< Job 36 >
1 Elihu sì tún sọ̀rọ̀ wí pé,
Et Elihou, continuant dit:
2 “Fún mi láyè díẹ̀ èmi ó sì fihàn ọ́, nítorí ọ̀rọ̀ sísọ ní ó kún fún Ọlọ́run.
Patiente un moment encore afin que je t'instruise; je sens en moi bien des choses à dire.
3 Èmi ó mú ìmọ̀ mi ti ọ̀nà jíjìn wá, èmi ó sì fi òdodo fún Ẹlẹ́dàá mi.
Je reprendrai de loin ce que je sais, et, d'accord avec mes œuvres,
4 Rí i dájú pé ọ̀rọ̀ mi kì yóò ṣèké nítòótọ́; ẹni tí ó pé ní ìmọ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
Je te parlerai sincèrement, en homme qui ne conçoit rien d'injuste.
5 “Kíyèsi i, Ọlọ́run ni alágbára, òun kò i sì gàn ènìyàn; ó ní agbára ní ipá àti òye.
Apprends que jamais Dieu, en la force de son cœur, ne repoussera l'innocence.
6 Òun kì í dá ẹ̀mí ènìyàn búburú sí, ṣùgbọ́n ó fi òtítọ́ fún àwọn tálákà.
Jamais il ne vivifiera l'impie; il ne refusera point de juger l'indigent.
7 Òun kì í mú ojú rẹ̀ kúrò lára olódodo, ṣùgbọ́n àwọn ọba ni wọ́n wà lórí ìtẹ́; àní ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé, a sì gbé wọn lékè.
Il ne détournera pas ses regards du juste; il le placera sur le trône avec les rois; il le fera triompher comme eux; ils seront pareillement glorifiés.
8 Bí ó bá sì dè wọ́n nínú àbà, tí a sì fi okùn ìpọ́njú dè wọ́n,
Ceux qu'auront pris des entraves ou les liens de la pauvreté,
9 nígbà náà ni ó ń sọ àwọn ohun tí wọn ti ṣe fún wọn, wí pé wọ́n ti ṣẹ̀ pẹ̀lú ìgbéraga wọn.
Il se contentera de leur faire connaître leurs fautes et leurs œuvres; car ils se raffermiront.
10 Ó sí wọn létí pẹ̀lú sí ọ̀nà ẹ̀kọ́, ó sì pàṣẹ kí wọn kí ó padà kúrò nínú àìṣedédé.
Mais il écoutera les justes, parce qu'il est résolu à les corriger de l'iniquité.
11 Bí wọ́n bá gbàgbọ́ tí wọ́n sì sìn ín, wọn ó lo ọjọ́ wọn ní ìrọ̀rùn, àti ọdún wọn nínú afẹ́.
S'ils lui sont dociles et le servent, ils achèveront leurs jours dans l'abondance des biens, et leurs années dans les grandeurs.
12 Ṣùgbọ́n, bí wọn kò bá gbàgbọ́, wọ́n ó ti ọwọ́ idà ṣègbé, wọ́n á sì kú láìní òye.
Il ne protège point les impies, parce qu'ils refusent de le connaître, et qu'ils sont rebelles à ses avertissements.
13 “Ṣùgbọ́n àwọn àgàbàgebè ní ayé kó ìbínú jọ; wọn kò kígbe fún ìrànlọ́wọ́ nígbà tí ó bá wọ́n wí.
Et les hommes au cœur hypocrite réprimeront leur colère, et ils ne crieront point s'il vient à les enchaîner.
14 Nígbà náà ni ọkàn wọn yóò kú ní èwe, ní àárín àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà.
Ceux-là, que leur âme meure en leur jeunesse, que la vie leur soit ôtée par des anges.
15 Òun gba òtòṣì nínú ìpọ́njú wọn, a sì sọ̀rọ̀ sí wọn ní etí nínú ìnira wọn.
Car ils auront opprimé le pauvre et le faible; que le Seigneur absolve les esprits pacifiques.
16 “Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lúpẹ̀lú ó fa wọn yọ láti inú ìhágágá sí ibi gbòòrò, sí ibi tí ó ní ààyè tí kò ní wàhálà nínú rẹ̀, ohun tí a sì gbé kalẹ̀ ní tábìlì rẹ̀ jẹ́ kìkì ọ̀rá oúnjẹ tí ó fẹ́.
S'il a permis que la bouche de ton ennemi t'ait trompé; les flots de l'abîme sont sous ta table, et elle y tombera chargée de mets.
17 Ṣùgbọ́n ìwọ kún fún ìdájọ́ àwọn búburú; ìdájọ́ àti òtítọ́ dì ọ́ mú.
Il ne fera pas attendre aux justes sa sentence.
18 Nítorí ìbínú ń bẹ, ṣọ́ra kí òtítọ́ rẹ máa bá a tàn ọ; láti jẹ́ kí títóbi rẹ mú ọ ṣìnà.
Son courroux s'élèvera contre les pervers, à cause des dons honteux qu'ils ont reçus pour salaire de leur iniquité.
19 Ọrọ̀ rẹ pọ̀ tó, tí wàhálà kì yóò fi dé bá ọ bí? Tàbí ipa agbára rẹ?
Veille à ne point te détourner de la demande du pauvre pressé par le besoin; quant à ceux qui usent de violence,
20 Má ṣe ìfẹ́ òru, nígbà tí a ń ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò ní ipò wọn.
Ne les soustrais pas la nuit au peuple qui marche contre eux.
21 Máa ṣọ́ra kí ìwọ ki ó má yí ara rẹ̀ padà sí búburú, nítorí èyí tí ìwọ rò pé ó dára jù ìpọ́njú lọ.
Sois attentif à t'abstenir d'actions vaines; c'est d'elles que provient la pauvreté.
22 “Kíyèsi i, Ọlọ́run ni gbéga nípa agbára rẹ̀; ta ni jẹ́ olùkọ́ni bí rẹ̀?
Le Tout-Puissant s'est affermi dans sa force; qui peut prévaloir contre lui?
23 Ta ni ó là ọ̀nà iṣẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ fún un, tàbí ta ni ó lè wí pé ìwọ ti ń ṣe àìṣedéédéé?
Qui peut le rechercher dans ses œuvres et l'accuser d'injustice?
24 Rántí kí ìwọ kí ó gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga, ti ènìyàn ni yín nínú orin.
Souviens-toi qu'il n'a rien fait que de grand, et que les hommes l'ont célébré.
25 Olúkúlùkù ènìyàn a máa rí i; ẹni ikú a máa wò ó ní òkèrè.
Tout homme a vu en lui-même combien les mortels sont vulnérables.
26 Kíyèsi i, Ọlọ́run tóbi, àwa kò sì mọ̀ bí ó ti ní òye tó, bẹ́ẹ̀ ni a kò lè wádìí iye ọdún rẹ̀ rí.
Le Tout-Puissant est multiple, et nous ne le connaîtrons jamais; le nombre de ses années est infini.
27 “Nítorí pé òun ni ó fa ìkán omi òjò sílẹ̀, kí wọn kí ó kán bí òjò ní ìkùùkuu rẹ̀,
Il sait le nombre des gouttes de pluie et il les recueille pour en former de nouveaux nuages.
28 tí àwọsánmọ̀ ń rọ̀ ìrì rẹ̀ sílẹ̀, tí ó sì fi ń sẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ lórí ènìyàn.
Les anciens monuments s'écrouleront, et les nuées couvrent d'ombre le mortel ignoré. Dieu a enseigné les heures aux bestiaux; ils savent régler leur sommeil.
29 Pẹ̀lúpẹ̀lú ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè ní ìmọ̀ ìtànká àwọsánmọ̀, tàbí ariwo àrá láti àgọ́ rẹ̀?
Toutes ces choses sont adhérentes à ta pensée, comme ton cœur à ta poitrine. Si le Seigneur rassemble en une seule toutes les nuées, c'est comme son tabernacle.
30 Kíyèsi i, ó tan ìmọ́lẹ̀ yí ara rẹ̀ ká ó sì bo ìsàlẹ̀ òkun mọ́lẹ̀.
S'il s'enveloppe d'une lueur incertaine, la mer se trouble, et ses profondeurs sont cachées.
31 Nítorí pé nípa wọn ní ń ṣe dájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ènìyàn; ó sí ń pèsè oúnjẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Il juge les peuples selon ce qu'ils valent; les plus puissants lui doivent leur nourriture.
32 Ó fi ìmọ́lẹ̀ bo ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì ó sì rán an sí ẹni olódì.
Il a caché de ses mains la lumière, et, à cause d'elle, il a donné ses préceptes à ceux qui sont survenus.
33 Ariwo àrá rẹ̀ fi ìjì hàn ní; ọ̀wọ́ ẹran pẹ̀lú wí pé, ó súnmọ́ etílé!
Dieu et le bien mal acquis montreront que le Seigneur aime la lumière.