< Job 38 >
1 Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àjàyíká wá, ó sì wí pé,
Atunci DOMNUL i-a răspuns lui Iov din vârtejul de vânt și a zis:
2 “Ta ni èyí tí ń fi ọ̀rọ̀ àìlóye láti fi ṣókùnkùn bo ìmọ̀ mi?
Cine este acesta care întunecă sfatul prin cuvinte fără cunoaștere?
3 Di ẹ̀gbẹ́ ara rẹ ní àmùrè bí ọkùnrin nísinsin yìí, nítorí pé èmi yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ kí o sì dá mi lóhùn.
Încinge-ți acum coapsele ca un bărbat; eu te voi întreba iar tu răspunde-mi.
4 “Níbo ni ìwọ wà nígbà tí mo fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀? Wí bí ìwọ bá mòye.
Unde erai tu când așezam temeliile pământului? Spune, dacă ai înțelegere.
5 Ta ni ó fi ìwọ̀n rẹ lélẹ̀, dájú bí ìwọ bá mọ̀ ọ́n? Tàbí ta ni ó ta okùn wíwọ̀n sórí rẹ?
Cine a pus măsurile acestuia, dacă știi; sau cine a întins frânghia peste el?
6 Lórí ibo ni a gbé kan ìpìlẹ̀ rẹ̀ mọ́, tàbí ta ni ó fi òkúta igun rẹ̀ lélẹ̀,
Pe ce sunt temeliile lui legate; sau cine i-a pus piatra unghiulară a temeliei,
7 nígbà náà àwọn ìràwọ̀ òwúrọ̀ jùmọ̀ kọrin pọ̀, tí gbogbo àwọn ọmọ Ọlọ́run hó ìhó ayọ̀?
Când stelele dimineții cântau împreună și toți fiii lui Dumnezeu strigau de bucurie?
8 “Tàbí ta ni ó fi ìlẹ̀kùn sé omi òkun mọ́, nígbà tí ó ya padà bí ẹni pé ó ti inú jáde wá.
Sau cine a închis marea cu porți, când a izbucnit, de parcă ar fi ieșit din pântece?
9 Nígbà tí mo fi àwọsánmọ̀ ṣe aṣọ rẹ̀, tí mo sì fi òkùnkùn biribiri ṣe ọ̀já ìgbà inú rẹ̀.
Când i-am făcut norul veșmânt și întunericul gros fașă pentru ea,
10 Nígbà tí mo ti pàṣẹ ìpinnu mi fún un, tí mo sì ṣe bèbè àti ìlẹ̀kùn.
Și am spart pentru ea locul meu hotărât și am pus drugi și porți,
11 Tí mo sì wí pé níhìn-ín ni ìwọ ó dé, kí o má sì rékọjá, níhìn-ín sì ni ìgbéraga rẹ yóò gbé dúró mọ?
Și am spus: Până aici să vii, dar nu mai departe; și aici să fie oprite mândrele tale valuri?
12 “Ìwọ pàṣẹ fún òwúrọ̀ láti ìgbà ọjọ́ rẹ̀ wá, ìwọ sì mú ìlà-oòrùn mọ ipò rẹ̀,
Ai poruncit tu dimineții în zilele tale; și ai făcut răsăritul să își cunoască locul,
13 í ó lè di òpin ilẹ̀ ayé mú, ki a lè gbọ́n àwọn ènìyàn búburú kúrò nínú rẹ̀?
Ca să apuce marginile pământului; și cei stricați să fie scuturați de pe el?
14 Kí ó yí padà bí amọ̀ fún èdìdì amọ̀, kí gbogbo rẹ̀ kí ó sì fi ara rẹ̀ hàn bí ẹni pé nínú aṣọ ìgúnwà.
Este întors ca lutul în sigiliu; și ei stau în picioare ca un veșmânt.
15 A sì fa ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ ènìyàn búburú, apá gíga ni a sì ṣẹ́.
Și celor răi lumina le este oprită și brațul înalt va fi frânt.
16 “Ìwọ ha wọ inú ìsun òkun lọ rí bí? Ìwọ sì rìn lórí ìsàlẹ̀ ibú ńlá?
Ai intrat tu în izvoarele mării? Sau te-ai plimbat în căutarea adâncului?
17 A ha ṣílẹ̀kùn ikú sílẹ̀ fún ọ rí bí, ìwọ sì rí ìlẹ̀kùn òjìji òkú?
Ți-au fost porțile morții deschise? Sau ai văzut tu porțile umbrei morții?
18 Ìwọ mòye ìbú ayé bí? Sọ bí ìwọ bá mọ gbogbo èyí.
Ai priceput tu lățimea pământului? Spune dacă le cunoști pe toate.
19 “Ọ̀nà wo ni ìmọ́lẹ̀ ń gbé? Bí ó ṣe ti òkùnkùn, níbo ni ipò rẹ̀,
Unde este calea pe care locuiește lumina? Și cât despre întuneric, unde este locul lui,
20 tí ìwọ í fi mú un lọ sí ibi àlá rẹ̀, tí ìwọ ó sì le mọ ipa ọ̀nà lọ sínú ilé rẹ̀?
Ca să îl duci la hotarul lui și să cunoști cărările spre casa lui?
21 Ìwọ mọ èyí, nítorí nígbà náà ni a bí ọ? Iye ọjọ́ rẹ sì pọ̀.
Îl cunoști tu, deoarece erai deja născut? Sau deoarece numărul zilelor tale este mare?
22 “Ìwọ ha wọ inú ìṣúra ìdì òjò lọ rí bí, ìwọ sì rí ilé ìṣúra yìnyín rí,
Ai intrat tu în tezaurele zăpezii? Sau ai văzut tu tezaurele grindinii,
23 tí mo ti fi pamọ́ de ìgbà ìyọnu, dé ọjọ́ ogun àti ìjà?
Pe care am păstrat-o pentru timpul tulburării, pentru ziua de bătălie și război?
24 Ọ̀nà wo ni ó lọ sí ibi tí ìmọ́lẹ̀ fi ń la, tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ń tàn káàkiri lórí ilẹ̀ ayé?
Pe ce cale este lumina împărțită, care împrăștie vântul de est pe pământ?
25 Ta ni ó la ipadò fún ẹ̀kún omi, àti ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
Cine a împărțit o albie pentru torent, sau o cale pentru fulgerul tunetului,
26 láti mú u rọ̀jò sórí ayé níbi tí ènìyàn kò sí, ní aginjù níbi tí ènìyàn kò sí;
Să îl facă să plouă peste pământ, unde nu este nimeni, în pustie, în care nu este om;
27 láti mú ilẹ̀ tútù, ijù àti aláìro láti mú àṣẹ̀ṣẹ̀yọ ewéko rú jáde?
Să sature pământul pustiit și secătuit și să facă mugurele verdeții să răsară?
28 Òjò ha ní baba bí? Tàbí ta ni o bí ìkún ìṣe ìrì?
Are ploaia tată, sau cine a născut picăturile de rouă?
29 Láti inú ta ni ìdì omi ti jáde wá? Ta ni ó bí ìrì dídì ọ̀run?
Din al cui pântece a venit gheața și chiciura cerului cine a născut-o?
30 Nígbà tí omi di líle bí òkúta, nígbà tí ojú ibú ńlá sì dìpọ̀.
Apele sunt ascunse precum cu o piatră și fața adâncului este înghețată.
31 “Ìwọ ha le fi ọ̀já de àwọn ìràwọ̀ Pleiadesi dáradára? Tàbí ìwọ le tún di ìràwọ̀ Orioni?
Poți tu lega dulcile influențe ale Pleiadelor, sau poți dezlega legăturile Orionului?
32 Ìwọ le mú àwọn àmì méjìlá ìràwọ̀ Masaroti jáde wá nígbà àkókò wọn? Tàbí ìwọ le ṣe amọ̀nà Beari pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀?
Poți scoate Mazarotul la timpul său? Sau poți conduce Arcturus cu fiii săi?
33 Ǹjẹ́ ìwọ mọ ìlànà ọ̀run? Ìwọ le fi ìjọba Ọlọ́run lélẹ̀ lórí ayé?
Cunoști tu rânduielile cerului, poți așeza domnia lui pe pământ?
34 “Ìwọ le gbé ohùn rẹ sókè dé àwọsánmọ̀ kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi kí ó lè bò ọ́?
Îți poți ridica vocea până la nori, ca mulțime de ape să te acopere?
35 Ìwọ le rán mọ̀nàmọ́ná kí wọn kí ó le lọ, ní ọ̀nà wọn kí wọn kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Àwa nìyí’?
Poți trimite fulgere, ca să meargă și să îți spună: Iată-ne?
36 Ta ni ó fi ọgbọ́n pamọ́ sí odò ikùn tàbí tí ó fi òye sínú àyà?
Cine a pus înțelepciune în rărunchi, sau cine a dat înțelegere inimii?
37 Ta ni ó fi ọgbọ́n ka iye àwọsánmọ̀? Ta ni ó sì mú ìgò ọ̀run dà jáde,
Cine poate număra norii în înțelepciune, sau cine poate opri burdufurile cerului,
38 nígbà tí erùpẹ̀ di líle, àti ògúlùtu dìpọ̀?
Când țărâna crește spre împietrire și bulgării de pământ se lipesc strâns împreună?
39 “Ìwọ ha dẹ ọdẹ fún abo kìnnìún bí? Ìwọ ó sì tẹ ebi ẹgbọrọ kìnnìún lọ́rùn,
Vei vâna prada pentru leu, sau vei sătura pofta leilor tineri,
40 nígbà tí wọ́n bá mọ́lẹ̀ nínú ihò tí wọ́n sì ba ní ibùba de ohun ọdẹ?
Când se culcă în vizuinile lor și rămân în adăpost pentru a sta la pândă?
41 Ta ni ó ń pèsè ohun jíjẹ fún ẹyẹ ìwò, nígbà tí àwọn ọmọ rẹ ń ké pe Ọlọ́run, tí wọ́n sì máa ń fò kiri nítorí àìní ohun jíjẹ?
Cine se îngrijește să dea corbului mâncarea sa? Când puii săi strigă către Dumnezeu ei rătăcesc din lipsă de mâncare.