< Job 38 >

1 Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àjàyíká wá, ó sì wí pé,
Then Yahweh responded to Job, out of a storm, and said: —
2 “Ta ni èyí tí ń fi ọ̀rọ̀ àìlóye láti fi ṣókùnkùn bo ìmọ̀ mi?
Who is it that darkeneth counsel, by words, without knowledge?
3 Di ẹ̀gbẹ́ ara rẹ ní àmùrè bí ọkùnrin nísinsin yìí, nítorí pé èmi yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ kí o sì dá mi lóhùn.
Gird, I pray thee—like a strong man—thy loins, that I may ask thee, and inform thou me:
4 “Níbo ni ìwọ wà nígbà tí mo fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀? Wí bí ìwọ bá mòye.
Where wast thou, when I founded the earth? Tell, if thou knowest understanding!
5 Ta ni ó fi ìwọ̀n rẹ lélẹ̀, dájú bí ìwọ bá mọ̀ ọ́n? Tàbí ta ni ó ta okùn wíwọ̀n sórí rẹ?
Who set the measurements thereof, if thou knowest? Or who stretched out over it a line?
6 Lórí ibo ni a gbé kan ìpìlẹ̀ rẹ̀ mọ́, tàbí ta ni ó fi òkúta igun rẹ̀ lélẹ̀,
Whereon were the pedestals thereof sunk? Or who laid the corner stone thereof; —
7 nígbà náà àwọn ìràwọ̀ òwúrọ̀ jùmọ̀ kọrin pọ̀, tí gbogbo àwọn ọmọ Ọlọ́run hó ìhó ayọ̀?
When the morning stars sang together, and all the sons of God shouted for joy?
8 “Tàbí ta ni ó fi ìlẹ̀kùn sé omi òkun mọ́, nígbà tí ó ya padà bí ẹni pé ó ti inú jáde wá.
Or [who] shut in, with double doors, the sea, when, bursting out of the womb, it came forth;
9 Nígbà tí mo fi àwọsánmọ̀ ṣe aṣọ rẹ̀, tí mo sì fi òkùnkùn biribiri ṣe ọ̀já ìgbà inú rẹ̀.
When I put a cloud as the garment thereof, and a thick cloud as the swaddling-band thereof;
10 Nígbà tí mo ti pàṣẹ ìpinnu mi fún un, tí mo sì ṣe bèbè àti ìlẹ̀kùn.
And brake off for it my boundary, and fixed a bar and double doors;
11 Tí mo sì wí pé níhìn-ín ni ìwọ ó dé, kí o má sì rékọjá, níhìn-ín sì ni ìgbéraga rẹ yóò gbé dúró mọ?
And said—Hitherto, shalt thou come, and no further, —and, here, shalt thou set a limit to the majesty of thy waves?
12 “Ìwọ pàṣẹ fún òwúrọ̀ láti ìgbà ọjọ́ rẹ̀ wá, ìwọ sì mú ìlà-oòrùn mọ ipò rẹ̀,
Since thy days [began] hast thou commanded the morning? or caused the dawn to know its place;
13 í ó lè di òpin ilẹ̀ ayé mú, ki a lè gbọ́n àwọn ènìyàn búburú kúrò nínú rẹ̀?
That it might lay hold of the wings of the earth, and the lawless be shaken out of it?
14 Kí ó yí padà bí amọ̀ fún èdìdì amọ̀, kí gbogbo rẹ̀ kí ó sì fi ara rẹ̀ hàn bí ẹni pé nínú aṣọ ìgúnwà.
It transformeth itself like the clay of a seal, so that things stand forth like one arrayed;
15 A sì fa ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ ènìyàn búburú, apá gíga ni a sì ṣẹ́.
That their light may be withdrawn from the lawless, and, the lofty arm, be shivered.
16 “Ìwọ ha wọ inú ìsun òkun lọ rí bí? Ìwọ sì rìn lórí ìsàlẹ̀ ibú ńlá?
Hast thou entered as far as the springs of the sea? Or, through the secret recesses of the resounding deep, hast thou wandered?
17 A ha ṣílẹ̀kùn ikú sílẹ̀ fún ọ rí bí, ìwọ sì rí ìlẹ̀kùn òjìji òkú?
Have the gates of death been disclosed to thee? And, the gates of the death-shade, couldst thou descry?
18 Ìwọ mòye ìbú ayé bí? Sọ bí ìwọ bá mọ gbogbo èyí.
Hast thou well considered, even the breadths of the earth? Tell—if thou knowest it all!
19 “Ọ̀nà wo ni ìmọ́lẹ̀ ń gbé? Bí ó ṣe ti òkùnkùn, níbo ni ipò rẹ̀,
Where then is the way, the light shall abide? And, the darkness, where then is its place?
20 tí ìwọ í fi mú un lọ sí ibi àlá rẹ̀, tí ìwọ ó sì le mọ ipa ọ̀nà lọ sínú ilé rẹ̀?
That thou mayest conduct it unto the bound thereof, and that thou mayest perceive the paths to its house.
21 Ìwọ mọ èyí, nítorí nígbà náà ni a bí ọ? Iye ọjọ́ rẹ sì pọ̀.
Thou knowest, for, then, hadst thou been born! And, in number, thy days are many!
22 “Ìwọ ha wọ inú ìṣúra ìdì òjò lọ rí bí, ìwọ sì rí ilé ìṣúra yìnyín rí,
Hast thou entered into the treasuries of the snow? And, the treasuries of the hail, couldst thou see?
23 tí mo ti fi pamọ́ de ìgbà ìyọnu, dé ọjọ́ ogun àti ìjà?
Which I have reserved for a time of distress, for the day of conflict and of war?
24 Ọ̀nà wo ni ó lọ sí ibi tí ìmọ́lẹ̀ fi ń la, tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ń tàn káàkiri lórí ilẹ̀ ayé?
Where then is the way the lightning is parted? The east wind spreadeth itself abroad over the earth.
25 Ta ni ó la ipadò fún ẹ̀kún omi, àti ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
Who hath cloven—for the torrent—a channel? Or a way for the lightning of thunders;
26 láti mú u rọ̀jò sórí ayé níbi tí ènìyàn kò sí, ní aginjù níbi tí ènìyàn kò sí;
To give rain over the no-man’s land, the desert, where no son of earth is;
27 láti mú ilẹ̀ tútù, ijù àti aláìro láti mú àṣẹ̀ṣẹ̀yọ ewéko rú jáde?
To satisfy the wild and the wilderness, to cause to spring forth the meadow of young grass?
28 Òjò ha ní baba bí? Tàbí ta ni o bí ìkún ìṣe ìrì?
Hath the rain a father? Or who hath begotten the drops of dew?
29 Láti inú ta ni ìdì omi ti jáde wá? Ta ni ó bí ìrì dídì ọ̀run?
Out of whose womb, came forth the ice? And, the hoar-frost of the heavens, who hath given it birth?
30 Nígbà tí omi di líle bí òkúta, nígbà tí ojú ibú ńlá sì dìpọ̀.
Like a stone, are the waters congealed, and, the face of the roaring deep, becometh firm!
31 “Ìwọ ha le fi ọ̀já de àwọn ìràwọ̀ Pleiadesi dáradára? Tàbí ìwọ le tún di ìràwọ̀ Orioni?
Canst thou bind the fetters of the Pleiades? Or, the bands of Orion, canst thou unloose?
32 Ìwọ le mú àwọn àmì méjìlá ìràwọ̀ Masaroti jáde wá nígbà àkókò wọn? Tàbí ìwọ le ṣe amọ̀nà Beari pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀?
Canst thou bring forth the signs of the Zodiac each in its season? Or, the Bear and her Young, canst thou lead?
33 Ǹjẹ́ ìwọ mọ ìlànà ọ̀run? Ìwọ le fi ìjọba Ọlọ́run lélẹ̀ lórí ayé?
Knowest thou, the statutes of the heavens? Or didst thou appoint his dominion over the earth?
34 “Ìwọ le gbé ohùn rẹ sókè dé àwọsánmọ̀ kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi kí ó lè bò ọ́?
Canst thou lift up, to the thick cloud, thy voice, and the overflow of waters cover thee?
35 Ìwọ le rán mọ̀nàmọ́ná kí wọn kí ó le lọ, ní ọ̀nà wọn kí wọn kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Àwa nìyí’?
Canst thou send forth the lightnings, so that they go, and say to thee, Behold us?
36 Ta ni ó fi ọgbọ́n pamọ́ sí odò ikùn tàbí tí ó fi òye sínú àyà?
Who hath put—into cloud-forms—wisdom? Or who hath given—to the meteor—understanding?
37 Ta ni ó fi ọgbọ́n ka iye àwọsánmọ̀? Ta ni ó sì mú ìgò ọ̀run dà jáde,
Who can count the thin clouds, in wisdom? And, the bottles of the heavens, who can empty out;
38 nígbà tí erùpẹ̀ di líle, àti ògúlùtu dìpọ̀?
When the dust is cast into a clod, and the lumps are bound together?
39 “Ìwọ ha dẹ ọdẹ fún abo kìnnìún bí? Ìwọ ó sì tẹ ebi ẹgbọrọ kìnnìún lọ́rùn,
Wilt thou hunt—for the Lioness—prey? Or, the craving of the Strong Lion, wilt thou satisfy;
40 nígbà tí wọ́n bá mọ́lẹ̀ nínú ihò tí wọ́n sì ba ní ibùba de ohun ọdẹ?
When they settle down in dens, abide in covert, for lying in wait?
41 Ta ni ó ń pèsè ohun jíjẹ fún ẹyẹ ìwò, nígbà tí àwọn ọmọ rẹ ń ké pe Ọlọ́run, tí wọ́n sì máa ń fò kiri nítorí àìní ohun jíjẹ?
Who prepareth for the Raven his nourishment, —when his young ones—unto GOD—cry out, [when] they wander for lack of food?

< Job 38 >