< Job 36 >
1 Elihu sì tún sọ̀rọ̀ wí pé,
Un Elihus vēl runāja un sacīja:
2 “Fún mi láyè díẹ̀ èmi ó sì fihàn ọ́, nítorí ọ̀rọ̀ sísọ ní ó kún fún Ọlọ́run.
Pagaidi man vēl maķenīt, es tev mācīšu, jo no Dieva puses vēl kas jāsaka.
3 Èmi ó mú ìmọ̀ mi ti ọ̀nà jíjìn wá, èmi ó sì fi òdodo fún Ẹlẹ́dàá mi.
Es meklēšu savu atzīšanu no tālienes un gādāšu savam radītājam taisnību.
4 Rí i dájú pé ọ̀rọ̀ mi kì yóò ṣèké nítòótọ́; ẹni tí ó pé ní ìmọ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
Jo tiešām, mana valoda nav meli; tavā priekšā ir, kam atzīšanas netrūkst.
5 “Kíyèsi i, Ọlọ́run ni alágbára, òun kò i sì gàn ènìyàn; ó ní agbára ní ipá àti òye.
Redzi, Dievs ir varens un tomēr neatmet, Viņš ir varens gudrības spēkā.
6 Òun kì í dá ẹ̀mí ènìyàn búburú sí, ṣùgbọ́n ó fi òtítọ́ fún àwọn tálákà.
Viņš bezdievīgam neliek dzīvot, un bēdīgam nes tiesu.
7 Òun kì í mú ojú rẹ̀ kúrò lára olódodo, ṣùgbọ́n àwọn ọba ni wọ́n wà lórí ìtẹ́; àní ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé, a sì gbé wọn lékè.
Viņš nenovērš savas acis no taisnā, bet pie ķēniņiem uz goda krēsla, tur Viņš tiem liek sēdēt mūžam, ka top paaugstināti.
8 Bí ó bá sì dè wọ́n nínú àbà, tí a sì fi okùn ìpọ́njú dè wọ́n,
Un kur cietuma ļaudis ir ķēdēs un top turēti bēdu saitēs,
9 nígbà náà ni ó ń sọ àwọn ohun tí wọn ti ṣe fún wọn, wí pé wọ́n ti ṣẹ̀ pẹ̀lú ìgbéraga wọn.
Tur Viņš tiem dara zināmu viņu darbu un viņu pārkāpumus, ka cēlušies lepnībā.
10 Ó sí wọn létí pẹ̀lú sí ọ̀nà ẹ̀kọ́, ó sì pàṣẹ kí wọn kí ó padà kúrò nínú àìṣedédé.
Viņš tiem atdara ausi mācībai, un saka, lai atgriežas no netaisnības.
11 Bí wọ́n bá gbàgbọ́ tí wọ́n sì sìn ín, wọn ó lo ọjọ́ wọn ní ìrọ̀rùn, àti ọdún wọn nínú afẹ́.
Ja tie nu klausa un Viņam kalpo, tad tie pavada savas dienas labumā un savus gadus laimē.
12 Ṣùgbọ́n, bí wọn kò bá gbàgbọ́, wọ́n ó ti ọwọ́ idà ṣègbé, wọ́n á sì kú láìní òye.
Un ja tie neklausa, tad tie krīt caur zobenu un mirst bez atzīšanas.
13 “Ṣùgbọ́n àwọn àgàbàgebè ní ayé kó ìbínú jọ; wọn kò kígbe fún ìrànlọ́wọ́ nígbà tí ó bá wọ́n wí.
Bet kam neskaidra sirds, tie kurn, tie nepiesauc, kad Viņš tos saistījis.
14 Nígbà náà ni ọkàn wọn yóò kú ní èwe, ní àárín àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà.
Tā tad viņu dvēsele mirst jaunībā, un viņu dzīvība paiet ar mauciniekiem.
15 Òun gba òtòṣì nínú ìpọ́njú wọn, a sì sọ̀rọ̀ sí wọn ní etí nínú ìnira wọn.
Bet bēdīgo Viņš izpestī viņa bēdās, un atver viņa ausis bēdu laikā.
16 “Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lúpẹ̀lú ó fa wọn yọ láti inú ìhágágá sí ibi gbòòrò, sí ibi tí ó ní ààyè tí kò ní wàhálà nínú rẹ̀, ohun tí a sì gbé kalẹ̀ ní tábìlì rẹ̀ jẹ́ kìkì ọ̀rá oúnjẹ tí ó fẹ́.
Tāpat Viņš tevi izraus no bēdu rīkles uz klaju vietu, kur bēdu nav, un tavs galds būs pilns ar treknumu.
17 Ṣùgbọ́n ìwọ kún fún ìdájọ́ àwọn búburú; ìdájọ́ àti òtítọ́ dì ọ́ mú.
Bet ja tu esi pilns bezdievīgas tiesāšanās, tad tiesa un sodība tevi ķers.
18 Nítorí ìbínú ń bẹ, ṣọ́ra kí òtítọ́ rẹ máa bá a tàn ọ; láti jẹ́ kí títóbi rẹ mú ọ ṣìnà.
Lai sirds rūgtums tev jel neskubina zaimot, un tā lielā pārbaudīšana lai tevi nenovērš.
19 Ọrọ̀ rẹ pọ̀ tó, tí wàhálà kì yóò fi dé bá ọ bí? Tàbí ipa agbára rẹ?
Vai tu ar brēkšanu no bēdām tiksi vaļā, vai cīnīdamies ar visu spēku?
20 Má ṣe ìfẹ́ òru, nígbà tí a ń ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò ní ipò wọn.
Neilgojies pēc tās nakts, kas noceļ tautas no savas vietas.
21 Máa ṣọ́ra kí ìwọ ki ó má yí ara rẹ̀ padà sí búburú, nítorí èyí tí ìwọ rò pé ó dára jù ìpọ́njú lọ.
Sargies, negriezies pie netaisnības, jo tā tev vairāk patīk nekā pacietība.
22 “Kíyèsi i, Ọlọ́run ni gbéga nípa agbára rẹ̀; ta ni jẹ́ olùkọ́ni bí rẹ̀?
Redzi, Dievs ir augsts savā spēkā; kur ir tāds mācītājs, kā Viņš?
23 Ta ni ó là ọ̀nà iṣẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ fún un, tàbí ta ni ó lè wí pé ìwọ ti ń ṣe àìṣedéédéé?
Kas Viņam raudzīs uz Viņa ceļu, vai kas uz Viņu sacīs: Tu dari netaisnību?
24 Rántí kí ìwọ kí ó gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga, ti ènìyàn ni yín nínú orin.
Piemini, ka arī tu paaugstini Viņa darbu, par ko ļaudis dzied.
25 Olúkúlùkù ènìyàn a máa rí i; ẹni ikú a máa wò ó ní òkèrè.
Visi ļaudis to skatās ar prieku, cilvēks to ierauga no tālienes.
26 Kíyèsi i, Ọlọ́run tóbi, àwa kò sì mọ̀ bí ó ti ní òye tó, bẹ́ẹ̀ ni a kò lè wádìí iye ọdún rẹ̀ rí.
Redzi, Dievs ir augsts un neizmanāms, Viņa gadu pulku nevar izdibināt.
27 “Nítorí pé òun ni ó fa ìkán omi òjò sílẹ̀, kí wọn kí ó kán bí òjò ní ìkùùkuu rẹ̀,
Viņš savelk ūdens lāsītes, un lietus līst no viņa miglas.
28 tí àwọsánmọ̀ ń rọ̀ ìrì rẹ̀ sílẹ̀, tí ó sì fi ń sẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ lórí ènìyàn.
Tas līst no padebešiem un pil uz daudz cilvēkiem.
29 Pẹ̀lúpẹ̀lú ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè ní ìmọ̀ ìtànká àwọsánmọ̀, tàbí ariwo àrá láti àgọ́ rẹ̀?
Vai var izprast, kā padebeši izplešas, un kā Viņa dzīvoklis rīb?
30 Kíyèsi i, ó tan ìmọ́lẹ̀ yí ara rẹ̀ ká ó sì bo ìsàlẹ̀ òkun mọ́lẹ̀.
Redzi, Viņš ģērbjas zibeņu spīdumā un apklājās ar jūras dziļumiem.
31 Nítorí pé nípa wọn ní ń ṣe dájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ènìyàn; ó sí ń pèsè oúnjẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Jo tā Viņš soda tautas un dod barības papilnam.
32 Ó fi ìmọ́lẹ̀ bo ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì ó sì rán an sí ẹni olódì.
Viņa abējās rokās spīdumi, un Viņš tiem rāda, kur lai sper.
33 Ariwo àrá rẹ̀ fi ìjì hàn ní; ọ̀wọ́ ẹran pẹ̀lú wí pé, ó súnmọ́ etílé!
Pērkona balss sludina Viņu nākam, un ganāmi pulki, ka Viņš tuvu.