< Job 38 >

1 Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àjàyíká wá, ó sì wí pé,
Преставшу же Елиусу от беседы, рече Господь Иову сквозе бурю и облаки:
2 “Ta ni èyí tí ń fi ọ̀rọ̀ àìlóye láti fi ṣókùnkùn bo ìmọ̀ mi?
кто сей скрываяй от Мене совет, содержай же глаголы в сердцы, Мене же ли мнится утаити?
3 Di ẹ̀gbẹ́ ara rẹ ní àmùrè bí ọkùnrin nísinsin yìí, nítorí pé èmi yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ kí o sì dá mi lóhùn.
Препояши яко муж чресла твоя: вопрошу же тя, ты же Ми отвещай.
4 “Níbo ni ìwọ wà nígbà tí mo fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀? Wí bí ìwọ bá mòye.
Где был еси, егда основах землю? Возвести ми, аще веси разум.
5 Ta ni ó fi ìwọ̀n rẹ lélẹ̀, dájú bí ìwọ bá mọ̀ ọ́n? Tàbí ta ni ó ta okùn wíwọ̀n sórí rẹ?
Кто положи меры ея, аще веси? Или кто наведый вервь на ню?
6 Lórí ibo ni a gbé kan ìpìlẹ̀ rẹ̀ mọ́, tàbí ta ni ó fi òkúta igun rẹ̀ lélẹ̀,
На чемже столпи ея утверждени суть? Ктоже есть положивый камень краеуголный на ней?
7 nígbà náà àwọn ìràwọ̀ òwúrọ̀ jùmọ̀ kọrin pọ̀, tí gbogbo àwọn ọmọ Ọlọ́run hó ìhó ayọ̀?
Егда (сотворены) быша звезды, восхвалиша Мя гласом велиим вси Ангели Мои.
8 “Tàbí ta ni ó fi ìlẹ̀kùn sé omi òkun mọ́, nígbà tí ó ya padà bí ẹni pé ó ti inú jáde wá.
Заградих же море враты, егда изливашеся из чрева матере своея исходящее:
9 Nígbà tí mo fi àwọsánmọ̀ ṣe aṣọ rẹ̀, tí mo sì fi òkùnkùn biribiri ṣe ọ̀já ìgbà inú rẹ̀.
положих же ему облак во одеяние, мглою же пових е:
10 Nígbà tí mo ti pàṣẹ ìpinnu mi fún un, tí mo sì ṣe bèbè àti ìlẹ̀kùn.
и положих ему пределы, обложив затворы и врата:
11 Tí mo sì wí pé níhìn-ín ni ìwọ ó dé, kí o má sì rékọjá, níhìn-ín sì ni ìgbéraga rẹ yóò gbé dúró mọ?
рех же ему: до сего дойдеши и не прейдеши, но в тебе сокрушатся волны твоя.
12 “Ìwọ pàṣẹ fún òwúrọ̀ láti ìgbà ọjọ́ rẹ̀ wá, ìwọ sì mú ìlà-oòrùn mọ ipò rẹ̀,
Или при тебе составих свет утренний, денница же весть чин свой,
13 í ó lè di òpin ilẹ̀ ayé mú, ki a lè gbọ́n àwọn ènìyàn búburú kúrò nínú rẹ̀?
ятися крил земли, оттрясти нечестивыя от нея?
14 Kí ó yí padà bí amọ̀ fún èdìdì amọ̀, kí gbogbo rẹ̀ kí ó sì fi ara rẹ̀ hàn bí ẹni pé nínú aṣọ ìgúnwà.
Или ты, брение взем, от земли создал еси животно, и глаголиваго сего посадил еси на земли?
15 A sì fa ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ ènìyàn búburú, apá gíga ni a sì ṣẹ́.
Отял же ли еси от нечестивых свет, мышцу же гордых сокрушил ли еси?
16 “Ìwọ ha wọ inú ìsun òkun lọ rí bí? Ìwọ sì rìn lórí ìsàlẹ̀ ibú ńlá?
Пришел же ли еси на источники моря, во следах же бездны ходил ли еси?
17 A ha ṣílẹ̀kùn ikú sílẹ̀ fún ọ rí bí, ìwọ sì rí ìlẹ̀kùn òjìji òkú?
Отверзаются же ли тебе страхом врата смертная, вратницы же адовы видевше тя убояшася ли?
18 Ìwọ mòye ìbú ayé bí? Sọ bí ìwọ bá mọ gbogbo èyí.
Навыкл же ли еси широты поднебесныя? Повеждь убо ми, колика есть?
19 “Ọ̀nà wo ni ìmọ́lẹ̀ ń gbé? Bí ó ṣe ti òkùnkùn, níbo ni ipò rẹ̀,
В коей же земли вселяется свет, тме же кое есть место?
20 tí ìwọ í fi mú un lọ sí ibi àlá rẹ̀, tí ìwọ ó sì le mọ ipa ọ̀nà lọ sínú ilé rẹ̀?
Аще убо введеши мя в пределы их, аще же ли и веси стези их?
21 Ìwọ mọ èyí, nítorí nígbà náà ni a bí ọ? Iye ọjọ́ rẹ sì pọ̀.
Вем убо, яко тогда рожден еси, число же лет твоих много.
22 “Ìwọ ha wọ inú ìṣúra ìdì òjò lọ rí bí, ìwọ sì rí ilé ìṣúra yìnyín rí,
Пришел же ли еси в сокровища снежная, и сокровища градная видел ли еси?
23 tí mo ti fi pamọ́ de ìgbà ìyọnu, dé ọjọ́ ogun àti ìjà?
Подлежат же ли тебе в час врагов, в день браней и рати?
24 Ọ̀nà wo ni ó lọ sí ibi tí ìmọ́lẹ̀ fi ń la, tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ń tàn káàkiri lórí ilẹ̀ ayé?
Откуду же исходит слана, или разсыпается юг на поднебесную?
25 Ta ni ó la ipadò fún ẹ̀kún omi, àti ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
Кто же уготова дождю велию пролияние, и путь молнии и грома,
26 láti mú u rọ̀jò sórí ayé níbi tí ènìyàn kò sí, ní aginjù níbi tí ènìyàn kò sí;
одождити на землю, на нейже несть мужа, пустыню, идеже человека несть в ней,
27 láti mú ilẹ̀ tútù, ijù àti aláìro láti mú àṣẹ̀ṣẹ̀yọ ewéko rú jáde?
насытити непроходиму и ненаселену, и прозябнути исход злака?
28 Òjò ha ní baba bí? Tàbí ta ni o bí ìkún ìṣe ìrì?
Кто есть дождю отец? Кто же есть родивый капли росныя?
29 Láti inú ta ni ìdì omi ti jáde wá? Ta ni ó bí ìrì dídì ọ̀run?
Из чиего чрева исходит лед? Слану же на небеси кто родил,
30 Nígbà tí omi di líle bí òkúta, nígbà tí ojú ibú ńlá sì dìpọ̀.
яже нисходит яко вода текущая? Лице нечестива кто устраши?
31 “Ìwọ ha le fi ọ̀já de àwọn ìràwọ̀ Pleiadesi dáradára? Tàbí ìwọ le tún di ìràwọ̀ Orioni?
Разумел же ли еси соуз Плиад, и ограждение Орионово отверзл ли еси?
32 Ìwọ le mú àwọn àmì méjìlá ìràwọ̀ Masaroti jáde wá nígbà àkókò wọn? Tàbí ìwọ le ṣe amọ̀nà Beari pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀?
Или отверзеши знамения небесная во время свое? И вечернюю звезду за власы ея привлечеши ли?
33 Ǹjẹ́ ìwọ mọ ìlànà ọ̀run? Ìwọ le fi ìjọba Ọlọ́run lélẹ̀ lórí ayé?
Веси же ли пременения небесная, или бывающая вкупе под небесем?
34 “Ìwọ le gbé ohùn rẹ sókè dé àwọsánmọ̀ kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi kí ó lè bò ọ́?
Призовеши же ли облак гласом? И трепетом воды великия послушает ли тя?
35 Ìwọ le rán mọ̀nàmọ́ná kí wọn kí ó le lọ, ní ọ̀nà wọn kí wọn kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Àwa nìyí’?
Послеши же ли молнии, и пойдут? Рекут же ли ти: что есть?
36 Ta ni ó fi ọgbọ́n pamọ́ sí odò ikùn tàbí tí ó fi òye sínú àyà?
Кто же дал есть женам ткания мудрость, или испещрения хитрость?
37 Ta ni ó fi ọgbọ́n ka iye àwọsánmọ̀? Ta ni ó sì mú ìgò ọ̀run dà jáde,
Кто же изчисляяй облаки премудростию, небо же на землю преклонил,
38 nígbà tí erùpẹ̀ di líle, àti ògúlùtu dìpọ̀?
разлияся же яко земля прах, спаях же е, аки каменем, на четыри углы?
39 “Ìwọ ha dẹ ọdẹ fún abo kìnnìún bí? Ìwọ ó sì tẹ ebi ẹgbọrọ kìnnìún lọ́rùn,
Уловиши же ли львам ядь, и душы змиев насытиши ли?
40 nígbà tí wọ́n bá mọ́lẹ̀ nínú ihò tí wọ́n sì ba ní ibùba de ohun ọdẹ?
Убояшася бо на ложах своих и седят в дебрех уловляюще.
41 Ta ni ó ń pèsè ohun jíjẹ fún ẹyẹ ìwò, nígbà tí àwọn ọmọ rẹ ń ké pe Ọlọ́run, tí wọ́n sì máa ń fò kiri nítorí àìní ohun jíjẹ?
Кто же врану уготова пищу? Птичищи бо его ко Господу воззваша, облетающе брашна ищуще.

< Job 38 >