< Job 36 >

1 Elihu sì tún sọ̀rọ̀ wí pé,
Elihu de asemenea a continuat și a spus:
2 “Fún mi láyè díẹ̀ èmi ó sì fihàn ọ́, nítorí ọ̀rọ̀ sísọ ní ó kún fún Ọlọ́run.
Permite-mi încă puțin și îți voi arăta că mai [am] să vorbesc pentru Dumnezeu.
3 Èmi ó mú ìmọ̀ mi ti ọ̀nà jíjìn wá, èmi ó sì fi òdodo fún Ẹlẹ́dàá mi.
Îmi voi aduce cunoașterea de departe și voi atribui dreptate Făcătorului meu.
4 Rí i dájú pé ọ̀rọ̀ mi kì yóò ṣèké nítòótọ́; ẹni tí ó pé ní ìmọ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
Căci cu adevărat cuvintele mele nu vor fi false, cel desăvârșit în cunoaștere este cu tine.
5 “Kíyèsi i, Ọlọ́run ni alágbára, òun kò i sì gàn ènìyàn; ó ní agbára ní ipá àti òye.
Iată, Dumnezeu este puternic și nu disprețuiește pe nimeni, el este puternic în tărie și în înțelepciune.
6 Òun kì í dá ẹ̀mí ènìyàn búburú sí, ṣùgbọ́n ó fi òtítọ́ fún àwọn tálákà.
El nu păstrează viața celui stricat, ci dă dreptate celor săraci.
7 Òun kì í mú ojú rẹ̀ kúrò lára olódodo, ṣùgbọ́n àwọn ọba ni wọ́n wà lórí ìtẹ́; àní ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé, a sì gbé wọn lékè.
El nu își ia ochii de la cei drepți, ci ei sunt pe tron cu împărați; da, el îi întemeiază pentru totdeauna, iar ei sunt înălțați.
8 Bí ó bá sì dè wọ́n nínú àbà, tí a sì fi okùn ìpọ́njú dè wọ́n,
Și dacă sunt legați în cătușe și sunt ținuți în funii ale nenorocirii,
9 nígbà náà ni ó ń sọ àwọn ohun tí wọn ti ṣe fún wọn, wí pé wọ́n ti ṣẹ̀ pẹ̀lú ìgbéraga wọn.
Atunci le arată lucrarea lor și fărădelegile lor pe care le-au întrecut.
10 Ó sí wọn létí pẹ̀lú sí ọ̀nà ẹ̀kọ́, ó sì pàṣẹ kí wọn kí ó padà kúrò nínú àìṣedédé.
El de asemenea le deschide urechea la disciplină și le poruncește să se întoarcă de la nelegiuire.
11 Bí wọ́n bá gbàgbọ́ tí wọ́n sì sìn ín, wọn ó lo ọjọ́ wọn ní ìrọ̀rùn, àti ọdún wọn nínú afẹ́.
Dacă ei ascultă de el și îl servesc, își vor petrece zilele în prosperitate și anii lor în plăceri.
12 Ṣùgbọ́n, bí wọn kò bá gbàgbọ́, wọ́n ó ti ọwọ́ idà ṣègbé, wọ́n á sì kú láìní òye.
Dar dacă nu ascultă de el, vor pieri prin sabie și vor muri fără cunoaștere.
13 “Ṣùgbọ́n àwọn àgàbàgebè ní ayé kó ìbínú jọ; wọn kò kígbe fún ìrànlọ́wọ́ nígbà tí ó bá wọ́n wí.
Dar fățarnicii în inimă îngrămădesc furie, ei nu strigă când îi leagă.
14 Nígbà náà ni ọkàn wọn yóò kú ní èwe, ní àárín àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà.
Ei mor la tinerețe și viața lor este printre cei necurați.
15 Òun gba òtòṣì nínú ìpọ́njú wọn, a sì sọ̀rọ̀ sí wọn ní etí nínú ìnira wọn.
El eliberează pe cel sărac în nenorocirea lui și le deschide urechile în oprimare.
16 “Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lúpẹ̀lú ó fa wọn yọ láti inú ìhágágá sí ibi gbòòrò, sí ibi tí ó ní ààyè tí kò ní wàhálà nínú rẹ̀, ohun tí a sì gbé kalẹ̀ ní tábìlì rẹ̀ jẹ́ kìkì ọ̀rá oúnjẹ tí ó fẹ́.
Chiar așa te-ar fi mutat dintr-un loc strâmt într-unul larg, unde nu este strâmtorare și ceea ce ar fi pus pe masa ta ar fi plin de grăsime.
17 Ṣùgbọ́n ìwọ kún fún ìdájọ́ àwọn búburú; ìdájọ́ àti òtítọ́ dì ọ́ mú.
Dar ai împlinit judecata celui stricat, judecată și justiție te apucă.
18 Nítorí ìbínú ń bẹ, ṣọ́ra kí òtítọ́ rẹ máa bá a tàn ọ; láti jẹ́ kí títóbi rẹ mú ọ ṣìnà.
Pentru că este furie, ferește-te ca nu cumva el să te ia cu lovitura lui, atunci o mare răscumpărare nu te va elibera.
19 Ọrọ̀ rẹ pọ̀ tó, tí wàhálà kì yóò fi dé bá ọ bí? Tàbí ipa agbára rẹ?
Va prețui el bogățiile tale? Nu, nici aur, nici toate forțele tăriei.
20 Má ṣe ìfẹ́ òru, nígbà tí a ń ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò ní ipò wọn.
Nu dori noaptea, când oamenii sunt stârpiți din locul lor.
21 Máa ṣọ́ra kí ìwọ ki ó má yí ara rẹ̀ padà sí búburú, nítorí èyí tí ìwọ rò pé ó dára jù ìpọ́njú lọ.
Fii atent, nu privi nelegiuirea, pentru că aceasta ai ales mai degrabă decât nenorocire.
22 “Kíyèsi i, Ọlọ́run ni gbéga nípa agbára rẹ̀; ta ni jẹ́ olùkọ́ni bí rẹ̀?
Iată, Dumnezeu înalță prin puterea sa, cine învață ca el?
23 Ta ni ó là ọ̀nà iṣẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ fún un, tàbí ta ni ó lè wí pé ìwọ ti ń ṣe àìṣedéédéé?
Cine i-a rânduit calea sa? Sau cine poate spune: Tu ai lucrat nelegiuire?
24 Rántí kí ìwọ kí ó gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga, ti ènìyàn ni yín nínú orin.
Amintește-ți să îi preamărești lucrarea, pe care oamenii o privesc.
25 Olúkúlùkù ènìyàn a máa rí i; ẹni ikú a máa wò ó ní òkèrè.
Fiecare o poate vedea; omul o poate privi de departe.
26 Kíyèsi i, Ọlọ́run tóbi, àwa kò sì mọ̀ bí ó ti ní òye tó, bẹ́ẹ̀ ni a kò lè wádìí iye ọdún rẹ̀ rí.
Iată, Dumnezeu este mare și nu îl cunoaștem, nici numărul anilor săi nu poate fi cercetat.
27 “Nítorí pé òun ni ó fa ìkán omi òjò sílẹ̀, kí wọn kí ó kán bí òjò ní ìkùùkuu rẹ̀,
Pentru că el micșorează picăturile de apă; ele toarnă ploaie după aburul lor,
28 tí àwọsánmọ̀ ń rọ̀ ìrì rẹ̀ sílẹ̀, tí ó sì fi ń sẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ lórí ènìyàn.
Pe care norii o picură și o răspândesc abundent peste om.
29 Pẹ̀lúpẹ̀lú ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè ní ìmọ̀ ìtànká àwọsánmọ̀, tàbí ariwo àrá láti àgọ́ rẹ̀?
De asemenea poate cineva înțelege răspândirile norilor, sau zgomotul tabernacolului său?
30 Kíyèsi i, ó tan ìmọ́lẹ̀ yí ara rẹ̀ ká ó sì bo ìsàlẹ̀ òkun mọ́lẹ̀.
Iată, el întinde lumina lui peste acesta și acoperă fundul mării.
31 Nítorí pé nípa wọn ní ń ṣe dájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ènìyàn; ó sí ń pèsè oúnjẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Fiindcă prin ei judecă el pe oameni; el dă mâncare din abundență.
32 Ó fi ìmọ́lẹ̀ bo ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì ó sì rán an sí ẹni olódì.
Cu nori el acoperă lumina și îi poruncește să nu lumineze prin norul din mijloc.
33 Ariwo àrá rẹ̀ fi ìjì hàn ní; ọ̀wọ́ ẹran pẹ̀lú wí pé, ó súnmọ́ etílé!
Tunetul lor arată despre aceasta, vitele de asemenea arată cu privire la abur.

< Job 36 >