< Job 37 >

1 “Àyà sì fò mi sí èyí pẹ̀lú, ó sì kúrò ní ipò rẹ̀.
A nad tem zdumiewa się serce moje, i porusza się z miejsca swego.
2 Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀, kí ẹ sì gbọ́ ìró ohùn rẹ̀, àti èyí tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde wá.
Słuchajcie z pilnością grzmienia głosu jego, i dźwięku który wychodzi z ust jego.
3 Ó ṣe ìlànà rẹ̀ ní ìsàlẹ̀ ọ̀run gbogbo, mọ̀nàmọ́ná rẹ̀ ni ó sì jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́wọ́ dé òpin ilẹ̀ ayé.
Pod wszystkiem niebem prosto go wypuszcza, a światłość jego po wszystkich kończynach ziemi.
4 Lẹ́yìn mọ̀nàmọ́ná ohùn kan fọ̀ ramúramù; ó sì fi ohùn ọláńlá rẹ̀ sán àrá. Òhun kì yóò sì dá àrá dúró, nígbà tí ó bá ń gbọ́ ohùn rẹ̀.
Za nią wnet huczy dźwiękiem, grzmi głosem zacności swojej, i nie odkłada innych rzeczy, gdy bywa słyszany głos jego.
5 Ọlọ́run fi ohùn rẹ̀ sán àrá ní ọ̀nà ìyanu; ohùn ńlá ńlá ni í ṣe tí àwa kò le mọ̀.
Dziwnie Bóg grzmi głosem swoim; sprawuje rzeczy tak wielkie, że ich rozumieć nie możemy.
6 Nítorí tí ó wí fún yìnyín pé, ‘Ìwọ rọ̀ sílẹ̀ ayé,’ àti pẹ̀lú fún ọwọ́ òjò, ‘Fún òjò ńlá agbára rẹ̀.’
Bo mówi do śniegu: Padaj na ziemię; także i do deszczu wolnego, i do deszczu gwałtownego.
7 Ó fi èdìdì di ọwọ́ gbogbo ènìyàn kí gbogbo wọn kí ó lè mọ iṣẹ́ rẹ̀, ó sì tún dá olúkúlùkù ènìyàn dúró lẹ́nu iṣẹ́ rẹ̀.
Rękę wszystkich ludzi zawiera, aby nikt z ludzi nie doglądał roboty swojej.
8 Nígbà náà ní àwọn ẹranko wọ inú ihò lọ, wọn a sì wà ni ipò wọn.
Tedy zwierz wchodzi do jaskini, a w jamach swoich zostaje.
9 Láti ìhà gúúsù ni ìjì àjàyíká tí jáde wá, àti òtútù láti inú afẹ́fẹ́ ti tú àwọsánmọ̀ ká.
Wicher z skrytych miejsc wychodzi, a zima z wiatrów północnych.
10 Nípa ẹ̀mí Ọlọ́run a fi ìdí omi fún ni, ibú omi á sì súnkì.
Tchnieniem swojem Bóg czyni lód, tak iż się szerokość wód ściska.
11 Pẹ̀lúpẹ̀lú ó fi omi púpọ̀ mú àwọsánmọ̀ wúwo, a sì tú àwọsánmọ̀ ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ká ara wọn.
Także dla pokropienia ziemi obciąża obłok, i rozpędza chmurę światłem swojem.
12 Àwọn wọ̀nyí yí káàkiri nípa ìlànà rẹ̀, kí wọn kí ó lè ṣe ohunkóhun tí ó pàṣẹ fún wọn lórí ilẹ̀ ayé.
A ten się obraca w koło według rady jego, aby czynił wszystko, co Bóg rozkaże, na oblicze okręgu ziemskiego.
13 Ó mú àwọsánmọ̀ wá, ìbá ṣe fún ìkìlọ̀, tàbí omi wá sí ayé láti fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn.
A czyni to Bóg, że się stawia bądź na skaranie, bądź dla pożytku ziemi swojej, bądź dla jakiej dobroczynności.
14 “Jobu, dẹtí sílẹ̀ sí èyí; dúró jẹ́ẹ́ kí o sì ro iṣẹ́ ìyanu Ọlọ́run.
Słuchajże tego pilnie, Ijobie! zastanów się, a uważaj dziwne sprawy Boże.
15 Ṣe ìwọ mọ àkókò ìgbà tí Ọlọ́run ṣe wọ́n lọ́jọ̀, tí ó sì mú ìmọ́lẹ̀ àwọsánmọ̀ rẹ̀ dán?
Izali wiesz, kiedy co Bóg stanowi o tych rzeczach? albo gdy ma rozjaśnić światło obłoku swego?
16 Ṣé ìwọ mọ ìgbà tí àwọsánmọ̀ í fò lọ, iṣẹ́ ìyanu ẹni tí ó pé ní ìmọ̀?
Izali wiesz, co za waga obłoków? Izali wiesz cuda Doskonałego we wszelakiej umiejętności?
17 Ìwọ ẹni ti aṣọ rẹ̀ ti máa n gbóná, nígbà tí ó fi atẹ́gùn ìhà gúúsù mú ayé dákẹ́.
Wieszże, jako cię szaty twoje ogrzewają, gdy ucisza ziemię od południa?
18 Ìwọ ha ba tẹ́ pẹpẹ ojú ọ̀run, tí ó dúró ṣinṣin, tí ó sì dàbí dígí tí ó yọ̀ dà?
Izażeś z nim rozpościerał niebiosa, które są trwałe, a zwierciadłu odlewanemu podobne?
19 “Kọ́ wa ní èyí tí a lè wí fún un; nítorí pé àwa kò le wádìí ọ̀rọ̀ náà nítorí òkùnkùn wa.
Ukażże nam, co mu mamy powiedzieć; bo nie możemy sporządzić słów dla ciemności.
20 A ó ha wí fún un pé, èmi fẹ́ sọ̀rọ̀? Tàbí ẹnìkan lè wí pé, ìfẹ́ mi ni pé kí a gbé mi mì?
Izali mu kto odniesie to, cobym mówił? I owszem, gdyby to kto przedłożył, byłby pewnie pożarty.
21 Síbẹ̀ nísinsin yìí ènìyàn kò rí oòrùn tí ń dán nínú àwọsánmọ̀, ṣùgbọ́n afẹ́fẹ́ ń kọjá, a sì gbá wọn mọ́.
Wszak teraz nie mogą ludzie patrzyć i na światło, gdy jest jasne na obłokach, gdy wiatr przechodzi, i przeczyszcza je.
22 Wúrà dídán ti inú ìhà àríwá jáde wá; lọ́dọ̀ Ọlọ́run ni ọláńlá ẹ̀rù ńlá wa.
Od północy jako złoto przychodzi, ale w Bogu straszniejsza jest chwała.
23 Nípa ti Olódùmarè àwa kò le wádìí rẹ̀, ó rékọjá ní ipá; nínú ìdájọ́ àti títí bi òun kì í ba ẹ̀tọ́ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ òtítọ́ jẹ́.
Wszechmogący jest, doścignąć go nie możemy; wielki w mocy, wszakże sądem i ostrą sprawiedliwością ludzi nie trapi.
24 Nítorí náà ènìyàn ha máa bẹ̀rù rẹ̀, òun kì í ṣe ojú sájú ẹnikẹ́ni tí ó gbọ́n ní ayé?”
Przetoż boją się go ludzie; nie ma względu na żadnego, by też był i najmędrszy.

< Job 37 >