< Job 38 >

1 Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àjàyíká wá, ó sì wí pé,
Et l’Éternel répondit à Job du milieu du tourbillon, et dit:
2 “Ta ni èyí tí ń fi ọ̀rọ̀ àìlóye láti fi ṣókùnkùn bo ìmọ̀ mi?
Qui est celui-ci qui obscurcit le conseil par des discours sans connaissance?
3 Di ẹ̀gbẹ́ ara rẹ ní àmùrè bí ọkùnrin nísinsin yìí, nítorí pé èmi yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ kí o sì dá mi lóhùn.
Ceins tes reins comme un homme, et je t’interrogerai et tu m’instruiras!
4 “Níbo ni ìwọ wà nígbà tí mo fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀? Wí bí ìwọ bá mòye.
Où étais-tu quand j’ai fondé la terre? Déclare-le-moi, si tu as de l’intelligence.
5 Ta ni ó fi ìwọ̀n rẹ lélẹ̀, dájú bí ìwọ bá mọ̀ ọ́n? Tàbí ta ni ó ta okùn wíwọ̀n sórí rẹ?
Qui lui a établi sa mesure, – si tu le sais? Ou qui a étendu le cordeau sur elle?
6 Lórí ibo ni a gbé kan ìpìlẹ̀ rẹ̀ mọ́, tàbí ta ni ó fi òkúta igun rẹ̀ lélẹ̀,
Sur quoi ses bases sont-elles assises, ou qui a placé sa pierre angulaire,
7 nígbà náà àwọn ìràwọ̀ òwúrọ̀ jùmọ̀ kọrin pọ̀, tí gbogbo àwọn ọmọ Ọlọ́run hó ìhó ayọ̀?
Quand les étoiles du matin chantaient ensemble, et que tous les fils de Dieu éclataient de joie?
8 “Tàbí ta ni ó fi ìlẹ̀kùn sé omi òkun mọ́, nígbà tí ó ya padà bí ẹni pé ó ti inú jáde wá.
Et qui a renfermé la mer dans des portes, quand elle rompit [les bornes] et sortit de la matrice,
9 Nígbà tí mo fi àwọsánmọ̀ ṣe aṣọ rẹ̀, tí mo sì fi òkùnkùn biribiri ṣe ọ̀já ìgbà inú rẹ̀.
Quand je fis de la nuée son vêtement, et de l’obscurité ses langes;
10 Nígbà tí mo ti pàṣẹ ìpinnu mi fún un, tí mo sì ṣe bèbè àti ìlẹ̀kùn.
Quand je lui découpai ses limites et lui mis des barres et des portes,
11 Tí mo sì wí pé níhìn-ín ni ìwọ ó dé, kí o má sì rékọjá, níhìn-ín sì ni ìgbéraga rẹ yóò gbé dúró mọ?
Et que je dis: Tu viendras jusqu’ici et tu n’iras pas plus loin, et ici s’arrêtera l’orgueil de tes flots?
12 “Ìwọ pàṣẹ fún òwúrọ̀ láti ìgbà ọjọ́ rẹ̀ wá, ìwọ sì mú ìlà-oòrùn mọ ipò rẹ̀,
As-tu, de ta vie, commandé au matin? As-tu montré à l’aube du jour sa place,
13 í ó lè di òpin ilẹ̀ ayé mú, ki a lè gbọ́n àwọn ènìyàn búburú kúrò nínú rẹ̀?
Pour qu’elle saisisse les bords de la terre, et que les méchants en soient secoués?
14 Kí ó yí padà bí amọ̀ fún èdìdì amọ̀, kí gbogbo rẹ̀ kí ó sì fi ara rẹ̀ hàn bí ẹni pé nínú aṣọ ìgúnwà.
Elle se change comme l’argile d’un sceau, et [toutes choses] se présentent parées comme d’un vêtement;
15 A sì fa ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ ènìyàn búburú, apá gíga ni a sì ṣẹ́.
Et leur lumière est ôtée aux méchants, et le bras levé est cassé.
16 “Ìwọ ha wọ inú ìsun òkun lọ rí bí? Ìwọ sì rìn lórí ìsàlẹ̀ ibú ńlá?
Es-tu allé aux sources de la mer, et t’es-tu promené dans les profondeurs de l’abîme?
17 A ha ṣílẹ̀kùn ikú sílẹ̀ fún ọ rí bí, ìwọ sì rí ìlẹ̀kùn òjìji òkú?
Les portes de la mort se sont-elles découvertes à toi? Et as-tu vu les portes de l’ombre de la mort?
18 Ìwọ mòye ìbú ayé bí? Sọ bí ìwọ bá mọ gbogbo èyí.
Ton regard a-t-il pénétré jusque dans les vastes espaces de la terre? Dis-le, si tu connais tout cela.
19 “Ọ̀nà wo ni ìmọ́lẹ̀ ń gbé? Bí ó ṣe ti òkùnkùn, níbo ni ipò rẹ̀,
Où est le chemin vers le séjour de la lumière? et les ténèbres, où est leur place?
20 tí ìwọ í fi mú un lọ sí ibi àlá rẹ̀, tí ìwọ ó sì le mọ ipa ọ̀nà lọ sínú ilé rẹ̀?
Pour que tu les prennes à leur limite, et que tu connaisses les sentiers de leur maison?
21 Ìwọ mọ èyí, nítorí nígbà náà ni a bí ọ? Iye ọjọ́ rẹ sì pọ̀.
Tu le sais, car tu étais né alors, et le nombre de tes jours est grand!
22 “Ìwọ ha wọ inú ìṣúra ìdì òjò lọ rí bí, ìwọ sì rí ilé ìṣúra yìnyín rí,
Es-tu allé aux trésors de la neige, et as-tu vu les trésors de la grêle,
23 tí mo ti fi pamọ́ de ìgbà ìyọnu, dé ọjọ́ ogun àti ìjà?
Que j’ai mis en réserve pour le temps de la détresse, pour le jour du combat et de la guerre?
24 Ọ̀nà wo ni ó lọ sí ibi tí ìmọ́lẹ̀ fi ń la, tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ń tàn káàkiri lórí ilẹ̀ ayé?
Par quel chemin se distribue la lumière, et le vent d’orient se répand-il sur la terre?
25 Ta ni ó la ipadò fún ẹ̀kún omi, àti ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
Qui a découpé des canaux aux torrents de pluie, et un chemin à l’éclair des tonnerres,
26 láti mú u rọ̀jò sórí ayé níbi tí ènìyàn kò sí, ní aginjù níbi tí ènìyàn kò sí;
Pour faire pleuvoir sur une terre où il n’y a personne, sur le désert où il n’y a pas d’hommes;
27 láti mú ilẹ̀ tútù, ijù àti aláìro láti mú àṣẹ̀ṣẹ̀yọ ewéko rú jáde?
Pour rassasier les lieux désolés et déserts, pour faire germer les pousses de l’herbe?
28 Òjò ha ní baba bí? Tàbí ta ni o bí ìkún ìṣe ìrì?
La pluie a-t-elle un père? ou qui engendre les gouttes de la rosée?
29 Láti inú ta ni ìdì omi ti jáde wá? Ta ni ó bí ìrì dídì ọ̀run?
Du sein de qui sort la glace? et le frimas des cieux, qui l’enfante?
30 Nígbà tí omi di líle bí òkúta, nígbà tí ojú ibú ńlá sì dìpọ̀.
Devenues pierre, les eaux se cachent, et la surface de l’abîme se prend.
31 “Ìwọ ha le fi ọ̀já de àwọn ìràwọ̀ Pleiadesi dáradára? Tàbí ìwọ le tún di ìràwọ̀ Orioni?
Peux-tu serrer les liens des Pléiades, ou détacher les cordes d’Orion?
32 Ìwọ le mú àwọn àmì méjìlá ìràwọ̀ Masaroti jáde wá nígbà àkókò wọn? Tàbí ìwọ le ṣe amọ̀nà Beari pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀?
Fais-tu sortir les signes du zodiaque en leurs saisons, et mènes-tu la grande Ourse avec ses filles?
33 Ǹjẹ́ ìwọ mọ ìlànà ọ̀run? Ìwọ le fi ìjọba Ọlọ́run lélẹ̀ lórí ayé?
Connais-tu les lois des cieux, ou établis-tu leur empire sur la terre?
34 “Ìwọ le gbé ohùn rẹ sókè dé àwọsánmọ̀ kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi kí ó lè bò ọ́?
Peux-tu élever ta voix vers les nuages, en sorte que des torrents d’eau te couvrent?
35 Ìwọ le rán mọ̀nàmọ́ná kí wọn kí ó le lọ, ní ọ̀nà wọn kí wọn kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Àwa nìyí’?
As-tu lancé la foudre, en sorte qu’elle soit allée et t’ait dit: Me voici?
36 Ta ni ó fi ọgbọ́n pamọ́ sí odò ikùn tàbí tí ó fi òye sínú àyà?
Qui a mis la sagesse dans les reins, ou qui donna l’intelligence à l’esprit?
37 Ta ni ó fi ọgbọ́n ka iye àwọsánmọ̀? Ta ni ó sì mú ìgò ọ̀run dà jáde,
Qui a compté les nuages dans [sa] sagesse? et qui verse les outres des cieux,
38 nígbà tí erùpẹ̀ di líle, àti ògúlùtu dìpọ̀?
Quand la poussière coule comme du métal en fusion et que les mottes se soudent entre elles?
39 “Ìwọ ha dẹ ọdẹ fún abo kìnnìún bí? Ìwọ ó sì tẹ ebi ẹgbọrọ kìnnìún lọ́rùn,
Est-ce toi qui chasses la proie pour la lionne, et qui rassasies l’appétit des lionceaux,
40 nígbà tí wọ́n bá mọ́lẹ̀ nínú ihò tí wọ́n sì ba ní ibùba de ohun ọdẹ?
Quand ils sont couchés dans leurs tanières [et] se tiennent aux aguets dans leur fourré?
41 Ta ni ó ń pèsè ohun jíjẹ fún ẹyẹ ìwò, nígbà tí àwọn ọmọ rẹ ń ké pe Ọlọ́run, tí wọ́n sì máa ń fò kiri nítorí àìní ohun jíjẹ?
Qui prépare au corbeau sa pâture quand ses petits crient à Dieu [et] qu’ils errent sans nourriture?

< Job 38 >