< Job 36 >
1 Elihu sì tún sọ̀rọ̀ wí pé,
І далі Елігу казав:
2 “Fún mi láyè díẹ̀ èmi ó sì fihàn ọ́, nítorí ọ̀rọ̀ sísọ ní ó kún fún Ọlọ́run.
„Почекай мені тро́хи, й тобі покажу́, бо ще́ є про Бога слова́.
3 Èmi ó mú ìmọ̀ mi ti ọ̀nà jíjìn wá, èmi ó sì fi òdodo fún Ẹlẹ́dàá mi.
Зачну́ виклада́ти я зда́лека, і Творце́ві своєму віддам справедливість.
4 Rí i dájú pé ọ̀rọ̀ mi kì yóò ṣèké nítòótọ́; ẹni tí ó pé ní ìmọ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
Бо справді слова́ мої не неправдиві, — я з тобою безва́дний в знанні́.
5 “Kíyèsi i, Ọlọ́run ni alágbára, òun kò i sì gàn ènìyàn; ó ní agbára ní ipá àti òye.
Таж Бог си́льний, і не відкидає ніко́го, Він міцни́й в силі серця.
6 Òun kì í dá ẹ̀mí ènìyàn búburú sí, ṣùgbọ́n ó fi òtítọ́ fún àwọn tálákà.
Не лишає безбожного Він при житті, але право для бідних дає.
7 Òun kì í mú ojú rẹ̀ kúrò lára olódodo, ṣùgbọ́n àwọn ọba ni wọ́n wà lórí ìtẹ́; àní ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé, a sì gbé wọn lékè.
Від праведного Він очей Своїх не відверта́є, але їх садо́вить з царями на троні наза́вжди, — і вони підвищаються.
8 Bí ó bá sì dè wọ́n nínú àbà, tí a sì fi okùn ìpọ́njú dè wọ́n,
А як тільки вони ланцюга́ми пов'я́зані, і тримаються в пу́тах біди́,
9 nígbà náà ni ó ń sọ àwọn ohun tí wọn ti ṣe fún wọn, wí pé wọ́n ti ṣẹ̀ pẹ̀lú ìgbéraga wọn.
то Він їм представляє їх вчинок та їхні провини, що багато їх стало.
10 Ó sí wọn létí pẹ̀lú sí ọ̀nà ẹ̀kọ́, ó sì pàṣẹ kí wọn kí ó padà kúrò nínú àìṣedédé.
Відкриває Він ухо їх для осторо́ги, та вели́ть, щоб вернулися від беззако́ння.
11 Bí wọ́n bá gbàgbọ́ tí wọ́n sì sìn ín, wọn ó lo ọjọ́ wọn ní ìrọ̀rùn, àti ọdún wọn nínú afẹ́.
Якщо тільки послу́хаються, та стануть служити Йому, покі́нчать вони свої дні у добрі, а ро́ки свої у приє́мнощах.
12 Ṣùgbọ́n, bí wọn kò bá gbàgbọ́, wọ́n ó ti ọwọ́ idà ṣègbé, wọ́n á sì kú láìní òye.
Коли ж не послухаються, то наскочать на ра́тище, і покі́нчать життя без знання́.
13 “Ṣùgbọ́n àwọn àgàbàgebè ní ayé kó ìbínú jọ; wọn kò kígbe fún ìrànlọ́wọ́ nígbà tí ó bá wọ́n wí.
А злосерді кладуть гнів на себе, не кричать, коли в'яже Він їх.
14 Nígbà náà ni ọkàn wọn yóò kú ní èwe, ní àárín àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà.
У мо́лодості помирає душа їх, а їхня живая — поміж блудника́ми.
15 Òun gba òtòṣì nínú ìpọ́njú wọn, a sì sọ̀rọ̀ sí wọn ní etí nínú ìnira wọn.
Він визволяє убогого з горя його, а в переслі́дуванні відкриває їм ухо.
16 “Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lúpẹ̀lú ó fa wọn yọ láti inú ìhágágá sí ibi gbòòrò, sí ibi tí ó ní ààyè tí kò ní wàhálà nínú rẹ̀, ohun tí a sì gbé kalẹ̀ ní tábìlì rẹ̀ jẹ́ kìkì ọ̀rá oúnjẹ tí ó fẹ́.
Також і тебе Він би ви́бавив був із тісноти́ на широ́кість, що в ній нема у́тиску, а те, що на стіл твій поклалося б, повне то́вщу було б.
17 Ṣùgbọ́n ìwọ kún fún ìdájọ́ àwọn búburú; ìdájọ́ àti òtítọ́ dì ọ́ mú.
Та правом безбожного ти перепо́внений, право ж та суд підпира́ють люди́ну.
18 Nítorí ìbínú ń bẹ, ṣọ́ra kí òtítọ́ rẹ máa bá a tàn ọ; láti jẹ́ kí títóbi rẹ mú ọ ṣìnà.
Отож лютість нехай не намо́вить тебе до плеска́ння в долоні, а о́куп великий нехай не заве́рне з дороги тебе.
19 Ọrọ̀ rẹ pọ̀ tó, tí wàhálà kì yóò fi dé bá ọ bí? Tàbí ipa agbára rẹ?
Чи в біді допоможе твій зойк та всі змі́цнення сили?
20 Má ṣe ìfẹ́ òru, nígbà tí a ń ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò ní ipò wọn.
Не квапся до ночі тієї, коли ви́рвані будуть народи із місця свого́.
21 Máa ṣọ́ra kí ìwọ ki ó má yí ara rẹ̀ padà sí búburú, nítorí èyí tí ìwọ rò pé ó dára jù ìpọ́njú lọ.
Стережись, не звертайся до зла, яке за́мість біди ти обрав.
22 “Kíyèsi i, Ọlọ́run ni gbéga nípa agbára rẹ̀; ta ni jẹ́ olùkọ́ni bí rẹ̀?
Отож, Бог найвищий у силі Своїй, — хто навчає, як Він?
23 Ta ni ó là ọ̀nà iṣẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ fún un, tàbí ta ni ó lè wí pé ìwọ ti ń ṣe àìṣedéédéé?
Хто дорогу Його Йому вказувати бу́де? І хто скаже: „Ти кривду зробив?“
24 Rántí kí ìwọ kí ó gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga, ti ènìyàn ni yín nínú orin.
Пам'ятай, щоб звели́чувати Його вчинок, про якого виспівують люди,
25 Olúkúlùkù ènìyàn a máa rí i; ẹni ikú a máa wò ó ní òkèrè.
що його бачить всяка люди́на, чоловік приглядається зда́лека.
26 Kíyèsi i, Ọlọ́run tóbi, àwa kò sì mọ̀ bí ó ti ní òye tó, bẹ́ẹ̀ ni a kò lè wádìí iye ọdún rẹ̀ rí.
Отож, Бог великий та недовідо́мий, і недосліди́ме число Його літ!
27 “Nítorí pé òun ni ó fa ìkán omi òjò sílẹ̀, kí wọn kí ó kán bí òjò ní ìkùùkuu rẹ̀,
Бо стягає Він краплі води, і доще́м вони падають з хмари Його,
28 tí àwọsánmọ̀ ń rọ̀ ìrì rẹ̀ sílẹ̀, tí ó sì fi ń sẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ lórí ènìyàn.
що хмари спускають його, і спада́ють дощем на багато людей.
29 Pẹ̀lúpẹ̀lú ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè ní ìmọ̀ ìtànká àwọsánmọ̀, tàbí ariwo àrá láti àgọ́ rẹ̀?
Також хто зрозуміє розтя́гнення хмари, грім намету Його?
30 Kíyèsi i, ó tan ìmọ́lẹ̀ yí ara rẹ̀ ká ó sì bo ìsàlẹ̀ òkun mọ́lẹ̀.
Отож, розтягає Він світло Своє над Собою і мо́рську глибі́нь закриває,
31 Nítorí pé nípa wọn ní ń ṣe dájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ènìyàn; ó sí ń pèsè oúnjẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
бо ними Він судить наро́ди, багато поживи дає.
32 Ó fi ìmọ́lẹ̀ bo ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì ó sì rán an sí ẹni olódì.
Він тримає в руках Своїх бли́скавку, і керує її проти цілі.
33 Ariwo àrá rẹ̀ fi ìjì hàn ní; ọ̀wọ́ ẹran pẹ̀lú wí pé, ó súnmọ́ etílé!
Її гу́ркіт звіщає про неї, і при́хід її відчуває й худо́ба.