< Job 38 >
1 Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àjàyíká wá, ó sì wí pé,
And Jehovah answered Job out of the whirlwind and said,
2 “Ta ni èyí tí ń fi ọ̀rọ̀ àìlóye láti fi ṣókùnkùn bo ìmọ̀ mi?
Who is this that darkeneth counsel by words without knowledge?
3 Di ẹ̀gbẹ́ ara rẹ ní àmùrè bí ọkùnrin nísinsin yìí, nítorí pé èmi yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ kí o sì dá mi lóhùn.
Gird up now thy loins like a man; and I will demand of thee, and inform thou me.
4 “Níbo ni ìwọ wà nígbà tí mo fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀? Wí bí ìwọ bá mòye.
Where wast thou when I founded the earth? Declare, if thou hast understanding.
5 Ta ni ó fi ìwọ̀n rẹ lélẹ̀, dájú bí ìwọ bá mọ̀ ọ́n? Tàbí ta ni ó ta okùn wíwọ̀n sórí rẹ?
Who set the measures thereof — if thou knowest? or who stretched a line upon it?
6 Lórí ibo ni a gbé kan ìpìlẹ̀ rẹ̀ mọ́, tàbí ta ni ó fi òkúta igun rẹ̀ lélẹ̀,
Whereupon were the foundations thereof sunken? or who laid its corner-stone,
7 nígbà náà àwọn ìràwọ̀ òwúrọ̀ jùmọ̀ kọrin pọ̀, tí gbogbo àwọn ọmọ Ọlọ́run hó ìhó ayọ̀?
When the morning stars sang together, and all the sons of God shouted for joy?
8 “Tàbí ta ni ó fi ìlẹ̀kùn sé omi òkun mọ́, nígbà tí ó ya padà bí ẹni pé ó ti inú jáde wá.
And who shut up the sea with doors, when it burst forth, issuing out of the womb?
9 Nígbà tí mo fi àwọsánmọ̀ ṣe aṣọ rẹ̀, tí mo sì fi òkùnkùn biribiri ṣe ọ̀já ìgbà inú rẹ̀.
When I made the cloud its garment, and thick darkness a swaddling band for it;
10 Nígbà tí mo ti pàṣẹ ìpinnu mi fún un, tí mo sì ṣe bèbè àti ìlẹ̀kùn.
When I cut out for it my boundary, and set bars and doors,
11 Tí mo sì wí pé níhìn-ín ni ìwọ ó dé, kí o má sì rékọjá, níhìn-ín sì ni ìgbéraga rẹ yóò gbé dúró mọ?
And said, Hitherto shalt thou come and no further, and here shall thy proud waves be stayed?
12 “Ìwọ pàṣẹ fún òwúrọ̀ láti ìgbà ọjọ́ rẹ̀ wá, ìwọ sì mú ìlà-oòrùn mọ ipò rẹ̀,
Hast thou since thy days commanded the morning? hast thou caused the dawn to know its place,
13 í ó lè di òpin ilẹ̀ ayé mú, ki a lè gbọ́n àwọn ènìyàn búburú kúrò nínú rẹ̀?
That it might take hold of the ends of the earth, and the wicked might be shaken out of it?
14 Kí ó yí padà bí amọ̀ fún èdìdì amọ̀, kí gbogbo rẹ̀ kí ó sì fi ara rẹ̀ hàn bí ẹni pé nínú aṣọ ìgúnwà.
It is changed like the signet-clay; and [all things] stand forth as in a garment:
15 A sì fa ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ ènìyàn búburú, apá gíga ni a sì ṣẹ́.
And from the wicked their light is withholden, and the uplifted arm is broken.
16 “Ìwọ ha wọ inú ìsun òkun lọ rí bí? Ìwọ sì rìn lórí ìsàlẹ̀ ibú ńlá?
Hast thou entered as far as the springs of the sea? and hast thou walked in the recesses of the deep?
17 A ha ṣílẹ̀kùn ikú sílẹ̀ fún ọ rí bí, ìwọ sì rí ìlẹ̀kùn òjìji òkú?
Have the gates of death been revealed unto thee? and hast thou seen the gates of the shadow of death?
18 Ìwọ mòye ìbú ayé bí? Sọ bí ìwọ bá mọ gbogbo èyí.
Hath thine understanding compassed the breadths of the earth? Declare if thou knowest it all.
19 “Ọ̀nà wo ni ìmọ́lẹ̀ ń gbé? Bí ó ṣe ti òkùnkùn, níbo ni ipò rẹ̀,
Where is the way to where light dwelleth? and the darkness, where is its place,
20 tí ìwọ í fi mú un lọ sí ibi àlá rẹ̀, tí ìwọ ó sì le mọ ipa ọ̀nà lọ sínú ilé rẹ̀?
That thou shouldest take it to its bound, and that thou shouldest know the paths to its house?
21 Ìwọ mọ èyí, nítorí nígbà náà ni a bí ọ? Iye ọjọ́ rẹ sì pọ̀.
Thou knowest, for thou wast then born, and the number of thy days is great!
22 “Ìwọ ha wọ inú ìṣúra ìdì òjò lọ rí bí, ìwọ sì rí ilé ìṣúra yìnyín rí,
Hast thou entered into the storehouses of the snow, and hast thou seen the treasuries of the hail,
23 tí mo ti fi pamọ́ de ìgbà ìyọnu, dé ọjọ́ ogun àti ìjà?
Which I have reserved for the time of distress, for the day of battle and war?
24 Ọ̀nà wo ni ó lọ sí ibi tí ìmọ́lẹ̀ fi ń la, tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ń tàn káàkiri lórí ilẹ̀ ayé?
By what way is the light parted, [and] the east wind scattered upon the earth?
25 Ta ni ó la ipadò fún ẹ̀kún omi, àti ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
Who hath divided a channel for the rain-flood, and a way for the thunder's flash;
26 láti mú u rọ̀jò sórí ayé níbi tí ènìyàn kò sí, ní aginjù níbi tí ènìyàn kò sí;
To cause it to rain on the earth, where no one is; on the wilderness wherein there is not a man;
27 láti mú ilẹ̀ tútù, ijù àti aláìro láti mú àṣẹ̀ṣẹ̀yọ ewéko rú jáde?
To satisfy the desolate and waste [ground], and to cause the sprout of the grass to spring forth?
28 Òjò ha ní baba bí? Tàbí ta ni o bí ìkún ìṣe ìrì?
Hath the rain a father? or who begetteth the drops of dew?
29 Láti inú ta ni ìdì omi ti jáde wá? Ta ni ó bí ìrì dídì ọ̀run?
Out of whose womb cometh the ice? and the hoary frost of heaven, who bringeth it forth?
30 Nígbà tí omi di líle bí òkúta, nígbà tí ojú ibú ńlá sì dìpọ̀.
When the waters lie hidden as in stone, and the face of the deep holdeth fast together.
31 “Ìwọ ha le fi ọ̀já de àwọn ìràwọ̀ Pleiadesi dáradára? Tàbí ìwọ le tún di ìràwọ̀ Orioni?
Canst thou fasten the bands of the Pleiades, or loosen the cords of Orion?
32 Ìwọ le mú àwọn àmì méjìlá ìràwọ̀ Masaroti jáde wá nígbà àkókò wọn? Tàbí ìwọ le ṣe amọ̀nà Beari pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀?
Dost thou bring forth the constellations each in its season? or dost thou guide the Bear with her sons?
33 Ǹjẹ́ ìwọ mọ ìlànà ọ̀run? Ìwọ le fi ìjọba Ọlọ́run lélẹ̀ lórí ayé?
Knowest thou the ordinances of the heavens? dost thou determine their rule over the earth?
34 “Ìwọ le gbé ohùn rẹ sókè dé àwọsánmọ̀ kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi kí ó lè bò ọ́?
Dost thou lift up thy voice to the clouds, that floods of waters may cover thee?
35 Ìwọ le rán mọ̀nàmọ́ná kí wọn kí ó le lọ, ní ọ̀nà wọn kí wọn kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Àwa nìyí’?
Dost thou send forth lightnings that they may go, and say unto thee, Here we are?
36 Ta ni ó fi ọgbọ́n pamọ́ sí odò ikùn tàbí tí ó fi òye sínú àyà?
Who hath put wisdom in the inward parts? or who hath given understanding to the mind?
37 Ta ni ó fi ọgbọ́n ka iye àwọsánmọ̀? Ta ni ó sì mú ìgò ọ̀run dà jáde,
Who numbereth the clouds with wisdom? or who poureth out the bottles of the heavens,
38 nígbà tí erùpẹ̀ di líle, àti ògúlùtu dìpọ̀?
When the dust runneth as into a molten mass, and the clods cleave fast together?
39 “Ìwọ ha dẹ ọdẹ fún abo kìnnìún bí? Ìwọ ó sì tẹ ebi ẹgbọrọ kìnnìún lọ́rùn,
Dost thou hunt the prey for the lioness, and dost thou satisfy the appetite of the young lions,
40 nígbà tí wọ́n bá mọ́lẹ̀ nínú ihò tí wọ́n sì ba ní ibùba de ohun ọdẹ?
When they crouch in [their] dens, [and] abide in the thicket to lie in wait?
41 Ta ni ó ń pèsè ohun jíjẹ fún ẹyẹ ìwò, nígbà tí àwọn ọmọ rẹ ń ké pe Ọlọ́run, tí wọ́n sì máa ń fò kiri nítorí àìní ohun jíjẹ?
Who provideth for the raven his food, when his young ones cry unto God, [and] they wander for lack of meat?