< Job 39 >

1 “Ìwọ mọ àkókò ìgbà tí àwọn ewúrẹ́ orí àpáta ń bímọ? Ìwọ sì lè kíyèsi ìgbà tí abo àgbọ̀nrín ń bímọ?
Víš-li, kterého času rodí kamsíkové, a laň ku porodu pracující spatřil-lis?
2 Ìwọ lè ka iye òṣùpá tí wọn ń pé, ìwọ sì mọ àkókò ìgbà tí wọn ń bímọ.
Máš-li v počtu měsíce, kteréž vyplňují? Znáš-li, pravím, čas porodu jejich?
3 Wọ́n tẹ ara wọn ba, wọ́n bímọ, wọ́n sì mú ìkáàánú wọn jáde.
Jak se kladou, plod svůj utiskají, a s bolestí ho pozbývají?
4 Àwọn ọmọ wọn rí dáradára, wọ́n dàgbà nínú ọ̀dàn; wọ́n jáde lọ, wọn kò sì tún padà wá sọ́dọ̀ wọn.
Jak se zmocňují mladí jejich, i odchovávají picí polní, a vycházejíce, nenavracují se k nim?
5 “Ta ni ó jọ̀wọ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ oko lọ́wọ́? Tàbí ta ní ó tú ìdè kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó,
Kdo propustil zvěř, aby byla svobodná? A řemení divokého osla kdo rozvázal?
6 èyí tí mo fi aginjù ṣe ilé fún, àti ilẹ̀ iyọ̀ ní ibùgbé rẹ̀.
Jemuž jsem dal pustinu místo domu jeho, a místo příbytku jeho zemi slatinnou.
7 Ó rẹ́rìn-ín sí ariwo ìlú, bẹ́ẹ̀ ni òun kò sì gbọ́ igbe darandaran.
Posmívá se hluku městskému, a na křikání toho, kdož by jej honil, nic nedbá.
8 Orí àtòlé òkè ńlá ni ibùjẹ oko rẹ̀, òun a sì máa wá ewé tútù gbogbo rí.
To, což nachází v horách, jest pastva jeho; nebo toliko zeliny hledá.
9 “Àgbáǹréré ha jẹ́ sìn ọ́ bí? Tàbí ó jẹ́ dúró ní ibùjẹ ẹran rẹ ní òru?
Svolí-liž jednorožec, aby tobě sloužil, a u jeslí tvých aby nocoval?
10 Ìwọ le fi òkun tata de àgbáǹréré nínú aporo? Tàbí ó jẹ́ máa fa ìtulẹ̀ nínú aporo oko tọ̀ ọ́ lẹ́yìn?
Připřáhneš-liž provazem jednorožce k orání? Bude-liž vláčeti brázdy za tebou?
11 Ìwọ ó gbẹ́kẹ̀lé e nítorí agbára rẹ̀ pọ̀? Ìwọ ó sì fi iṣẹ́ rẹ lé e lọ́wọ́?
Zdaž se na něj ubezpečíš, proto že jest veliká síla jeho, a poručíš jemu svou práci?
12 Ìwọ le gbẹ́kẹ̀lé pé, yóò mú èso oko rẹ̀ wá sílé, àti pé yóò sì kó ọ jọ sínú àká rẹ?
Zdaž se jemu dověříš, že sveze semeno tvé, a na humno tvé shromáždí?
13 “Ìwọ ni yóò ha fi ìyẹ́ dáradára fún ọ̀kín bí, tàbí ìyẹ́ àti ìhùhù bo ògòǹgò?
Ty-lis dal pávům křídlo pěkné, aneb péro čápu neb pstrosu?
14 Ó yé ẹ̀yìn rẹ̀ sílẹ̀ lórí ilẹ̀, a sì mú wọn gbóná nínú ekuru;
A že opouští na zemi vejce svá, ačkoli je v prachu osedí,
15 tí ó sì gbàgbé pé, ẹsẹ̀ lè tẹ̀ wọ́n fọ́, tàbí pé ẹranko igbó lè tẹ̀ wọ́n fọ́.
Nic nemysle, že by je noha potlačiti, aneb zvěř polní pošlapati mohla?
16 Kò ní àánú sí àwọn ọmọ rẹ̀ bí ẹni pé wọn kì í ṣe tirẹ̀; asán ni iṣẹ́ rẹ̀ láìní ìbẹ̀rù;
Tak se zatvrzuje k mladým svým, jako by jich neměl; jako by neužitečná byla práce jeho, tak jest bez starosti.
17 nítorí pé Ọlọ́run kò fún un ní ọgbọ́n, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi ìpín òye fún un.
Nebo nedal jemu Bůh moudrosti, aniž mu udělil rozumnosti.
18 Nígbà tí ó gbé ara sókè, ó gan ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin.
Èasem svým zhůru se vznášeje, posmívá se koni i jezdci jeho.
19 “Ìwọ ni ó fi agbára fún ẹṣin bí, tàbí ṣé ìwọ ni ó fi gọ̀gọ̀ wọ ọrùn rẹ̀ ní aṣọ?
Zdaž ty dáti můžeš koni sílu? Ty-li ozdobíš šíji jeho řehtáním?
20 Ìwọ le mú fò sókè bí ẹlẹ́ǹgà? Ògo èémí imú rẹ ní ẹ̀rù ńlá.
Zdali jej zastrašíš jako kobylku? Anobrž frkání chřípí jeho strašlivé jest.
21 Ó fi ẹsẹ̀ halẹ̀ nínú àfonífojì, ó sì yọ̀ nínú agbára rẹ̀; ó lọ jáde láti pàdé àwọn ìhámọ́ra ogun.
Kopá důl, a pléše v síle své, vycházeje vstříc i zbroji.
22 Ó fi ojú kékeré wo ẹ̀rù, àyà kò sì fò ó; bẹ́ẹ̀ ni kì í sì í padà sẹ́yìn kúrò lọ́wọ́ idà.
Směje se strachu, aniž se leká, aniž ustupuje zpátkem před ostrostí meče,
23 Lọ́dọ̀ rẹ ni apó-ọfà ń mì pẹkẹpẹkẹ, àti ọ̀kọ̀ dídán àti àpáta.
Ač i toul na něm chřestí, a blyští se dřevce a kopí.
24 Ó fi kíkorò ojú àti ìbínú ńlá gbé ilé mi, bẹ́ẹ̀ ni òun kò sì gbà á gbọ́ pé, ìró ìpè ni.
S hřmotem a s hněvem kopá zemi, aniž pokojně stojí k zvuku trouby.
25 Ó wí nígbà ìpè pé, Háà! Háà! Ó sì gbóhùn ogun lókèèrè réré, igbe àwọn balógun àti ìhó ayọ̀ ogun wọn.
Anobrž k zvuku trouby řehce, a zdaleka cítí boj, hluk knížat a prokřikování.
26 “Àwòdì ha máa ti ipa ọgbọ́n rẹ̀ fò sókè, tí ó sì na ìyẹ́ apá rẹ̀ sí ìhà gúúsù?
Zdali podlé rozumu tvého létá jestřáb, roztahuje křídla svá na poledne?
27 Idì ha máa fi àṣẹ rẹ̀ fò sókè, kí ó sì lọ tẹ́ ìtẹ́ rẹ̀ sí òkè gíga?
Zdali k rozkazu tvému zhůru se vznáší orlice, a vysoko se hnízdí?
28 Ó ń gbé, ó sì ń wò ní orí àpáta, lórí pàlàpálá òkúta àti ibi orí òkè.
Na skále přebývá, přebývá na špičaté skále jako na hradě,
29 Láti ibẹ̀ lọ ni ó ti ń wá oúnjẹ kiri, ojú rẹ̀ sì ríran rí òkè réré.
Odkudž hledá pokrmu, kterýž z daleka očima svýma spatřuje.
30 Àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú a máa mu ẹ̀jẹ̀, níbi tí òkú bá gbé wà, níbẹ̀ ni òun wà pẹ̀lú.”
Ano i mladí její střebí krev, a kde těla mrtvá, tu i ona jest.

< Job 39 >