l’as-tu observé?
2 Ìwọ lè ka iye òṣùpá tí wọn ń pé, ìwọ sì mọ àkókò ìgbà tí wọn ń bímọ.
Peux-tu compter les mois de leur grossesse? Sais-tu l’heure de leur délivrance?
3 Wọ́n tẹ ara wọn ba, wọ́n bímọ, wọ́n sì mú ìkáàánú wọn jáde.
Elles s’accroupissent, émettent leur portée et se débarrassent de leurs douleurs.
4 Àwọn ọmọ wọn rí dáradára, wọ́n dàgbà nínú ọ̀dàn; wọ́n jáde lọ, wọn kò sì tún padà wá sọ́dọ̀ wọn.
Leurs petits gagnent en force, grandissent en plein air, ils partent et ne reviennent plus vers elles.
5 “Ta ni ó jọ̀wọ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ oko lọ́wọ́? Tàbí ta ní ó tú ìdè kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó,
Qui a lâché l’onagre en liberté? Qui a dénoué les liens de l’âne sauvage,
6 èyí tí mo fi aginjù ṣe ilé fún, àti ilẹ̀ iyọ̀ ní ibùgbé rẹ̀.
à qui j’ai assigné le désert pour demeure et les plaines salées pour habitation?
7 Ó rẹ́rìn-ín sí ariwo ìlú, bẹ́ẹ̀ ni òun kò sì gbọ́ igbe darandaran.
Il se rit du tumulte de la cité, il n’entend pas les cris d’un maître.
8 Orí àtòlé òkè ńlá ni ibùjẹ oko rẹ̀, òun a sì máa wá ewé tútù gbogbo rí.
Il explore les montagnes pour trouver son pâturage et se met en quête, de n’importe quelle verdure.
9 “Àgbáǹréré ha jẹ́ sìn ọ́ bí? Tàbí ó jẹ́ dúró ní ibùjẹ ẹran rẹ ní òru?
Le buffle consent-il à te servir? Passera-t-il la nuit à ton râtelier?
10 Ìwọ le fi òkun tata de àgbáǹréré nínú aporo? Tàbí ó jẹ́ máa fa ìtulẹ̀ nínú aporo oko tọ̀ ọ́ lẹ́yìn?
L’Attacheras-tu au sillon par une corde, ou ira-t-il hersant les vallées derrière toi?
11 Ìwọ ó gbẹ́kẹ̀lé e nítorí agbára rẹ̀ pọ̀? Ìwọ ó sì fi iṣẹ́ rẹ lé e lọ́wọ́?
Te fieras-tu à lui, parce que grande est sa force? Lui abandonneras-tu le soin de ton travail?
12 Ìwọ le gbẹ́kẹ̀lé pé, yóò mú èso oko rẹ̀ wá sílé, àti pé yóò sì kó ọ jọ sínú àká rẹ?
Compteras-tu sur lui pour rentrer ton grain, pour recueillir le produit de ton aire?
13 “Ìwọ ni yóò ha fi ìyẹ́ dáradára fún ọ̀kín bí, tàbí ìyẹ́ àti ìhùhù bo ògòǹgò?
L’Autruche bat joyeusement des ailes: si seulement ses ailes et ses plumes étaient tendrement fidèles!
14 Ó yé ẹ̀yìn rẹ̀ sílẹ̀ lórí ilẹ̀, a sì mú wọn gbóná nínú ekuru;
Car elle abandonne ses œufs à la terre et les laisse chauffer sur le sable,
15 tí ó sì gbàgbé pé, ẹsẹ̀ lè tẹ̀ wọ́n fọ́, tàbí pé ẹranko igbó lè tẹ̀ wọ́n fọ́.
oubliant qu’un pied peut les fouler et la bête des champs les écraser.
16 Kò ní àánú sí àwọn ọmọ rẹ̀ bí ẹni pé wọn kì í ṣe tirẹ̀; asán ni iṣẹ́ rẹ̀ láìní ìbẹ̀rù;
Elle est dure pour ses petits, comme s’ils lui étaient étrangers: sa peine aura été en pure perte, et elle n’en a pas de regret.
17 nítorí pé Ọlọ́run kò fún un ní ọgbọ́n, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi ìpín òye fún un.
C’Est que Dieu lui a refusé la sagesse et ne lui a pas départi de l’intelligence.
18 Nígbà tí ó gbé ara sókè, ó gan ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin.
Mais quand elle se dresse pour prendre son élan, elle défie chevaux et cavaliers.
19 “Ìwọ ni ó fi agbára fún ẹṣin bí, tàbí ṣé ìwọ ni ó fi gọ̀gọ̀ wọ ọrùn rẹ̀ ní aṣọ?
Est-ce toi qui donnes la vigueur au cheval, qui garnis son cou d’une crinière flottante?
20 Ìwọ le mú fò sókè bí ẹlẹ́ǹgà? Ògo èémí imú rẹ ní ẹ̀rù ńlá.
Est-ce toi qui le fais bondir comme la sauterelle? L’Éclat de son ébrouement inspire l’effroi.
21 Ó fi ẹsẹ̀ halẹ̀ nínú àfonífojì, ó sì yọ̀ nínú agbára rẹ̀; ó lọ jáde láti pàdé àwọn ìhámọ́ra ogun.
Il creuse le sol et, tout joyeux de sa force, il s’élance vers la mêlée.
22 Ó fi ojú kékeré wo ẹ̀rù, àyà kò sì fò ó; bẹ́ẹ̀ ni kì í sì í padà sẹ́yìn kúrò lọ́wọ́ idà.
Il se rit de la crainte, il ne tremble ni ne recule devant l’épée.
23 Lọ́dọ̀ rẹ ni apó-ọfà ń mì pẹkẹpẹkẹ, àti ọ̀kọ̀ dídán àti àpáta.
Sur son dos résonnent le carquois, la lance étincelante et le javelot.
24 Ó fi kíkorò ojú àti ìbínú ńlá gbé ilé mi, bẹ́ẹ̀ ni òun kò sì gbà á gbọ́ pé, ìró ìpè ni.
D’Impatience et de colère, il dévore l’espace; il ne se possède plus lorsque sonne le clairon.
25 Ó wí nígbà ìpè pé, Háà! Háà! Ó sì gbóhùn ogun lókèèrè réré, igbe àwọn balógun àti ìhó ayọ̀ ogun wọn.
Au coup de trompette, il dit: "Ah!" Et de loin il flaire la bataille, la voix tonnante des chefs et les cris des combattants.
26 “Àwòdì ha máa ti ipa ọgbọ́n rẹ̀ fò sókè, tí ó sì na ìyẹ́ apá rẹ̀ sí ìhà gúúsù?
Est-ce par un effet de ton intelligence que l’épervier prend son essor et déploie ses ailes vers le Midi?
27 Idì ha máa fi àṣẹ rẹ̀ fò sókè, kí ó sì lọ tẹ́ ìtẹ́ rẹ̀ sí òkè gíga?
Est-ce par ton ordre que l’aigle s’élève et va nicher dans les hauteurs?
28 Ó ń gbé, ó sì ń wò ní orí àpáta, lórí pàlàpálá òkúta àti ibi orí òkè.
Il fait du rocher sa demeure et se gîte sur la dent des montagnes et les pics escarpés.
29 Láti ibẹ̀ lọ ni ó ti ń wá oúnjẹ kiri, ojú rẹ̀ sì ríran rí òkè réré.
De là il guette la proie ses regards portent au loin.
30 Àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú a máa mu ẹ̀jẹ̀, níbi tí òkú bá gbé wà, níbẹ̀ ni òun wà pẹ̀lú.”
Ses aiglons se gorgent de sang partout où il y a des cadavres, il est présent.

< Job 39 >