< Job 36 >

1 Elihu sì tún sọ̀rọ̀ wí pé,
Elihu sɵzini dawamlaxturup mundaⱪ dedi: —
2 “Fún mi láyè díẹ̀ èmi ó sì fihàn ọ́, nítorí ọ̀rọ̀ sísọ ní ó kún fún Ọlọ́run.
«Meni birdǝm sɵzligili ⱪoysang, Mǝn yǝnǝ Tǝngrigǝ wakalitǝn ⱪilidiƣan sɵzümning barliⱪini sanga ayan ⱪilimǝn.
3 Èmi ó mú ìmọ̀ mi ti ọ̀nà jíjìn wá, èmi ó sì fi òdodo fún Ẹlẹ́dàá mi.
Bilimni yiraⱪlardin elip kǝltürimǝn, Adǝmlǝrni Yaratⱪuqimni ⱨǝⱪⱪaniy dǝp ⱨesablaydiƣan ⱪilimǝn.
4 Rí i dájú pé ọ̀rọ̀ mi kì yóò ṣèké nítòótọ́; ẹni tí ó pé ní ìmọ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
Mening gepim ⱨǝⱪiⱪǝtǝn yalƣan ǝmǝstur; Bilimi mukǝmmǝl birsi sǝn bilǝn billǝ bolidu.
5 “Kíyèsi i, Ọlọ́run ni alágbára, òun kò i sì gàn ènìyàn; ó ní agbára ní ipá àti òye.
Mana, Tǝngri degǝn uluƣdur, Biraⱪ U ⱨeqkimni kǝmsitmǝydu; Uning qüxinixi qongⱪurdur, mǝⱪsitidǝ qing turidu.
6 Òun kì í dá ẹ̀mí ènìyàn búburú sí, ṣùgbọ́n ó fi òtítọ́ fún àwọn tálákà.
U yamanlarni ⱨayat saⱪlimaydu; Biraⱪ ezilgǝnlǝr üqün adalǝt yürgüzidu.
7 Òun kì í mú ojú rẹ̀ kúrò lára olódodo, ṣùgbọ́n àwọn ọba ni wọ́n wà lórí ìtẹ́; àní ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé, a sì gbé wọn lékè.
U ⱨǝⱪⱪaniylardin kɵzini elip kǝtmǝydu, Bǝlki ularni mǝnggügǝ padixaⱨlar bilǝn tǝhttǝ olturƣuzidu, Xundaⱪ ⱪilip ularning mǝrtiwisi üstün bolidu.
8 Bí ó bá sì dè wọ́n nínú àbà, tí a sì fi okùn ìpọ́njú dè wọ́n,
Wǝ ǝgǝr ular kixǝnlǝngǝn bolsa, Japaning asaritigǝ tutulƣan bolsa,
9 nígbà náà ni ó ń sọ àwọn ohun tí wọn ti ṣe fún wọn, wí pé wọ́n ti ṣẹ̀ pẹ̀lú ìgbéraga wọn.
Undaⱪta U ularƣa ⱪilƣanlirini, Ularning itaǝtsizliklirini, Yǝni ularning kɵrǝnglǝp kǝtkǝnlikini ɵzlirigǝ kɵrsǝtkǝn bolidu.
10 Ó sí wọn létí pẹ̀lú sí ọ̀nà ẹ̀kọ́, ó sì pàṣẹ kí wọn kí ó padà kúrò nínú àìṣedédé.
Xuning bilǝn U ⱪulaⱪlirini tǝrbiyigǝ eqip ⱪoyidu, Ularni yamanliⱪtin ⱪaytixⱪa buyruydu.
11 Bí wọ́n bá gbàgbọ́ tí wọ́n sì sìn ín, wọn ó lo ọjọ́ wọn ní ìrọ̀rùn, àti ọdún wọn nínú afẹ́.
Ular ⱪulaⱪ selip Uningƣa boysunsila Ular [ⱪalƣan] künlirini awatqiliⱪta, Yillirini huxluⱪta ɵtküzidu.
12 Ṣùgbọ́n, bí wọn kò bá gbàgbọ́, wọ́n ó ti ọwọ́ idà ṣègbé, wọ́n á sì kú láìní òye.
Biraⱪ ular ⱪulaⱪ salmisa, ⱪiliqlinip dunyadin ketidu, Bilimsiz ⱨalda nǝpǝstin tohtap ⱪalidu.
13 “Ṣùgbọ́n àwọn àgàbàgebè ní ayé kó ìbínú jọ; wọn kò kígbe fún ìrànlọ́wọ́ nígbà tí ó bá wọ́n wí.
Biraⱪ kɵngligǝ iplasliⱪni pükkǝnlǝr yǝnila adawǝt saⱪlaydu; U ularƣa asarǝt qüxürgǝndimu ular yǝnila tilawǝt ⱪilmaydu.
14 Nígbà náà ni ọkàn wọn yóò kú ní èwe, ní àárín àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà.
Ular yax turupla jan üzidu, Ularning ⱨayati bǝqqiwazlar arisida tügǝydu.
15 Òun gba òtòṣì nínú ìpọ́njú wọn, a sì sọ̀rọ̀ sí wọn ní etí nínú ìnira wọn.
Biraⱪ U azab tartⱪuqilarni azablardin bolƣan tǝrbiyǝ arⱪiliⱪ ⱪutⱪuzidu, U ular har bolƣan waⱪtida ularning ⱪuliⱪini aqidu.
16 “Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lúpẹ̀lú ó fa wọn yọ láti inú ìhágágá sí ibi gbòòrò, sí ibi tí ó ní ààyè tí kò ní wàhálà nínú rẹ̀, ohun tí a sì gbé kalẹ̀ ní tábìlì rẹ̀ jẹ́ kìkì ọ̀rá oúnjẹ tí ó fẹ́.
U xundaⱪ ⱪilip senimu azarning aƣzidin ⱪistangqiliⱪi yoⱪ kǝng bir yǝrgǝ jǝlp ⱪilƣan bolatti; Undaⱪta dastihining mayƣa toldurulƣan bolatti.
17 Ṣùgbọ́n ìwọ kún fún ìdájọ́ àwọn búburú; ìdájọ́ àti òtítọ́ dì ọ́ mú.
Biraⱪ sǝn ⱨazir yamanlarƣa ⱪaritilƣan tegixlik jazalarƣa toldurulƣansǝn; Xunga [Hudaning] ⱨɵkümi ⱨǝm adaliti seni tutuwaldi.
18 Nítorí ìbínú ń bẹ, ṣọ́ra kí òtítọ́ rẹ máa bá a tàn ọ; láti jẹ́ kí títóbi rẹ mú ọ ṣìnà.
Ƣǝzipingning ⱪaynap ketixining seni mazaⱪⱪa baxlap ⱪoyuxidin ⱨuxyar bol; Undaⱪta ⱨǝtta zor kapalǝtmu seni ⱪutⱪuzalmaydu.
19 Ọrọ̀ rẹ pọ̀ tó, tí wàhálà kì yóò fi dé bá ọ bí? Tàbí ipa agbára rẹ?
Yaki bayliⱪliring, Yaki küqüngning zor tirixixliri, Ɵzüngni azab-oⱪubǝttin neri ⱪilalamdu?
20 Má ṣe ìfẹ́ òru, nígbà tí a ń ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò ní ipò wọn.
Keqigǝ ümid baƣlima, Qünki u qaƣda hǝlⱪ ɵz ornidin yoⱪilip ketidu.
21 Máa ṣọ́ra kí ìwọ ki ó má yí ara rẹ̀ padà sí búburú, nítorí èyí tí ìwọ rò pé ó dára jù ìpọ́njú lọ.
Ⱨuxyar bol, ǝskilikkǝ burulup kǝtmǝ; Qünki sǝn [ⱪǝbiⱨlikni] dǝrdkǝ [sǝwr boluxning] ornida talliƣansǝn.
22 “Kíyèsi i, Ọlọ́run ni gbéga nípa agbára rẹ̀; ta ni jẹ́ olùkọ́ni bí rẹ̀?
Mana, Tǝngri küq-ⱪudriti tüpǝylidin üstündur; Uningdǝk ɵgǝtküqi barmu?
23 Ta ni ó là ọ̀nà iṣẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ fún un, tàbí ta ni ó lè wí pé ìwọ ti ń ṣe àìṣedéédéé?
Kim Uningƣa mangidiƣan yolni bekitip bǝrgǝnidi? Wǝ yaki Uningƣa: «Yaman ⱪilding?» deyixkǝ petinalaydu?
24 Rántí kí ìwọ kí ó gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga, ti ènìyàn ni yín nínú orin.
Insanlar tǝbriklǝydiƣan Hudaning ǝmǝllirini uluƣlaxni untuma!
25 Olúkúlùkù ènìyàn a máa rí i; ẹni ikú a máa wò ó ní òkèrè.
Ⱨǝmmǝ adǝm ularni kɵrgǝndur; Insan baliliri yiraⱪtin ularƣa ⱪarap turidu».
26 Kíyèsi i, Ọlọ́run tóbi, àwa kò sì mọ̀ bí ó ti ní òye tó, bẹ́ẹ̀ ni a kò lè wádìí iye ọdún rẹ̀ rí.
« — Bǝrⱨǝⱪ, Tǝngri uluƣdur, biz Uni qüxinǝlmǝymiz, Uning yillirining sanini tǝkxürüp eniⱪliƣili bolmaydu.
27 “Nítorí pé òun ni ó fa ìkán omi òjò sílẹ̀, kí wọn kí ó kán bí òjò ní ìkùùkuu rẹ̀,
Qünki U suni tamqilardin xümürüp qiⱪiridu; Ular parƣa aylinip andin yamƣur bolup yaƣidu.
28 tí àwọsánmọ̀ ń rọ̀ ìrì rẹ̀ sílẹ̀, tí ó sì fi ń sẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ lórí ènìyàn.
Xundaⱪ ⱪilip asmanlar [yamƣurlarni] ⱪuyup berip, Insan baliliri üstigǝ molqiliⱪ yaƣduridu.
29 Pẹ̀lúpẹ̀lú ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè ní ìmọ̀ ìtànká àwọsánmọ̀, tàbí ariwo àrá láti àgọ́ rẹ̀?
Biraⱪ kim bulutlarning toⱪuluxini, Uning [samawi] qedirining gümbür-gümbür ⱪilidiƣanliⱪini qüxinǝlisun?
30 Kíyèsi i, ó tan ìmọ́lẹ̀ yí ara rẹ̀ ká ó sì bo ìsàlẹ̀ òkun mọ́lẹ̀.
Mana, U qaⱪmiⱪi bilǝn ǝtrapini yoruⱪ ⱪilidu, Ⱨǝtta dengiz tǝktinimu yoruⱪ ⱪilidu.
31 Nítorí pé nípa wọn ní ń ṣe dájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ènìyàn; ó sí ń pèsè oúnjẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
U bular arⱪiliⱪ hǝlⱪlǝr üstidin ⱨɵküm qiⱪiridu; Ⱨǝm ular [arⱪiliⱪmu] mol axliⱪ beridu.
32 Ó fi ìmọ́lẹ̀ bo ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì ó sì rán an sí ẹni olódì.
U ⱪollirini qaⱪmaⱪ bilǝn tolduridu, Uningƣa uridiƣan nixanni buyruydu.
33 Ariwo àrá rẹ̀ fi ìjì hàn ní; ọ̀wọ́ ẹran pẹ̀lú wí pé, ó súnmọ́ etílé!
[Hudaning] güldürmamisi uning kelidiƣanliⱪini elan ⱪilidu; Ⱨǝtta kalilarmu sezip, uni elan ⱪilidu.

< Job 36 >