< Job 37 >

1 “Àyà sì fò mi sí èyí pẹ̀lú, ó sì kúrò ní ipò rẹ̀.
« Oui, à cela mon cœur tremble, et est déplacé de sa place.
2 Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀, kí ẹ sì gbọ́ ìró ohùn rẹ̀, àti èyí tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde wá.
Écoutez, oh, écoutez le bruit de sa voix, le son qui sort de sa bouche.
3 Ó ṣe ìlànà rẹ̀ ní ìsàlẹ̀ ọ̀run gbogbo, mọ̀nàmọ́ná rẹ̀ ni ó sì jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́wọ́ dé òpin ilẹ̀ ayé.
Il l'envoie sous tout le ciel, et sa foudre jusqu'aux extrémités de la terre.
4 Lẹ́yìn mọ̀nàmọ́ná ohùn kan fọ̀ ramúramù; ó sì fi ohùn ọláńlá rẹ̀ sán àrá. Òhun kì yóò sì dá àrá dúró, nígbà tí ó bá ń gbọ́ ohùn rẹ̀.
Après cela, une voix rugit. Il tonne de la voix de sa majesté. Il ne retient rien quand sa voix est entendue.
5 Ọlọ́run fi ohùn rẹ̀ sán àrá ní ọ̀nà ìyanu; ohùn ńlá ńlá ni í ṣe tí àwa kò le mọ̀.
Dieu fait retentir sa voix d'une manière merveilleuse. Il fait de grandes choses, que nous ne pouvons pas comprendre.
6 Nítorí tí ó wí fún yìnyín pé, ‘Ìwọ rọ̀ sílẹ̀ ayé,’ àti pẹ̀lú fún ọwọ́ òjò, ‘Fún òjò ńlá agbára rẹ̀.’
Car il dit à la neige: « Tombe sur la terre ». comme pour l'averse de pluie, et aux averses de sa pluie puissante.
7 Ó fi èdìdì di ọwọ́ gbogbo ènìyàn kí gbogbo wọn kí ó lè mọ iṣẹ́ rẹ̀, ó sì tún dá olúkúlùkù ènìyàn dúró lẹ́nu iṣẹ́ rẹ̀.
Il scelle la main de chaque homme, afin que tous les hommes qu'il a créés la connaissent.
8 Nígbà náà ní àwọn ẹranko wọ inú ihò lọ, wọn a sì wà ni ipò wọn.
Puis les animaux se mettent à l'abri, et restent dans leur tanière.
9 Láti ìhà gúúsù ni ìjì àjàyíká tí jáde wá, àti òtútù láti inú afẹ́fẹ́ ti tú àwọsánmọ̀ ká.
De sa chambre sort la tempête, et du froid venant du nord.
10 Nípa ẹ̀mí Ọlọ́run a fi ìdí omi fún ni, ibú omi á sì súnkì.
Par le souffle de Dieu, la glace est donnée, et la largeur des eaux est gelée.
11 Pẹ̀lúpẹ̀lú ó fi omi púpọ̀ mú àwọsánmọ̀ wúwo, a sì tú àwọsánmọ̀ ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ká ara wọn.
Oui, il charge d'humidité l'épais nuage. Il répand à l'étranger le nuage de sa foudre.
12 Àwọn wọ̀nyí yí káàkiri nípa ìlànà rẹ̀, kí wọn kí ó lè ṣe ohunkóhun tí ó pàṣẹ fún wọn lórí ilẹ̀ ayé.
Elle est retournée par ses conseils, pour qu'ils fassent tout ce qu'il leur ordonne sur la surface du monde habitable,
13 Ó mú àwọsánmọ̀ wá, ìbá ṣe fún ìkìlọ̀, tàbí omi wá sí ayé láti fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn.
que ce soit pour la correction, ou pour son pays, ou par bonté d'âme, qu'il la fait venir.
14 “Jobu, dẹtí sílẹ̀ sí èyí; dúró jẹ́ẹ́ kí o sì ro iṣẹ́ ìyanu Ọlọ́run.
« Écoute ceci, Job. Arrêtez-vous, et considérez les merveilles de Dieu.
15 Ṣe ìwọ mọ àkókò ìgbà tí Ọlọ́run ṣe wọ́n lọ́jọ̀, tí ó sì mú ìmọ́lẹ̀ àwọsánmọ̀ rẹ̀ dán?
Savez-vous comment Dieu les contrôle? et fait briller les éclairs de sa nuée?
16 Ṣé ìwọ mọ ìgbà tí àwọsánmọ̀ í fò lọ, iṣẹ́ ìyanu ẹni tí ó pé ní ìmọ̀?
Connaissez-vous le fonctionnement des nuages, les merveilles de celui qui est parfait dans la connaissance?
17 Ìwọ ẹni ti aṣọ rẹ̀ ti máa n gbóná, nígbà tí ó fi atẹ́gùn ìhà gúúsù mú ayé dákẹ́.
Toi dont les vêtements sont chauds quand la terre est immobile à cause du vent du sud?
18 Ìwọ ha ba tẹ́ pẹpẹ ojú ọ̀run, tí ó dúró ṣinṣin, tí ó sì dàbí dígí tí ó yọ̀ dà?
Pouvez-vous, avec lui, déployer le ciel, qui est aussi solide qu'un miroir en métal moulé?
19 “Kọ́ wa ní èyí tí a lè wí fún un; nítorí pé àwa kò le wádìí ọ̀rọ̀ náà nítorí òkùnkùn wa.
Apprends-nous ce que nous allons lui dire, car nous ne pouvons pas défendre notre cause à cause de l'obscurité.
20 A ó ha wí fún un pé, èmi fẹ́ sọ̀rọ̀? Tàbí ẹnìkan lè wí pé, ìfẹ́ mi ni pé kí a gbé mi mì?
Lui dira-t-on que je veux parler? Ou un homme devrait-il souhaiter être englouti?
21 Síbẹ̀ nísinsin yìí ènìyàn kò rí oòrùn tí ń dán nínú àwọsánmọ̀, ṣùgbọ́n afẹ́fẹ́ ń kọjá, a sì gbá wọn mọ́.
Maintenant, les hommes ne voient pas la lumière qui brille dans les cieux, mais le vent passe, et les dégage.
22 Wúrà dídán ti inú ìhà àríwá jáde wá; lọ́dọ̀ Ọlọ́run ni ọláńlá ẹ̀rù ńlá wa.
Du nord vient la splendeur de l'or. Avec Dieu, la majesté est impressionnante.
23 Nípa ti Olódùmarè àwa kò le wádìí rẹ̀, ó rékọjá ní ipá; nínú ìdájọ́ àti títí bi òun kì í ba ẹ̀tọ́ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ òtítọ́ jẹ́.
Nous ne pouvons pas atteindre le Tout-Puissant. Il est exalté par le pouvoir. Dans la justice et la grande droiture, il n'opprimera pas.
24 Nítorí náà ènìyàn ha máa bẹ̀rù rẹ̀, òun kì í ṣe ojú sájú ẹnikẹ́ni tí ó gbọ́n ní ayé?”
C'est pourquoi les hommes le révèrent. Il ne considère pas ceux qui sont sages de cœur. »

< Job 37 >